ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • ypq ìbéèrè 7 ojú ìwé 21-23
  • Kí Ni Mo Lè Ṣe tí Wọ́n Bá Ń Fi Ìbálòpọ̀ Lọ̀ Mí?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kí Ni Mo Lè Ṣe tí Wọ́n Bá Ń Fi Ìbálòpọ̀ Lọ̀ Mí?
  • Ìdáhùn Àwọn Ìbéèrè 10 Táwọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣé Ìbálòpọ̀ Máa Jẹ́ Ká Túbọ̀ Fẹ́ràn Ara Wa?
    Àwọn Ìbéèrè Tí Àwọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè—Àwọn Ìdáhùn Tí Ó Gbéṣẹ́, Apá Kìíní
  • Ṣé Ìbálòpọ̀ Máa Jẹ́ Ká Túbọ̀ Fẹ́ràn Ara Wa?
    Jí!—2010
  • Báwo Ni Mi Ò Ṣe Ní Jẹ́ Káwọn Ojúgbà Mi Mú Kí N Ṣèṣekúṣe?
    Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé
  • Báwo Ni Mo Ṣe Lè Ṣàlàyé Ohun Tí Mo Gbà Gbọ́ Nípa Ìbálòpọ̀?
    Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé
Àwọn Míì
Ìdáhùn Àwọn Ìbéèrè 10 Táwọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè
ypq ìbéèrè 7 ojú ìwé 21-23
Ọ̀dọ́bìnrin kan ò gbà fún ọ̀dọ́kùnrin kan

ÌBÉÈRÈ 7

Kí Ni Mo Lè Ṣe tí Wọ́n Bá Ń Fi Ìbálòpọ̀ Lọ̀ Mí?

ÌDÍ TỌ́RỌ̀ YÌÍ FI ṢE PÀTÀKÌ

Ipa kékeré kọ́ ni ìpinnu tó o bá ṣe lórí ọ̀rọ̀ ìbálòpọ̀ máa ní lórí ìgbésí ayé rẹ.

KÍ LO MÁA ṢE?

Fojú inú wo ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí: Kò tíì ju oṣù méjì lọ tí Heather àti Mike ti ń fẹ́ra, àmọ́ lójú Heather, àfi bíi pé wọ́n ti mọra tipẹ́. Wọ́n máa ń fọ̀rọ̀ ránṣẹ́ síra wọn ní gbogbo ìgbà, ọ̀pọ̀ wákàtí ni wọ́n fi máa ń bára wọn sọ̀rọ̀ lórí fóònù, kódà, níbi tọ́rọ̀ wọn wọ̀ dé, bí ọ̀kan nínú wọn bá gbẹ́nu lé ọ̀rọ̀, èkejì lè bá a parí ẹ̀ torí ó ti mọ ohun tó fẹ́ sọ! Àmọ́ ohun tí Mike ń wá jùyẹn lọ.

Láàárín oṣù méjì tó kọjá, Mike àti Heather ò ṣe kọjá kí wọ́n kàn dira wọn lọ́wọ́ mú kí wọ́n sì fẹnu konu fẹ́ẹ́rẹ́fẹ́. Heather ò sì fẹ́ kó jùyẹn lọ. Síbẹ̀, kò fẹ́ kí Mike fi òun sílẹ̀. Kò sẹ́ni tó gba tiẹ̀ bíi Mike, ṣe ni Mike máa ń kẹ́ ẹ lójú kẹ́ ẹ nímú. Ó tún ń rò ó lọ́kàn ara rẹ̀ pé, ‘Èmi àti Mike kúkú fẹ́ràn ara wa gan-an . . . ’

Tó bá jẹ́ ìwọ ni Heather, tó o sì ti dàgbà tẹ́ni tó ń ní àfẹ́sọ́nà, kí lo máa ṣe?

RÒ Ó WÀ NÁ!

