ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • my ìtàn 71
  • Ọlọ́run Ṣèlérí Párádísè

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ọlọ́run Ṣèlérí Párádísè
  • Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Kí Ni Ète Ọlọrun fún Ilẹ̀ Ayé?
    Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
  • “Àá Pàdé ní Párádísè!”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2018
  • Kí Ni Ọlọ́run Ní Lọ́kàn fún Aráyé?
    Kí Ni Bíbélì Kọ́ Wa?
  • Ìdí Tí Wọ́n Fi Pàdánù Ibùgbé Wọn
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
Àwọn Míì
Ìwé Ìtàn Bíbélì
my ìtàn 71
Àwọn èèyàn ń láyọ̀ nínú Párádísè ẹlẹ́wà tí Aísáyà sọ tẹ́lẹ̀

ÌTÀN 71

Ọlọ́run Ṣèlérí Párádísè

ÀWÒRÁN Párádísè kan nìyí, irú èyí tó ṣeé ṣe kí Ọlọ́run ti fi han Aísáyà wòlíì rẹ̀. Aísáyà gbé láìpẹ́ lẹ́yìn tí Jónà kú.

Párádísè túmọ̀ sí “ọgbà” tàbí “ibi ìtura.” Ṣé kò rán ẹ létí ohun kan tá a ti rí tẹ́lẹ̀ nínú ìwé yìí? Ó jọ ọgbà ẹlẹ́wà tí Jèhófà Ọlọ́run ṣe fún Ádámù àti Éfà lọ́pọ̀lọpọ̀, àbí kò jọ ọ́? Ṣùgbọ́n ǹjẹ́ gbogbo ayé lè di Párádísè bí?

Jèhófà sọ fún Aísáyà wòlíì rẹ̀ pé kó kọ̀wé nípa Párádísè tuntun tó ń bọ̀ fún àwọn èèyàn Ọlọ́run. Ó wí pé: ‘Ìkookò àti ọ̀dọ́ àgùntàn á jùmọ̀ máa gbé pọ̀ lálàáfíà. Àwọn ọmọ màlúù àti ọmọ kìnnìún á máa jẹun pọ̀, àwọn ọmọ kéékèèké á máa ṣe ìtọ́jú wọn. Àní bí ọmọ ọwọ́ bá ń ṣeré nítòsí ejò olóró, kò ní pa á lára.’

Ọ̀pọ̀ èèyàn láá sọ pé: ‘Ìyẹn ò lè ṣẹlẹ̀ láéláé. Kò sígbà tí kò sí ìṣòro ní ayé, kò sì sígbà tí ìṣòro máa tán láyé.’ Ṣùgbọ́n ronú nípa rẹ̀: Irú ilé wo ni Ọlọ́run fún Ádámù àti Éfà?

Ṣebí inú Párádísè ni Ọlọ́run fi Ádámù àti Éfà sí. Nítorí pé wọ́n ṣe àìgbọràn sí Ọlọ́run ni wọ́n fi pàdánù ilé wọn ẹlẹ́wà, tí wọ́n fi darúgbó tí wọ́n sì kú. Ọlọ́run ṣèlérí pé òun máa fún àwọn tó fẹ́ràn òun ní àwọn nǹkan tí Ádámù àti Éfà pàdánù rẹ̀ gan-an.

Nínú Párádísè tó ń bọ̀ kò sí ohun tó máa pani lára tàbí pani run. Àlàáfíà pípé yóò wà. Gbogbo èèyàn ló máa láyọ̀ tí wọ́n sì máa lágbára. Bí Ọlọ́run ti fẹ́ kó rí ní ìbẹ̀rẹ̀ gẹ́lẹ́ ló máa rí. Ṣùgbọ́n a máa rí i níwájú bí Ọlọ́run ṣe máa ṣe èyí.

Aísáyà 11:6-9; Ìṣípayá 21:3, 4.

Àwọn Ìbéèrè fún Ìkẹ́kọ̀ọ́

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́