ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • rq ẹ̀kọ́ 13 ojú ìwé 26-27
  • Báwo Ni O Ṣe Lè Rí Ìsìn Tòótọ́?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Báwo Ni O Ṣe Lè Rí Ìsìn Tòótọ́?
  • Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Báwo Lo Ṣe Lè Mọ Ìsìn Tòótọ́?
    Ìròyìn Ayọ̀ Látọ̀dọ̀ Ọlọ́run!
  • Kí Lo Lè Fi Dá Ẹ̀sìn Tòótọ́ Mọ̀?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
  • Ìjọsìn Tó Ní Ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
  • Ìwọ Ha Ti Rí Ìsì Tí Ó Tọ̀nà Bí?
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1994
Àwọn Míì
Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
rq ẹ̀kọ́ 13 ojú ìwé 26-27

Ẹ̀kọ́ 13

Báwo Ni O Ṣe Lè Rí Ìsìn Tòótọ́?

Gbogbo ìsìn ha ni ó dùn mọ́ Ọlọrun nínú bí, tàbí ẹyọ kan ṣoṣo ni? (1)

Èé ṣe tí ìsìn tí ń jẹ́wọ́ pé wọ́n jẹ́ Kristian fi pọ̀ tó bẹ́ẹ̀? (2)

Báwo ni o ṣe lè mọ àwọn Kristian tòótọ́ yàtọ̀? (3-⁠7)

1. Ìsìn Kristian tòótọ́ kan ṣoṣo ni Jesu dá sílẹ̀. Nítorí náà lónìí, ẹgbẹ́, tàbí àwùjọ, àwọn olùjọsìn Jehofa Ọlọrun kan ṣoṣo péré ni ó ní láti wà. (Johannu 4:​23, 24; Efesu 4:​4, 5) Bibeli kọ́ni pé àwọn ènìyàn díẹ̀ péré ni ó wà ní ojú ọ̀nà tóóró, tí ó lọ sí ìyè.​—⁠Matteu 7:​13, 14.

2. Bibeli sọ tẹ́lẹ̀ pé, lẹ́yìn ikú àwọn aposteli, àwọn ẹ̀kọ́ èké àti àwọn àṣà tí kì í ṣe ti Kristian, yóò yọ́ wọnú ìjọ Kristian. Àwọn ènìyàn yóò fa àwọn onígbàgbọ́ lọ sẹ́yìn ara wọn dípò sẹ́yìn Kristi. (Matteu 7:​15, 21-23; Ìṣe 20:​29, 30) Ìdí nìyẹn tí a fi ń rí púpọ̀ ìsìn tí wọ́n ń jẹ́wọ́ pé àwọ́n jẹ́ Kristian. Báwo ní a ṣe lè mọ àwọn Kristian tòótọ́ yàtọ̀?

3. Àmì ìdánimọ̀ tí ó ṣe kedere jù lọ lára àwọn Kristian tòótọ́ ni pé, wọ́n ní ojúlówó ìfẹ́ láàárín ara wọn. (Johannu 13:​34, 35) A kò kọ́ wọn láti ronú pé wọ́n sàn ju àwọn ènìyàn tí wọ́n jẹ́ ti ẹ̀yà ìran tàbí àwọ̀ ara mìíràn. Bẹ́ẹ̀ sì ni a kò kọ́ wọn láti kórìíra àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti orílẹ̀-èdè míràn. (Ìṣe 10:​34, 35) Nítorí náà, wọn kì í lọ́wọ́ nínú ogun jíjà. Àwọn Kristian tòótọ́ máa ń bá ara wọn lò gẹ́gẹ́ bí arákùnrin àti arábìnrin.​—⁠1 Johannu 4:​20, 21.

4. Àmì ìdánimọ̀ míràn lára ìsìn tòótọ́ ni pé, àwọn mẹ́ḿbà rẹ̀ ní ọ̀wọ̀ jíjinlẹ̀ fún Bibeli. Wọn tẹ́wọ́ gbà á gẹ́gẹ́ bí Ọ̀rọ̀ Ọlọrun, wọ́n sì gbà ohun tí ó sọ gbọ́. (Johannu 17:17; 2 Timoteu 3:​16, 17) Wọ́n ka Ọ̀rọ̀ Ọlọrun sí ohun tí ó ṣe pàtàkì ju èrò tàbí àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ ènìyàn lọ. (Matteu 15:​1-3, 7-⁠9) Wọ́n ń gbìyànjú láti gbé ní ìbámu pẹ̀lú Bibeli nínú ìgbésí ayé wọn ojoojúmọ́. Nítorí náà, wọn kì í wàásù ohun kan, kí wọ́n sì ṣe òmíràn.​—⁠Titu 1:​15, 16.

5. Ìsìn tòótọ́ tún gbọ́dọ̀ bọlá fún orúkọ Ọlọrun. (Matteu 6:⁠9) Jesu sọ orúkọ Ọlọrun, Jehofa, di mímọ̀ fún àwọn ẹlòmíràn. Àwọn Kristian tòótọ́ gbọ́dọ̀ ṣe ohun kan náà. (Johannu 17:​6, 26; Romu 10:​13, 14) Àwọn wo ní àgbègbè rẹ ní ń sọ nípa orúkọ Ọlọrun fún àwọn ẹlòmíràn?

6. Àwọn Kristian tòótọ́ gbọ́dọ̀ wàásù nípa Ìjọba Ọlọrun. Jesu ṣe bẹ́ẹ̀. Òún máa ń sọ nípa Ìjọba náà nígbà gbogbo. (Luku 8:⁠1) Ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ láti wàásù ìhìn iṣẹ́ kan náà yìí ní gbogbo ilẹ̀ ayé. (Matteu 24:14; 28:​19, 20) Àwọn Kristian tòótọ́ gbà gbọ́ pé Ìjọba Ọlọrun nìkan ṣoṣo ni yóò mú àlàáfíà àti ààbò tòótọ́ wá sí ayé yìí.​—⁠Orin Dafidi 146:​3-⁠5.

7. Àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jesu kò gbọdọ̀ jẹ́ apá kan ayé búburú yìí. (Johannu 17:16) Wọn kì í lọ́wọ́ nínú àlámọ̀rí ìṣèlú ayé àti àríyànjiyàn ẹgbẹ́-òun-ọ̀gbà. Wọ́n ń yẹra fún àwọn ìwà, àṣà, àti ìṣarasíhùwà, tí ń pani lára, tí ó wọ́pọ̀ nínú ayé. (Jakọbu 1:27; 4:⁠4) O ha lè dá ẹgbẹ́ ìsìn tí ó ní àwọn àmì ìdánimọ̀ ìsìn Kristian tòótọ́ wọ̀nyí mọ̀ yàtọ̀ ní agbègbè rẹ bi?

[Àwọn àwòrán tó wà ní ojú ìwé 26, 27]

Àwọn Kristian tòótọ́ nífẹ̀ẹ́ ara wọn, wọ́n bọ̀wọ̀ fún Bibeli, wọ́n sì ń wàásù nípa Ìjọba Ọlọrun

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́