ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • sjj orin 19
  • Oúnjẹ Alẹ́ Olúwa

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Oúnjẹ Alẹ́ Olúwa
  • “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Oúnjẹ Alẹ́ Olúwa
    Kọrin sí Jèhófà
  • Bá A Ṣe Lè Ṣe Ọ̀nà Wa Ní Rere
    Kọrin sí Jèhófà
  • Ìyanu Ni Ìwàláàyè Jẹ́
    Kọrin sí Jèhófà
  • Ìyanu Ni Ìwàláàyè Jẹ́
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
Àwọn Míì
“Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
sjj orin 19

ORIN 19

Oúnjẹ Alẹ́ Olúwa

Bíi Ti Orí Ìwé

(Mátíù 26:26-30)

  1. 1. Jèhófà, Bàbá wa ní ọ̀run,

    Alẹ́ mímọ́ jù lọ nìyí,

    Tó o pinnu láti fagbára àtìfẹ́ hàn

    Pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo.

    Ẹ̀jẹ̀ àgùntàn Ìrékọjá

    Lo fi gbàwọn èèyàn rẹ là.

    Alẹ́ yìí kan náà ni Kristi kú torí wa

    Kó lè mú àsọtẹ́lẹ̀ náà ṣẹ.

  2. 2. Búrẹ́dì tó wà níwájú wa

    Àti wáìnì ń rán wa létí

    Pé Jésù jólóòótọ́

    títí dójú ikú;

    Ohun ńlá lo san, Jèhófà.

    A ó máa ṣèrántí ikú Jésù.

    Alẹ́ yìí ń rán wa létí pé

    Ikú Ọmọ rẹ yìí

    lo fi rà wá pa dà.

    A moore ńlá tó o ṣe fún wa yìí.

  3. 3. O pè wá, a sì dá ọ lóhùn.

    A pé jọ ká lè jọ́sìn rẹ.

    O fìfẹ́ yọ̀ǹda Kristi

    Láti kú fún wa;

    A yìn ọ́, a yin Ọmọ rẹ.

    Ìrántí tá à ńṣe ńfògo fún ọ,

    Ó ń fún àwa náà nígbàgbọ́.

    A ó máa tẹ̀ lápẹẹrẹ tí Jésù fi lélẹ̀

    Ká lè rí ìyè àìnípẹ̀kun.

(Tún wo Lúùkù 22:​14-20; 1 Kọ́r. 11:​23-26.)

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́