ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 4 ojú ìwé 16-ojú ìwé 17 ìpínrọ̀ 2
  • Kéènì Bínú Pa Àbúrò Rẹ̀

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kéènì Bínú Pa Àbúrò Rẹ̀
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àwọn Ọmọ Ìyá Kan Náà Tí Ìwà Wọ́n Yàtọ̀ Síra
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
  • Ọmọ Rere Àti Ọmọ Búburú
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Rírú Ẹbọ Tí Jèhófà Yóò Tẹ́wọ́ Gbà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1999
  • Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn Òǹkàwé
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 4 ojú ìwé 16-ojú ìwé 17 ìpínrọ̀ 2
Inú bí Kéènì nígbà tí Ébẹ́lì rú ẹbọ sí Jèhófà

Ẹ̀KỌ́ 4

Kéènì Bínú Pa Àbúrò Rẹ̀

Lẹ́yìn tí Ádámù àti Éfà jáde kúrò nínú ọgbà Édẹ́nì, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í bímọ. Kéènì lorúkọ ọmọ tí wọ́n kọ́kọ́ bí, iṣẹ́ àgbẹ̀ ló ń ṣe. Ébẹ́lì lọmọ wọn kejì, àgùntàn lòun máa ń bójú tó ní tiẹ̀.

Lọ́jọ́ kan, àwọn méjèèjì rú ẹbọ sí Jèhófà. Ṣé o mọ ohun tíyẹn túmọ̀ sí? Ńṣe ni wọ́n fún Jèhófà ní ẹ̀bùn pàtàkì. Inú Jèhófà dùn sí ẹbọ Ébẹ́lì, àmọ́ inú rẹ̀ kò dùn sí ẹbọ Kéènì. Ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn bí Kéènì nínú gan-an. Jèhófà wá kìlọ̀ fún Kéènì pé inú tó ń bí i lè mú kó ṣe nǹkan tó burú. Àmọ́, Kéènì kò gbọ́ràn sí Ọlọ́run lẹ́nu.

Ǹjẹ́ o mọ ohun tí Kéènì ṣe? Ó sọ fún Ébẹ́lì àbúrò ẹ̀ pé: ‘Jẹ́ ká jọ lọ sí oko.’ Nígbà tí wọ́n dénú oko, Kéènì fi nǹkan lu àbúrò ẹ̀, ó sì pa á. Kí lo rò pé Jèhófà máa ṣe? Jèhófà fìyà jẹ Kéènì, ó lé e jìnnà sílé. Kéènì ò lè pa dà sọ́dọ̀ àwọn ẹbí ẹ̀ mọ́.

Kéènì ń lọ sọ́dọ̀ Ébẹ́lì nínú oko

Ẹ̀kọ́ wo nìyẹn kọ́ ẹ? O lè máa bínú tí nǹkan ò bá rí bó o ṣe fẹ́. Bóyá o máa ń bínú gan-an débi pé àwọn èèyàn ti ń kìlọ̀ fún ẹ. Á dáa kó o tètè wá nǹkan ṣe, kó o sì yíwà pa dà. Ìdí ni pé tó ò bá tètè wá nǹkan ṣe, ìbínú lè mú kó o hùwà burúkú.

Ébẹ́lì nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, ó sì níwà tó dáa, ìdí nìyẹn tí Jèhófà ò fi ní gbàgbé ẹ̀ láé. Jèhófà máa jí Ébẹ́lì dìde nígbà tí ayé bá di Párádísè.

“Kọ́kọ́ wá àlàáfíà pẹ̀lú arákùnrin rẹ, lẹ́yìn náà, kí o pa dà wá fi ẹ̀bùn rẹ rúbọ.”​—Mátíù 5:24

Ìbéèrè: Kí lorúkọ ọmọ àkọ́kọ́ àti ìkejì tí Ádámù àti Éfà bí? Kí nìdí tí Kéènì fi pa àbúrò ẹ̀?

Jẹ́nẹ́sísì 4:1-12; Hébérù 11:4; 1 Jòhánù 3:11, 12

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́