Ó ń fi aṣọ tó dáa nu ìdọ̀tí

Ẹ̀bùn látọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ìbálòpọ̀, àwọn tó sì ti ṣègbéyàwó nìkan ló wà fún. Tó o bá ní ìbálòpọ̀ láìtíì ṣègbéyàwó, ṣe lò ń ṣe ẹ̀bùn tí Ọlọ́run fún ẹ báṣubàṣu. Ṣe nìyẹn sì dà bí ìgbà tó o sọ aṣọ olówó iyebíye tẹ́nì kan fún ẹ di aṣọ ìnulẹ̀

Ẹni bá finá ṣeré, iná á jó o. Bẹ́ẹ̀ náà lọ̀rọ̀ rí tó o bá rú òfin tó jẹ mọ́ irú ìwà tó yẹ kéèyàn máa hù, bí èyí tó sọ pé: “Ẹ ta kété sí àgbèrè.”​—1 Tẹsalóníkà 4:⁠3.

Kí làwọn ohun tó máa ṣẹlẹ̀ tó o bá rú òfin yìí? Bíbélì sọ pé: “Ẹni tí ó bá ń ṣe àgbèrè ń ṣẹ̀ sí ara òun fúnra rẹ̀.” (1 Kọ́ríńtì 6:18) Ṣé òótọ́ lọ̀rọ̀ yìí?

Àwọn tó ń ṣèwádìí ti rí i pé ọ̀kan tàbí jú bẹ́ẹ̀ lọ lára àwọn nǹkan tá a máa bẹ̀rẹ̀ sí í jíròrò yìí ti ṣẹlẹ̀ sí ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀dọ́ tó ti ní ìbálòpọ̀ láìtíì ṣègbéyàwó.

  • ÌDÀÀMÚ ỌKÀN. Ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀dọ́ tí wọ́n ti ní ìbálòpọ̀ láìtíì ṣègbéyàwó ló sọ pé àwọn pa dà kábàámọ̀ rẹ̀.

  • WỌN KÌ Í FỌKÀN TÁN ARA WỌN. Lẹ́yìn táwọn méjì tí kò tíì ṣègbéyàwó bá ti ní ìbálòpọ̀, wọ́n á máa sọ lọ́kàn ara wọn pé, ‘Ta ló mọ ẹlòmíì tó ti tún bá sùn?’

  • ÌJÁKULẸ̀. Nínú ọkàn wọn lọ́hùn-ún, àwọn ọmọbìnrin sábà máa ń fẹ́ ẹni tó máa tọ́jú wọn, kì í ṣẹni tó kàn máa bá wọn sùn tán, táá sì já wọn jù sílẹ̀. Àwọn ọmọkùnrin sì máa ń sọ pé àwọn ò lè fẹ́ ọmọbìnrin táwọn ti bá sùn.

  • Òótọ́ ibẹ̀ ni pé: Tó o bá lọ ní ìbálòpọ̀ kó o tó ṣègbéyàwó, ṣe lo ta ara rẹ lọ́pọ̀, ohun iyebíye lo sì gbé sọ nù yẹn. (Róòmù 1:24) O ṣeyebíye gan-an, kò sì ní dáa kó o tara ẹ lọ́pọ̀!

Séra ró, kó o sì tipa bẹ́ẹ̀ “ta kété sí àgbèrè.” (1 Tẹsalóníkà 4:⁠3) Tó o bá sì wá pa dà ṣègbéyàwó, wàá lómìnira láti ní ìbálòpọ̀. Wàá sì lè gbádùn rẹ̀ dáadáa, láìsí ìdààmú tàbí àbámọ̀, o ò sì ní kó sínú ìṣòro àìbalẹ̀ ọkàn tí àwọn tó ní ìbálòpọ̀ láìtíì ṣègbéyàwó máa ń ní.​—Òwe 7:​22, 23; 1 Kọ́ríńtì 7:⁠3.

KÍ LÈRÒ Ẹ?

  • Ṣẹ́ni tó bá nífẹ̀ẹ́ rẹ lóòótọ́ á ṣe ohun tó máa pa ẹ́ lára táá sì tún kó ẹ̀dùn ọkàn bá ẹ?

  • Ṣẹ́ni tó bá nífẹ̀ẹ́ rẹ dénú á tàn ẹ́ láti ṣe ohun tó máa mú kí àjọṣe ìwọ àti Ọlọ́run bà jẹ́?​—Hébérù 13:4.

