ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 75 ojú ìwé 178-ojú ìwé 179 ìpínrọ̀ 4
  • Èṣù Dán Jésù Wò

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Èṣù Dán Jésù Wò
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • A Gbọ́dọ̀ Kọ Ìdẹwò
    Kẹ́kọ̀ọ́ Lọ́dọ̀ Olùkọ́ Ńlá Náà
  • “Ẹ Kọ Ojú Ìjà sí Èṣù” bí Jésù Ti Ṣe
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Kẹ́kọ̀ọ́ Látinú Bí Jésù Ṣe Kojú Àdánwò
    Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
  • Kikẹkọọ Lati Inu Awọn Ìdẹwò Jesu
    Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 75 ojú ìwé 178-ojú ìwé 179 ìpínrọ̀ 4
Jésù kọ̀ láti bẹ́ sílẹ̀ láti ibi tó ga jù ní tẹ́ńpìlì

Ẹ̀KỌ́ 75

Èṣù Dán Jésù Wò

Jésù kọ̀ láti sọ òkúta di búrẹ́dì

Lẹ́yìn tí Jésù ṣèrìbọmi, ẹ̀mí mímọ́ darí ẹ̀ lọ sí aginjù. Jésù ò jẹ nǹkan kan fún ogójì (40) ọjọ́, ebi wá ń pa á gan-an. Bí Èṣù ṣe wá dán an wò nìyẹn, ó sọ fún Jésù pé: ‘Tó bá jẹ́ pé Ọmọ Ọlọ́run ni ẹ́ lóòótọ́, sọ fáwọn òkúta yìí pé kí wọ́n di búrẹ́dì.’ Àmọ́, Jésù fi ohun tó wà nínú Ìwé Mímọ́ dá a lóhùn, ó sọ pé: ‘A ti kọ ọ́ pé kì í ṣe oúnjẹ nìkan ló máa jẹ́ ká wà láàyè. A gbọ́dọ̀ máa fetí sí gbogbo ohun tí Jèhófà bá sọ.’

Lẹ́yìn ìyẹn, Èṣù tún sọ fún un pé: ‘Tó o bá jẹ́ Ọmọ Ọlọ́run lóòótọ́, bẹ́ sílẹ̀ láti ibi tó ga jù ní tẹ́ńpìlì yìí. Torí a ti kọ ọ́ pé Ọlọ́run á rán àwọn áńgẹ́lì ẹ̀ láti gbé ọ, kó o má bàa ṣubú.’ Jésù tún fi Ìwé Mímọ́ dá a lóhùn, ó sọ pé: ‘A ti kọ ọ́ pé, o ò gbọ́dọ̀ dán Jèhófà Ọlọ́run rẹ wò.’

Jésù kọ̀ láti tẹ́wọ́ gba gbogbo ìjọba ayé tí Sátánì fẹ́ fún un

Lẹ́yìn ìyẹn, Sátánì tún fi gbogbo ìjọba ayé yìí han Jésù, àti gbogbo ọrọ̀ àti ògo tó wà láyé, ó wá sọ fún un pé: ‘Màá fún ẹ ní gbogbo nǹkan yìí tó o bá jọ́sìn mi lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo.’ Jésù wá sọ fún Sátánì pé: ‘Kúrò lọ́dọ̀ mi, Sátánì! Torí a ti kọ ọ́ pé, Jèhófà Ọlọ́run nìkan lo gbọ́dọ̀ jọ́sìn.’

Èṣù kúrò lọ́dọ̀ Jésù, lẹ́yìn náà àwọn áńgẹ̀lì wá sọ́dọ̀ Jésù, wọ́n sì fún un lóúnjẹ. Látìgbà yẹn ni Jésù ti ń wàásù ìhìn rere nípa Ìjọba Ọlọ́run. Iṣẹ́ tí Jèhófà ní kí Jésù wá ṣe láyé nìyẹn. Àwọn èèyàn nífẹ̀ẹ́ ẹ̀kọ́ tí Jésù ń kọ́ wọn, torí náà gbogbo ibi tí Jésù bá ń lọ làwọn èèyàn máa ń tẹ̀ lé e lọ.

‘Tí Èṣù bá ń pa irọ́, ṣe ló ń sọ irú ẹni tí òun fúnra rẹ̀ jẹ́, torí pé òpùrọ́ ni, òun sì ni baba irọ.’​—Jòhánù 8:44

Ìbéèrè: Ọ̀nà mẹ́ta wo ni Èṣù gbà dán Jésù wò? Báwo ni Jésù ṣe dá Èṣù lóhùn?

Mátíù 4:1-11; Máàkù 1:12, 13; Lúùkù 4:1-15; Diutarónómì 6:13, 16; 8:3; Jémíìsì 4:7

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́