Ẹ̀KỌ́ 8
Ábúráhámù àti Sérà Ṣègbọràn sí Ọlọ́run
Ìlú kan wà tí kò jìnnà sí Bábélì, orúkọ ìlú yẹn ni Úrì. Òrìṣà làwọn ará ìlú yìí ń bọ, àmọ́ ọkùnrin kan wà níbẹ̀ tó ń sin Jèhófà. Orúkọ ọkùnrin náà ni Ábúráhámù.
Lọ́jọ́ kan, Jèhófà sọ fún Ábúráhámù pé: ‘Kúrò nílùú yìí, kó o sì fi àwọn èèyàn ẹ sílẹ̀, kó o lọ máa gbé nílẹ̀ kan tí màá fi hàn ẹ́.’ Jèhófà wá ṣèlérí fún un pé: ‘Màá sọ ẹ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, màá tún ṣe àwọn nǹkan dáadáa fáwọn èèyàn níbi gbogbo láyé nítorí tìẹ.’
Ábúráhámù ò mọ ibi tí Jèhófà fẹ́ kó lọ, àmọ́ ó gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà. Torí náà, Ábúráhámù ṣègbọràn, òun àti Sérà ìyàwó ẹ̀ pẹ̀lú Térà bàbá ẹ̀ àti Lọ́ọ̀tì tó jẹ́ ọmọ ẹ̀gbọ́n ẹ̀ kó gbogbo ẹrù wọn, wọ́n sì forí lé ibi tó jìnnà gan-an tí Jèhófà sọ pé òun máa fi hàn wọ́n.
Ẹni ọdún márùndínlọ́gọ́rin (75) ni Ábúráhámù nígbà tóun àti ìdílé ẹ̀ dé ibi tí Jèhófà ní kí wọ́n lọ. Orúkọ ibẹ̀ ni Kénáánì. Ìlú yẹn ni wọ́n wà nígbà tí Ọlọ́run tún bá Ábúráhámù sọ̀rọ̀ tó sì ṣèlérí fún un pé: ‘Ṣé o rí gbogbo ìlú yìí, àwọn ọmọ rẹ ni màá fún.’ Ǹjẹ́ o mọ̀ pé Ábúráhámù àti Sérà ò tíì bímọ lásìkò tí Jèhófà ṣèlérí yẹn? Torí náà, báwo ni Jèhófà ṣe máa mú kí ọmọ wọn jogún ilẹ̀ náà?
“Ìgbàgbọ́ mú kí Ábúráhámù ṣègbọràn . . . ó lọ sí ibì kan tó máa gbà, tó sì máa jogún; ó jáde lọ, bí kò tiẹ̀ mọ ibi tó ń lọ.”—Hébérù 11:8