ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w06 11/15 ojú ìwé 31
  • Kọ́ Àwọn Ọmọ Rẹ Bí Wọ́n Á Ṣe Máa Dáhùn Nípàdé

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kọ́ Àwọn Ọmọ Rẹ Bí Wọ́n Á Ṣe Máa Dáhùn Nípàdé
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2006
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Máa Yin Jèhófà Nínú Ìjọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2019
  • Ẹ Máa Gba Ara Yín Níyànjú Nípàdé Ìjọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
  • Ọ̀nà Wo Ló Dáa Jù Láti Gbà Múra Ìpàdé Ìjọ Sílẹ̀?
    Àwọn Wo Ló Ń Ṣe Ìfẹ́ Jèhófà Lóde Òní?
  • Ẹ Máa Gbé Ara Yín Ró Lẹ́nì Kìíní-Kejì Nípa Dídáhùn ní Àwọn Ìpàdé
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1998
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2006
w06 11/15 ojú ìwé 31

Kọ́ Àwọn Ọmọ Rẹ Bí Wọ́n Á Ṣe Máa Dáhùn Nípàdé

ỌMỌBÌNRIN kan tó ń jẹ́ Perla, tó wá láti ìlú Mẹ́síkò, rántí pé nígbà tóun wà ní kékeré, màmá òun máa ń kọ́ òun láti múra ìdáhùn ṣókí tóun máa dáhùn nígbà Ìkẹ́kọ̀ọ́ Ilé Ìṣọ́ sílẹ̀. Perla náà ti di ìyá báyìí, ọmọ rẹ̀ ọkùnrin sì ti pé ọdún márùn-ún. Báwo ló ṣe ń ran ọmọ náà lọ́wọ́? Ó sọ pé: “Màá kọ́kọ́ múra Ilé Ìṣọ́ náà sílẹ̀. Bí mo ṣe ń múra ẹ̀ sílẹ̀ ni màá máa fọkàn wá ìpínrọ̀ tó lè yé ọmọ mi, èyí táá lè fi ọ̀rọ̀ ara ẹ̀ ṣàlàyé. Lẹ́yìn ìyẹn la óò wá pọkàn pọ̀ sórí ìpínrọ̀ tó máa ń pè ní ‘ìpínrọ̀ mi.’ Mo máa ń sọ fún un pé kó ṣàlàyé ẹ̀ nípa lílo àpèjúwe tó bá mọ̀ pé ó rọrùn fóun. Lẹ́yìn náà la óò wá fi ìdáhùn náà dánra wò nígbà mélòó kan. Ó ní kiní kan tá a máa ń lò láti fi ṣe makirofóònù kó lè mọ bó ṣe máa gbé e dání bó bá ń dáhùn. Inú mi máa ń dùn gan-an pé kò sí ìpàdé náà tí kì í ti í dáhùn tàbí kó nawọ́ sókè. Lọ́pọ̀ ìgbà, á lọ bá olùdarí ìkẹ́kọ̀ọ́ kí ìpàdé tó bẹ̀rẹ̀ á sì sọ ìpínrọ̀ tó fẹ́ láti dáhùn fún un.”

Jens, alàgbà kan tó wà pẹ̀lú àwùjọ kan tó ń sọ èdè Hindi, ní ọmọkùnrin méjì, ọ̀kan jẹ́ ọmọ ọdún méjì, èkejì sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rin. Bí òun àti ìyàwó ẹ̀ bá ń múra ìpàdé sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ, ọgbọ́n kan tí Jens kọ́ lọ́dọ̀ àwọn òbí ẹ̀ ló máa ń lò. Ó sọ pé: “A máa wo ibi táwọn ọmọ á lè lóye nínú àpilẹ̀kọ náà. Lẹ́yìn náà la óò wá gbìyànjú láti ṣàlàyé ráńpẹ́ fún wọn lórí ọ̀rọ̀ tí àpilẹ̀kọ náà dá lé tàbí ká sọ àwọn kókó tó wà níbẹ̀ fún wọn, ká tó wá bi wọ́n láwọn ìbéèrè tá a ní lọ́kàn pé kí wọ́n dáhùn ní ìpàdé. Lọ́pọ̀ ìgbà, ìdáhùn tó tọkàn wọn wá tí wọ́n máa ń fún wa máa ń yà wá lẹ́nu. Ọ̀nà tí wọ́n máa ń gbà ṣàlàyé ara wọn máa ń jẹ́ ká mọ bí òye wọn ṣe tó. Nítorí èyí, ìdáhùn wọn máa ń fìyìn fún Jèhófà, ó sì jẹ́ ọ̀nà tí wọ́n ń gbà sọ̀rọ̀ nípa ohun tí wọ́n gbà gbọ́.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́