ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • jy orí 110 ojú ìwé 254-ojú ìwé 255 ìpínrọ̀ 2
  • Ọjọ́ Tí Jésù Wá sí Tẹ́ńpìlì Kẹ́yìn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ọjọ́ Tí Jésù Wá sí Tẹ́ńpìlì Kẹ́yìn
  • Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Iṣẹ́-òjíṣẹ́ ní Tẹmpili Parí
    Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
  • “Wákàtí Náà Ti Dé!”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
  • Mímú Àwọn Ọjọ́ Tí Jésù Lò Kẹ́yìn Lórí Ilẹ̀ Ayé Wá sí Ìrántí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1998
  • Ọsẹ Naa Ti Ó Yí Ayé Pada
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1992
Àwọn Míì
Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
jy orí 110 ojú ìwé 254-ojú ìwé 255 ìpínrọ̀ 2
Jésù ń wo opó aláìní kan nígbà tó ń fi ẹyọ owó kéékèèké méjì sínú àpótí ìṣúra

ORÍ 110

Ọjọ́ Tí Jésù Wá sí Tẹ́ńpìlì Kẹ́yìn

MÁTÍÙ 23:25–24:2 MÁÀKÙ 12:41–13:2 LÚÙKÙ 21:1-6

  • JÉSÙ TÚBỌ̀ DẸ́BI FÁWỌN AṢÁÁJÚ Ẹ̀SÌN

  • WỌ́N MÁA PA TẸ́ŃPÌLÌ RUN

  • OPÓ ALÁÌNÍ KAN FI ẸYỌ OWÓ KÉÉKÈÈKÉ MÉJÌ SÍNÚ ÀPÓTÍ ÌṢÚRA

Lọ́jọ́ tí Jésù wá sí tẹ́ńpìlì kẹ́yìn, ṣe ló túbọ̀ ń tú àṣírí ìwà àbòsí àwọn akọ̀wé òfin àtàwọn Farisí, ó sì ń pè wọ́n ní alágàbàgebè lójú gbogbo èèyàn. Ó lo àpèjúwe kan, ó ní: “Ẹ̀ ń fọ ẹ̀yìn ife àti abọ́ mọ́, àmọ́ wọ̀bìà àti ìkẹ́rabàjẹ́ kún inú wọn. Farisí afọ́jú, kọ́kọ́ fọ inú ife àti abọ́ mọ́, kí ẹ̀yìn rẹ̀ náà lè mọ́.” (Mátíù 23:25, 26) Tó bá dọ̀rọ̀ ká pa Òfin Mósè mọ́ lórí bóyá ohun kan mọ́ tàbí kò mọ́, àwọn Farisí ò fi ṣeré rárá. Báwọn èèyàn ṣe máa kà wọ́n séèyàn pàtàkì ló gbà wọ́n lọ́kàn. Wọ́n kọ̀ láti ṣàtúnṣe sírú ẹni tí wọ́n jẹ́, kí wọ́n sì fọ ọkàn wọn mọ́.

Bó ṣe ń wù wọ́n láti kọ́ sàréè fún àwọn wòlíì, kí wọ́n sì ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́ fi hàn pé alágàbàgebè ni wọ́n. Jésù sọ fún wọn pé, “ọmọ àwọn tó pa àwọn wòlíì ni yín.” (Mátíù 23:31) Òótọ́ ni Jésù sọ, torí wọ́n gbìyànjú àtipa òun náà.—Jòhánù 5:18; 7:1, 25.

Jésù wá sọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sáwọn aṣáájú ẹ̀sìn yìí tí wọn ò bá ronú pìwà dà, ó sọ pé: “Ẹ̀yin ejò, ọmọ paramọ́lẹ̀, báwo lẹ ṣe máa bọ́ nínú ìdájọ́ Gẹ̀hẹ́nà?” (Mátíù 23:33) Wọ́n máa ń sun ìdọ̀tí nítòsí Àfonífojì Hínómù, torí náà àpèjúwe yìí jẹ́ ká rí irú ìparun ayérayé tó máa gbẹ̀yìn àwọn akọ̀wé òfin àtàwọn Farisí burúkú yẹn.

Àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù ló máa ṣojú fún Jésù, wọ́n máa di ‘wòlíì, amòye àtàwọn tó ń kọ́ni ní gbangba.’ Báwo làwọn èèyàn ṣe máa hùwà sí wọn? Jésù sọ fáwọn aṣáájú ẹ̀sìn yẹn pé: “Ẹ máa pa àwọn kan lára [àwọn ọmọ ẹ̀yìn náà], ẹ sì máa kàn wọ́n mọ́gi, ẹ máa na àwọn kan lára wọn nínú àwọn sínágọ́gù yín, ẹ sì máa ṣe inúnibíni sí wọn láti ìlú dé ìlú, kí ẹ lè jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ gbogbo àwọn olódodo tí wọ́n ta sílẹ̀ ní ayé, látorí ẹ̀jẹ̀ Ébẹ́lì olódodo dórí ẹ̀jẹ̀ Sekaráyà . . . ẹni tí ẹ pa.” Ó wá kìlọ̀ pé: “Lóòótọ́ ni mo sọ fún yín, gbogbo nǹkan yìí máa wá sórí ìran yìí.” (Mátíù 23:34-36) Ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyẹn lọ́dún 70 S.K. nígbà táwọn ọmọ ogun Róòmù pa Jerúsálẹ́mù run, ọ̀pọ̀ àwọn Júù ló sì bá ogun yẹn lọ.

Nígbà tí Jésù ronú nípa gbogbo nǹkan burúkú tó máa ṣẹlẹ̀ yìí. Inú ẹ̀ bà jẹ́, ó sì sọ pé: “Jerúsálẹ́mù, Jerúsálẹ́mù, ìlú tó ń pa àwọn wòlíì, tó sì ń sọ àwọn tí a rán sí i lókùúta, wo bí mo ṣe máa ń fẹ́ kó àwọn ọmọ rẹ jọ tó lọ́pọ̀ ìgbà, bí ìgbà tí àgbébọ̀ adìyẹ ń kó àwọn ọmọ rẹ̀ jọ sábẹ́ ìyẹ́ rẹ̀! Àmọ́ ẹ ò fẹ́ bẹ́ẹ̀. Ẹ wò ó! A ti pa ilé yín tì fún yín.” (Mátíù 23:37, 38) Àwọn tó ń gbọ́rọ̀ rẹ̀ á máa rò ó pé “ilé” wo ló ń sọ. Ṣé ó lè jẹ́ tẹ́ńpìlì tó wà ní Jerúsálẹ́mù, tó jọ pé Ọlọ́run ń dáàbò bò ló ń sọ?

Jésù ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ, ó ní: “Mò ń sọ fún yín pé, ó dájú pé ẹ ò ní rí mi láti ìsinsìnyí títí ẹ fi máa sọ pé, ‘Ìbùkún ni fún ẹni tó ń bọ̀ ní orúkọ Jèhófà!’” (Mátíù 23:39) Inú àsọtẹ́lẹ̀ tó wà nínú Sáàmù 118:26 ni Jésù ti fa ọ̀rọ̀ yìí yọ. Sáàmù yẹn sọ pé: “Ìbùkún ni fún ẹni tó ń bọ̀ ní orúkọ Jèhófà; à ń bù kún yín látinú ilé Jèhófà.” Ó ṣe kedere pé tí tẹ́ńpìlì tó wà ní Jerúsálẹ́mù bá pa run, kò sẹ́ni táá máa wá síbẹ̀ láti wá jọ́sìn Ọlọ́run mọ́.

