ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb25 November ojú ìwé 4-5
  • November 10-16

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • November 10-16
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2025
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2025
mwb25 November ojú ìwé 4-5

NOVEMBER 10-16

ORIN SÓLÓMỌ́NÌ 3-5

Orin 31 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. Ìdí Tó Fi Yẹ Kó O Níwà Tó Dáa

(10 min.)

Àwọn ọ̀rọ̀ tí ọ̀dọ́bìnrin Ṣúlámáítì máa ń sọ fi hàn pé ó níwà tó dáa (Sol 4:3, 11; w15 1/15 30 ¶8)

Ó tún sọ pé bí ọ̀dọ́bìnrin náà ṣe pa ara ẹ̀ mọ́ mú kó dà bí ọgbà tó ní ẹwà tó ṣàrà ọ̀tọ̀ (Sol 4:12; w00 11/1 11 ¶17)

Ó sàn kéèyàn níwà tó dáa ju pé kó kàn rẹwà, gbogbo wa la sì lè níwà tó dáa (g05 1/8 21 ¶1-4)

Àwòrán: 1. Arábìnrin kan ń tu arábìnrin mí ì tó jẹ́ ọ̀dọ́ nínú. 2. Inú arákùnrin kan ń dùn bó ṣe ń ran arákùnrin àgbàlagbà kan lọ́wọ́ lóde ìwàásù.

BI ARA Ẹ PÉ, ‘Àwọn ìwà wo ni mo fẹ́ràn jù lára àwọn míì?’

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Sol 3:5—Kí nìdí tí ọ̀dọ́bìnrin Ṣúlámáítì fi sọ pé kí àwọn “ọmọbìnrin Jerúsálẹ́mù . . . fi àwọn egbin àti àwọn abo àgbọ̀nrín inú pápá búra”? (w06 11/15 18 ¶4)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

(4 min.) Sol 4:1-16 (th ẹ̀kọ́ 2)

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(3 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Fi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ ẹni náà, kó o sì ṣàlàyé bá a ṣe ń ṣe é. (lmd ẹ̀kọ́ 6 kókó 4)

5. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. Jẹ́ kí ẹni náà rí bó ṣe lè wá àwọn nǹkan tó fẹ́ mọ̀ lórí ìkànnì jw.org lédè rẹ̀. (lmd ẹ̀kọ́ 4 kókó 3)

6. Àsọyé

(5 min.) ijwbq àpilẹ̀kọ 131—Àkòrí: Kí Ni Bíbélì Sọ Nípa Ṣíṣe Ara Lóge? (th ẹ̀kọ́ 1)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 36

7. Gbéyàwó Kìkì Nínú Olúwa (Jẹ 28:2)

(8 min.)

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ náà.

8. Ṣé O Láwọn Ìwà Táá Mú Kó O Jẹ́ Ọkọ Tàbí Ìyàwó Rere?

(7 min.) Ìjíròrò.

Ṣé ò ń wá ẹni tó o máa fẹ́? Tí àwọn tó ń wá ẹni tí wọ́n máa fẹ́ bá rí ẹ, ṣé wọ́n máa gbà pé o níwà tó dáa? Òótọ́ ni pé ẹnì kan lè díbọ́n bí ẹni tó níwà tó dáa, àmọ́ bópẹ́ bóyá àwọn èèyàn máa mọ irú ẹni tó jẹ́ torí pé èéfín nìwà.

Arábìnrin kan wà nínú mọ́tò èrò, ó dìde fún obìnrin kan tó jẹ́ àgbàlagbà kí wọ́n lè ríbi jókòó.
Arákùnrin kan fún ẹni tí wọ́n jọ ń ṣiṣẹ́ ní ìwé ìléwọ́ bí wọ́n ṣe ń kúrò níbiiṣẹ́.
Arákùnrin méjì àti arábìnrin méjì jọ ń ṣiṣẹ́ lóde ìwàásù. Ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin yẹn ń sọ ibi tí àwọn arábìnrin náà á ti ṣiṣẹ́ fún wọn.

Àwọn ìwà tó yẹ kí Kristẹni kọ̀ọ̀kan ní la tò sísàlẹ̀ yìí, kọ àwọn ẹsẹ Bíbélì tó bá ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn mu.

  • Ẹni tó nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, tó sì nígbàgbọ́ nínú ẹ̀

  • Bó ṣe ń lo àṣẹ tó ní tàbí bóyá ó máa ń tẹrí ba

  • Ẹni tí ò mọ tara ẹ̀ nìkan, tó sì máa ń fìfẹ́ hàn

  • Ẹni tó máa ń ṣèpinnu tó dáa, tó mọ̀wọ̀n ara ẹ̀, tó sì máa ń fòye báni lò

  • Ẹni tó máa ń ṣiṣẹ́ kára, tí kì í fiṣẹ́ falẹ̀

9. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) lfb ẹ̀kọ́ 34-35

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 44 àti Àdúrà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́