ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 69 ojú ìwé 164-ojú ìwé 165 ìpínrọ̀ 2
  • Áńgẹ́lì Gébúrẹ́lì Lọ Sọ́dọ̀ Màríà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Áńgẹ́lì Gébúrẹ́lì Lọ Sọ́dọ̀ Màríà
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Áńgẹ́lì Kan Bẹ Màríà Wò
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • A Bọla Fun Un Ṣaaju Ìbí Rẹ̀
    Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
  • Wọ́n Pọ́n Jésù Lé Kí Wọ́n Tó Bí I
    Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
  • “Wò Ó! Ẹrúbìnrin Jèhófà!”
    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Ìgbàgbọ́ Wọn
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 69 ojú ìwé 164-ojú ìwé 165 ìpínrọ̀ 2
Áńgẹ́lì Gébúrẹ́lì fara han Màríà

Ẹ̀KỌ́ 69

Áńgẹ́lì Gébúrẹ́lì Lọ Sọ́dọ̀ Màríà

Áńgẹ́lì kan fara hàn Jósẹ́fù nínú àlá

Èlísábẹ́tì ní mọ̀lẹ́bí kan tórúkọ ẹ̀ ń jẹ́ Màríà, tó ń gbé nílùú Násárẹ́tì nílẹ̀ Gálílì. Màríà àti Jósẹ́fù ń fẹ́ ara wọn sọ́nà, iṣẹ́ káfíńtà ni Jósẹ́fù ń ṣe. Nígbà tí oyún Èlísábẹ́tì pé oṣù mẹ́fà, áńgẹ́lì Gébúrẹ́lì lọ sọ́dọ̀ Màríà. Ó sọ pé: ‘Ṣé dáadáa ni, Màríà? Jèhófà ti fi ojú rere hàn sí ẹ.’ Ohun tí áńgẹ́lì náà ń sọ kò yé Màríà. Gébúrẹ́lì wá sọ fún un pé: ‘O máa lóyún, wàá bí ọmọkùnrin kan, wàá sì pe orúkọ ẹ̀ ní Jésù. Ó máa ṣàkóso bí Ọba. Ìjọba ẹ̀ ò sì ní lópin.’

Màríà wá sọ fún un pé: ‘Báwo ni mo ṣe máa bímọ, torí pé mi ò tíì ní ìbálòpọ̀ rí.’ Gébúrẹ́lì sọ pé: ‘Kò sóhun tí Jèhófà ò lè ṣe. Ẹ̀mí mímọ́ máa bà lé ẹ, wàá sì bí ọmọkùnrin kan. Èlísábẹ́tì mọ̀lẹ́bí rẹ náà ti lóyún.’ Lẹ́yìn náà Màríà sọ pé: ‘Ẹrúbìnrin Jèhófà ni mo jẹ́. Kó ṣẹlẹ̀ sí mi bí o ṣe sọ.’

Jósẹ́fù fẹ́ Màríà bó tiẹ̀ jẹ́ pé ó ti lóyún

Màríà wá rìnrìn àjò lọ sọ́dọ̀ Èlísábẹ́tì. Nígbà tí Màríà kí i, Èlísábẹ́tì mọ̀ ọ́n lára pé ọmọ inú òun mira. Ẹ̀mí mímọ́ sì mú kí Èlísábẹ́tì sọ pé: ‘Màríà, Jèhófà ti bù kún ọ. Ojú rere ńlá ló jẹ́ fún mi pé ìyá Olúwa mi wá sílé mi.’ Màríà sì sọ pé: ‘Mo fi gbogbo ọkàn mi yin Jèhófà.’ Màríà dúró sọ́dọ̀ Èlísábẹ́tì fún oṣù mẹ́tà, lẹ́yìn náà, ó pa dà sílé ẹ̀ ní Násárẹ́tì.

Nígbà tí Jósẹ́fù gbọ́ pé Màríà ti lóyún, ó fẹ́ kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Àmọ́, áńgẹ́lì kan yọ sí i lójú àlá, ó sì sọ fún un pé: ‘Má bẹ̀rù láti gbé Màríà níyàwó. Kò ṣe ohun kankan tó burú.’ Torí náà, Jósẹ́fù gbé Màríà níyàwó, ó sì mú un wá sílé ẹ̀.

“Jèhófà ń ṣe gbogbo ohun tó bá fẹ́ ní ọ̀run àti ní ayé.”​—Sáàmù 135:6

Ìbéèrè: Kí ni Gébúrẹ́lì sọ fún Màríà nípa ọmọkùnrin tó máa bí? Báwo lohun tó ṣẹlẹ̀ sí Màríà àti Èlísábẹ́tì ṣe rí lára wọn?

Mátíù 1:18-25; Lúùkù 1:26-56; Àìsáyà 7:14; 9:7; Dáníẹ́lì 2:44; Gálátíà 4:4

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́