Jésù wá lọ sí apá ibòmíì nínú tẹ́ńpìlì, ìyẹn ibi táwọn àpótí ìṣúra máa ń wà. Àwọn àpótí ìṣúra yìí dà bíi kàkàkí, àwọn èèyàn sì máa ń fi owó sínú ẹ̀ láti ibi tó ṣí sílẹ̀ lápá òkè. Jésù wá rí ọ̀pọ̀ àwọn Júù tó ń ṣe bẹ́ẹ̀, “àwọn ọlọ́rọ̀ [náà] sì ń fi ẹyọ owó púpọ̀ síbẹ̀.” Ó tún rí opó kan tó jẹ́ aláìní nígbà tó “fi ẹyọ owó kéékèèké méjì tí ìníyelórí rẹ̀ kéré gan-an” sínú àpótí ìṣúra náà. (Máàkù 12:41, 42) Ó dájú pé Jésù mọ bínú Ọlọ́run ṣe máa dùn tó sí ẹ̀bùn tí obìnrin yẹn mú wá.

Jésù wá pe àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ mọ́ra, ó sọ fún wọn pé: “Lóòótọ́ ni mo sọ fún yín pé ohun tí opó aláìní yìí fi sílẹ̀ ju ti gbogbo àwọn yòókù tó fi owó sínú àwọn àpótí ìṣúra.” Lọ́nà wo? Jésù ṣàlàyé pé: “Gbogbo wọn fi síbẹ̀ látinú àjẹṣẹ́kù wọn, àmọ́ òun, láìka pé kò ní lọ́wọ́, ó fi gbogbo ohun tó ní síbẹ̀, gbogbo ohun tó ní láti gbé ẹ̀mí rẹ̀ ró.” (Máàkù 12:43, 44) Ó hàn pé irú ẹ̀mí tí obìnrin yìí ní yàtọ̀ pátápátá sí tàwọn aṣáájú ẹ̀sìn yẹn!

Nígbà tí Nísàn 11 ń parí lọ, Jésù kúrò nínú tẹ́ńpìlì, ọjọ́ yẹn ló sì wá síbẹ̀ kẹ́yìn. Bí wọ́n ṣe ń lọ, ọ̀kan lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ sọ pé: “Olùkọ́, wò ó! àwọn òkúta àti ilé yìí mà wuni o!” (Máàkù 13:1) Ká sòótọ́, bí ọ̀pọ̀ lára òkúta tí wọ́n fi kọ́ ògiri tẹ́ńpìlì yìí ṣe tóbi jẹ́ kó túbọ̀ lágbára, ìyẹn sì jẹ́ kó dà bíi pé títí láé ni tẹ́ńpìlì yẹn máa wà. Torí náà, ó máa yà wọ́n lẹ́nu nígbà tí Jésù sọ pé: “Ṣé o rí àwọn ilé ńlá yìí? Ó dájú pé wọn ò ní fi òkúta kan sílẹ̀ lórí òkúta míì níbí, láìwó o palẹ̀.”—Máàkù 13:2.

Lẹ́yìn tí Jésù parí ọ̀rọ̀ rẹ̀, òun àtàwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ sọdá Àfonífojì Kídírónì, wọ́n sì lọ sí apá ibì kan lórí Òkè Ólífì. Láàárín àsìkò yìí, àwọn ọmọ ẹ̀yìn mẹ́rin kan wà nítòsí Jésù, ìyẹn Pétérù, Áńdérù, Jémíìsì àti Jòhánù. Láti ibi tí wọ́n wà, ó rọrùn fún wọn láti rí tẹ́ńpìlì, kí wọ́n sì rí bó ṣe tóbi tó.

  • Kí ni Jésù ṣe lọ́jọ́ tó wá sí tẹ́ńpìlì kẹ́yìn?

  • Kí ni Jésù sọ pé ó máa ṣẹlẹ̀ sí tẹ́ńpìlì yẹn lọ́jọ́ iwájú?

  • Kí nìdí tí Jésù fi sọ pé ohun tí opó yẹn fi ṣètọrẹ pọ̀ ju tàwọn ọlọ́rọ̀ lọ?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́