ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w08 9/1 ojú ìwé 24
  • Òye Jésù Ṣe Àwọn Tó Gbọ́rọ̀ Rẹ̀ Ní Kàyéfì

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Òye Jésù Ṣe Àwọn Tó Gbọ́rọ̀ Rẹ̀ Ní Kàyéfì
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Bí Sódómù àti Gòmórà Ṣe Pa Run
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Jésù Fi Iṣẹ́ Ìyanu Mú Àwọn Aláìsàn Lára Dá
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Jésù Borí Ìdẹwò
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
  • Pétérù Sẹ́ Jésù
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
w08 9/1 ojú ìwé 24

Abala Àwọn Ọ̀dọ́

Òye Jésù Ṣe Àwọn Tó Gbọ́rọ̀ Rẹ̀ Ní Kàyéfì

Ohun tó o máa ṣe: Ibi tí kò sáriwo ni kó o ti ṣe ìdánrawò yìí. Bó o ṣe ń ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó wà nísàlẹ̀ yìí, máa fojú inú wò ó pé o wà níbi tí ohun tó ò ń kà náà ti ṣẹlẹ̀, kó dà bíi pé ò ń gbọ́ báwọn èèyàn náà ṣe ń sọ̀rọ̀. Kó o sì máa fojú inú wò ó bí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lọ́wọ́lọ́wọ́.

KA ÌTÀN NÁÀ DÁADÁA.—KA LÚÙKÙ 2:41-47.

Tó o bá fojú inú wo ohun tí ẹsẹ kẹrìndínláàádọ́ta sọ, ọ̀rọ̀ kí lo rò pé Jésù àtàwọn olùkọ́ yẹn jọ ń sọ?

․․․․․

ṢÈWÁDÌÍ KÓ O SÌ RONÚ JINLẸ̀.

Kí lo rò pé ó jẹ́ kí Jésù lè bá àwọn olórí ẹ̀sìn yẹn sọ̀rọ̀ pa pọ̀ bó ṣe jẹ́ ọmọdé tó yẹn? Ṣé torí pé ó jẹ́ ẹni pípé ni, àbí ó tún nídìí míì tó fi rí bẹ́ẹ̀?

․․․․․

KA ÌTÀN NÁÀ DÁADÁA.—KA LÚÙKÙ 2:48-52.

Irú ìwà wo lo rò pé Jésù hù sáwọn òbí ẹ̀ nígbà tó béèrè lọ́wọ́ wọn pé: “Èé ṣe tí ẹ fi ní láti máa wá mi?”

․․․․․

Kí ló mú kó dá wa lójú pé Jésù kò fìbínú sọ̀rọ̀ sáwọn òbí ẹ̀ àti pé ó bọ̀wọ̀ fún wọn?

․․․․․

ṢÈWÁDÌÍ KÓ O SÌ RONÚ JINLẸ̀.

Kí nìdí tá a fi gbà pé Jósẹ́fù àti Màríà máa dààmú lóòótọ́?

․․․․․

Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni pípé ni Jésù, kí nìdí tó fi ń bá a lọ láti máa gbọ́ràn sáwọn òbí rẹ̀ lẹ́nu?

․․․․․

Ǹjẹ́ o ronú pé ó ṣeé ṣe kí ojú ti Jésù bí àwọn òbí rẹ̀ ṣe bá a wí lójú àwọn èèyàn tó fẹ́ràn rẹ̀?

․․․․․

MÁA FOHUN TÓ O KỌ́ ṢÈWÀ HÙ. ṢÀKỌSÍLẸ̀ Ẹ̀KỌ́ TÓ O KỌ́ NÍPA . . .

Jíjẹ́ ẹni tó ń tẹrí ba.

․․․․․

Bó ti ṣe pàtàkì tó pé kéèyàn kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì nígbà tó wà lọ́mọdé.

․․․․․

KÍ LÓ WÚ Ẹ LÓRÍ JÙ NÍNÚ ÌTÀN INÚ BÍBÉLÌ YÌÍ, KÍ SÌ NÌDÍ?

․․․․․

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́