ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 8 ojú ìwé 26-ojú ìwé 27 ìpínrọ̀ 1
  • Ábúráhámù àti Sérà Ṣègbọràn sí Ọlọ́run

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ábúráhámù àti Sérà Ṣègbọràn sí Ọlọ́run
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ta Ni Ábúráhámù?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2012
  • Ábúráhámù—Ọ̀rẹ́ Ọlọ́run
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Ábúráhámù àti Sárà—O Lè Fara Wé Ìgbàgbọ́ Wọn!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2004
  • Jèhófà Pè É Ní “Ọ̀rẹ́ Mi”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 8 ojú ìwé 26-ojú ìwé 27 ìpínrọ̀ 1
Ábúráhámù àti Sérà ń kó ẹrù wọn bí wọ́n ṣe fẹ́ kúrò nílùú Úrì

Ẹ̀KỌ́ 8

Ábúráhámù àti Sérà Ṣègbọràn sí Ọlọ́run

Ìlú kan wà tí kò jìnnà sí Bábélì, orúkọ ìlú yẹn ni Úrì. Òrìṣà làwọn ará ìlú yìí ń bọ, àmọ́ ọkùnrin kan wà níbẹ̀ tó ń sin Jèhófà. Orúkọ ọkùnrin náà ni Ábúráhámù.

Lọ́jọ́ kan, Jèhófà sọ fún Ábúráhámù pé: ‘Kúrò nílùú yìí, kó o sì fi àwọn èèyàn ẹ sílẹ̀, kó o lọ máa gbé nílẹ̀ kan tí màá fi hàn ẹ́.’ Jèhófà wá ṣèlérí fún un pé: ‘Màá sọ ẹ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, màá tún ṣe àwọn nǹkan dáadáa fáwọn èèyàn níbi gbogbo láyé nítorí tìẹ.’

Ábúráhámù ò mọ ibi tí Jèhófà fẹ́ kó lọ, àmọ́ ó gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà. Torí náà, Ábúráhámù ṣègbọràn, òun àti Sérà ìyàwó ẹ̀ pẹ̀lú Térà bàbá ẹ̀ àti Lọ́ọ̀tì tó jẹ́ ọmọ ẹ̀gbọ́n ẹ̀ kó gbogbo ẹrù wọn, wọ́n sì forí lé ibi tó jìnnà gan-an tí Jèhófà sọ pé òun máa fi hàn wọ́n.

Ẹni ọdún márùndínlọ́gọ́rin (75) ni Ábúráhámù nígbà tóun àti ìdílé ẹ̀ dé ibi tí Jèhófà ní kí wọ́n lọ. Orúkọ ibẹ̀ ni Kénáánì. Ìlú yẹn ni wọ́n wà nígbà tí Ọlọ́run tún bá Ábúráhámù sọ̀rọ̀ tó sì ṣèlérí fún un pé: ‘Ṣé o rí gbogbo ìlú yìí, àwọn ọmọ rẹ ni màá fún.’ Ǹjẹ́ o mọ̀ pé Ábúráhámù àti Sérà ò tíì bímọ lásìkò tí Jèhófà ṣèlérí yẹn? Torí náà, báwo ni Jèhófà ṣe máa mú kí ọmọ wọn jogún ilẹ̀ náà?

Ábúráhámù àti ìdílé ẹ̀ ń rin ìrìn àjò lọ sí ilẹ̀ Kénáánì

“Ìgbàgbọ́ mú kí Ábúráhámù ṣègbọràn . . . ó lọ sí ibì kan tó máa gbà, tó sì máa jogún; ó jáde lọ, bí kò tiẹ̀ mọ ibi tó ń lọ.”​—Hébérù 11:8

Ìbéèrè: Kí ni Jèhófà sọ pé kí Ábúráhámù ṣe? Ìlérí wo ni Jèhófà ṣe fún Ábúráhámù?

Jẹ́nẹ́sísì 11:29–12:9; Ìṣe 7:2-4; Gálátíà 3:6; Hébérù 11:8

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́