ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 18 ojú ìwé 48-ojú ìwé 49 ìpínrọ̀ 4
  • Iná Ń Jó Lára Igi Kékeré Kan

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Iná Ń Jó Lára Igi Kékeré Kan
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Igbó Tí Ń Jó
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Bí Ohun Tí Mósè Gbélé Ayé Ṣe Ṣe Kàn Ọ́
    Jí!—2004
  • Ìdí Tí Mósè Fi Sá Lọ
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Mọ Àwọn Ọ̀nà Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 18 ojú ìwé 48-ojú ìwé 49 ìpínrọ̀ 4
Mósè níbi tíná ti ń jó igi kan

Ẹ̀KỌ́ 18

Iná Ń Jó Lára Igi Kékeré Kan

Ogójì (40) ọdún ni Mósè fi gbé nílẹ̀ Mídíánì. Ó fẹ́ ìyàwó, ó sì ní àwọn ọmọ. Lọ́jọ́ kan, ó ń tọ́jú àwọn àgùntàn ẹ̀ nítòsí Òkè Sínáì, ohun kan ṣẹlẹ̀ tó yà á lẹ́nu. Ṣàdédé ló rí i tí iná ń jó igi kékeré kan tó ní ẹ̀gún lára, síbẹ̀ igi náà ò jóná! Nígbà tí Mósè sún mọ́ tòsí ibẹ̀ kó lè mọ ohun tó ń ṣẹlẹ̀, ó gbọ́ ohùn kan láàárín igi náà, ohùn yẹn sọ pé: ‘Mósè! Dúró síbi tó o dé yẹn. Bọ́ bàtà ẹsẹ̀ rẹ torí pé ilẹ̀ mímọ́ ni ibi tó o wà.’ Jèhófà ló rán áńgẹ́lì kan láti bá Mósè sọ̀rọ̀.

Ẹ̀rù ba Mósè, ó sì bo ojú rẹ̀. Ohùn náà wá sọ pé: ‘Mo ti rí ìyà tí wọ́n fi ń jẹ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Mo máa gbà wọ́n sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Íjíbítì, màá sì mú wọn lọ sí ilẹ̀ tó dáa gan-an. Ìwọ lo máa kó wọn jáde kúrò nílẹ̀ Íjíbítì.’ Ọ̀rọ̀ yẹn máa ya Mósè lẹ́nu gan-an o, àbí bẹ́ẹ̀ kọ́?

Mósè béèrè pé: ‘Kí ni mo máa sọ táwọn èèyàn náà bá béèrè pé ta ló rán mi?’ Ọlọ́run dáhùn pé: ‘Sọ fún wọn pé Jèhófà, Ọlọ́run Ábúráhámù, Ọlọ́run Ísákì àti Ọlọ́run Jékọ́bù ló rán mi sí yín.’ Mósè wá sọ pé: ‘Táwọn èèyàn náà ò bá fetí sí mi ńkọ́?’ Jèhófà wá ṣe ohun kan táá jẹ́ kó mọ̀ pé òun máa ràn án lọ́wọ́. Ó ní kí Mósè sọ ọ̀pá tó wà lọ́wọ́ ẹ̀ sílẹ̀. Ǹjẹ́ o mọ ohun tó ṣẹlẹ̀? Ṣe ni ọ̀pá yẹn di ejò! Nígbà tí Mósè di ìrù ejò náà mú, ó tún pa dà di ọ̀pá. Jèhófà wá sọ pé: ‘Tí wọ́n bá rí ohun tó o ṣe yìí, wọ́n á gbà pé èmi ni mo rán ẹ.’

Mósè wá sọ pé: ‘Àmọ́ mi ò fi bẹ́ẹ̀ mọ ọ̀rọ̀ sọ.’ Jèhófà ṣèlérí fún un pé: ‘Màá jẹ́ kó o mọ ohun tí wàá sọ, màá sì ní kí Áárónì ẹ̀gbọ́n ẹ ràn ẹ́ lọ́wọ́.’ Ọkàn Mósè wá balẹ̀ pé Jèhófà wà pẹ̀lú òun. Torí náà, òun, ìyàwó ẹ̀ àtàwọn ọmọ ẹ̀ pa dà sílẹ̀ Íjíbítì.

“Ẹ má ṣàníyàn nípa bí ẹ ṣe máa sọ̀rọ̀ àti ohun tí ẹ máa sọ, torí a máa fún yín ní ohun tí ẹ máa sọ ní wákàtí yẹn.”​—Mátíù 10:19

Ìbéèrè: Kí ni Mósè rí nígbà tó ń tọ́jú àwọn àgùntàn ẹ̀ nítòsí Òkè Sínáì? Iṣẹ́ wo ni Jèhófà fẹ́ rán Mósè?

Ẹ́kísódù 3:1–4:20; Ìṣe 7:30-36

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́