Ẹ̀YIN ỌMỌBÌNRIN

Ọ̀dọ́bìnrin kan jókòó, ó ń ronú

Àìmọye àwọn ọkùnrin ló máa ń sọ pé àwọn ò lè fẹ́ obìnrin tí àwọn ti bá sùn. Kí nìdí? Ìdí ni pé, wọn ò fẹ́ oníṣekúṣe obìnrin!

Ṣé ọ̀rọ̀ yẹn yà ẹ́ lẹ́nu? Bóyá ó tiẹ̀ múnú bí ẹ pàápàá. Wá fi kókó pàtàkì yìí sọ́kàn: Ṣe làwọn fíìmù àtàwọn ètò orí tẹlifíṣọ̀n tí wọ́n máa ń gbé jáde máa ń jẹ́ kó dà bíi pé kò sóhun tó burú níbẹ̀ tàwọn ọ̀dọ́ tí kò tíì pọ́mọ ogún ọdún bá ń ní ìbálòpọ̀, wọ́n ní ìgbádùn ni, wọ́n tiẹ̀ máa ń mú kó dà bíi pé ìfẹ́ tòótọ́ ni.

Má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn ẹ́ jẹ o! Ọgbọ́n kí wọ́n lè tẹ́ ìfẹ́ ọkàn ara wọn lọ́rùn láwọn tó ń fi ìbálòpọ̀ lọ̀ ẹ́ ń wá.​—1 Kọ́ríńtì 13:​4, 5.

Ẹ̀YIN ỌMỌKÙNRIN

Ọ̀dọ́kùnrin kan jókòó, ó ń ronú

Tó o bá ti lẹ́ni tó ò ń fẹ́, bi ara rẹ pé, ‘Ṣé mo nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ dénú lóòótọ́?’ Tó o bá nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ dénú lóòótọ́, báwo lo ṣe lè jẹ́ kó mọ̀ pé o nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ lóòótọ́? Àwọn ọ̀nà tó o lè gbà ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé kó o séra ró kó o lè pa òfin Ọlọ́run mọ́, kó o jẹ́ ọlọgbọ́n kó o lè yẹra fún àwọn ohun tó lè mú kẹ́ ẹ ṣèṣekúṣe, kó o sì nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ débi pé o ò ní fẹ́ ṣohun tó máa pa á lára.

Tó o bá ṣe àwọn nǹkan yìí, ṣe ni inú ọ̀rẹ́bìnrin rẹ á máa dùn bíi ti ọmọbìnrin Ṣúnémù tó sọ pé: “Tèmi ni olólùfẹ́ mi, tirẹ̀ sì ni èmi.” (Orin Sólómọ́nì 2:16) Ṣe ni ìfẹ́ rẹ á túbọ̀ máa lágbára sí i lọ́kàn rẹ̀!

OHUN TÓ O LÈ ṢE

Tẹ́nì kan bá fẹ́ dọ́gbọ́n tàn ẹ́ kẹ́ ẹ lè bá ara yín lòpọ̀, tó ń sọ pé, “Tó o bá nífẹ̀ẹ́ mi, wàá gbà fún mi,” ìwọ náà fún un lésì láìyẹhùn pé, “Tó o bá nífẹ̀ẹ́ mi, o ò ní fi lọ̀ mí!”

Tó bá dọ̀rọ̀ bó ṣe yẹ kí ọkùnrin àti obìnrin máa ṣe pẹ̀lú ara wọn, ìlànà tó dára tó o lè tẹ̀ lé rèé: Tó bá jẹ́ pé ohun tó ò fẹ́ káwọn òbí ẹ ká mọ́ ẹ lọ́wọ́ lo fẹ́ ṣe, a jẹ́ pé kò yẹ kó o ṣe é nìyẹn.

OHUN TÍ MÀÁ ṢE

  • Kí lo máa ṣe tẹ́nì kan bá sọ pé kẹ́ ẹ jọ ní ìbálòpọ̀?

  • Àwọn nǹkan wo ló lè mú kó túbọ̀ ṣòro fún ẹ láti kọ̀ jálẹ̀ pé o ò ṣe?

  • Kí lo lè ṣe láti yẹra fún irú àwọn nǹkan bẹ́ẹ̀?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́