ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w09 4/1 ojú ìwé 8-9
  • Báwo Lèèyàn Ṣe Lè Di Àtúnbí?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Báwo Lèèyàn Ṣe Lè Di Àtúnbí?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tí “Omi àti Ẹ̀mí” Túmọ̀ Sí Gan-an
  • Ṣe Batisí Nípasẹ̀ “Ẹ̀mí Mímọ́”
  • Batisí Méjì Ló Ń Sọ Èèyàn Di Àtúnbí
  • ‘Ni Orukọ Ẹmi Mímọ́’
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1992
  • Kí Ni Ìrìbọmi Túmọ̀ Sí?
    Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ìtumọ̀ Ìrìbọmi Tó O Ṣe
    Jọ́sìn Ọlọ́run Tòótọ́ Kan Ṣoṣo Náà
  • Máa Rìn Nípa Ẹ̀mí Kó O Sì Mú Ẹ̀jẹ́ Ìyàsímímọ́ Rẹ Ṣẹ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
w09 4/1 ojú ìwé 8-9

Báwo Lèèyàn Ṣe Lè Di Àtúnbí?

YÀTỌ̀ sí pé Jésù jẹ́ kí Nikodémù mọ bí dídi àtúnbí ṣe ṣe pàtàkì tó, tó jẹ́ kó mọ ohun tó máa jẹ́ kéèyàn di àtúnbí, tó sì jẹ́ kó mọ ìdí tó fi yẹ káwọn kan di àtúnbí, ó tún jẹ́ kó mọ béèyàn ṣe lè di àtúnbí. Jésù sọ pé: “Láìjẹ́ pé a bí ẹnikẹ́ni láti inú omi àti ẹ̀mí kò lè wọ ìjọba Ọlọ́run.” (Jòhánù 3:5) Torí náà, omi àti ẹ̀mí ló ń sọ ẹnì kan di àtúnbí. Àmọ́, kí ni “omi àti ẹ̀mí” túmọ̀ sí gan-an?

Ohun Tí “Omi àti Ẹ̀mí” Túmọ̀ Sí Gan-an

Torí pé ọ̀mọ̀wé ẹlẹ́kọ̀ọ́ ìsìn Júù ni Nikodémù, ó dájú pé ó ti ní láti mọ bí Ìwé Mímọ́ lédè Hébérù ṣe máa ń sọ̀rọ̀ nípa “ẹ̀mí Ọlọ́run,” ìyẹn agbára ìṣiṣẹ́ tí Ọlọ́run lè fi mú káwọn èèyàn ṣe ohun kan tí kò ṣeé ṣe lójú lásán. (Jẹ́nẹ́sísì 41:38; Ẹ́kísódù 31:3; 1 Sámúẹ́lì 10:6) Torí náà, nígbà tí Jésù mẹ́nu ba “ẹ̀mí,” ó ti máa yé Nikodémù pé ọ̀rọ̀ nípa ẹ̀mí mímọ́, ìyẹn agbára ìṣiṣẹ́ Ọlọ́run, ni Jésù ń sọ.

Omi tí Jésù wá sọ ńkọ́? Kíyè sáwọn ohun tí Bíbélì sọ pó ṣẹlẹ̀ ṣáájú kí Nikodémù tó wá bá Jésù àti lẹ́yìn tí wọ́n jọ sọ̀rọ̀ tán. Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé Jòhánù Olùbatisí àtàwọn ọmọlẹ́yìn Jésù ń batisí àwọn èèyàn nínú omi. (Jòhánù 1:19, 31; 3:22; 4:1-3) Nílùú Jerúsálẹ́mù, ọ̀pọ̀ ló mọ̀ pé ó yẹ́ kéèyàn ṣe batisí nínú omi. Torí náà, nígbà tí Jésù sọ̀rọ̀ nípa omi, Nikodémù á ti fòye gbé e pé omi tí wọ́n fi ń ṣe batisí ni Jésù ń sọ, kì í kàn ṣe omi lásán.a

Ṣe Batisí Nípasẹ̀ “Ẹ̀mí Mímọ́”

Tí bíbí ẹnì kan “láti inú omi” bá túmọ̀ sí kéèyàn ṣe batisí nínú omi, kí ló wá túmọ̀ sí láti bí ẹnì kan ‘látinú ẹ̀mí’? Kó tó di pé Nikodémù lọ bá Jésù nílé, Jòhánù Olùbatisí ti sọ fáwọn èèyàn pé yàtọ̀ sí omi, ẹ̀mí tún máa nípa tó ń kó nínú batisí. Ó sọ pé: “Èmi fi omi batisí yín, ṣùgbọ́n [Jésù] yóò fi ẹ̀mí mímọ́ batisí yín.” (Máàkù 1:7, 8) Máàkù tóun náà kọ lára ìwé Ìhìn Rere sọ ohun tó ṣẹlẹ̀ nígbà àkọ́kọ́ tírú batisí bẹ́ẹ̀ wáyé. Ó sọ pé: “Ó sì ṣe ní ọjọ́ wọnnì, Jésù wá láti Násárétì ti Gálílì, Jòhánù sì batisí rẹ̀ nínú Jọ́dánì. Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, bí ó ti ń jáde sókè kúrò nínú omi, ó rí tí ọ̀run ń pínyà, àti pé, bí àdàbà, ẹ̀mí bà lé e.” (Máàkù 1:9, 10) Nígbà tí Jésù ṣèrìbọmi lódò Jọ́dánì, ó ṣe batisí nínú omi. Àmọ́, ó ṣe batisí nípasẹ̀ ẹ̀mí mímọ́ nígbà tí ẹ̀mí láti ọ̀run bà lé e.

Ní nǹkan bí ọdún mẹ́ta lẹ́yìn tí Jésù ṣe batisí, ó jẹ́ kó dá àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ lójú pé: “A ó batisí [wọn] nínú ẹ̀mí mímọ́ ní ọjọ́ tí kò ní pẹ́ púpọ̀ lẹ́yìn èyí.” (Ìṣe 1:5) Ìgbà wo nìyẹn ṣẹlẹ̀?

Ní Pẹ́ńtíkọ́sì ọdún 33 Sànmánì Kristẹni, nǹkan bí ọgọ́fà [120] ọmọ ẹ̀yìn Jésù kora jọ sílé kan ní Jerúsálẹ́mù. Bíbélì ròyìn pé: “Lójijì, ariwo kan dún láti ọ̀run gan-an gẹ́gẹ́ bí ti atẹ́gùn líle tí ń rọ́ yìì, ó sì kún inú gbogbo ilé tí wọ́n jókòó sí. Àwọn ahọ́n bí ti iná sì di rírí fún wọn . . . , gbogbo wọ́n sì wá kún fún ẹ̀mí mímọ́.” (Ìṣe 2:1-4) Lọ́jọ́ yẹn kan náà ni àpọ́sítélì Pétérù rọ àwọn èèyàn tó wà ní Jerúsálẹ́mù láti ṣe batisí nínú omi. Àpọ́sítélì Pétérù sọ fáwọn tó ń bá sọ̀rọ̀ pé: “Ẹ ronú pìwà dà, kí a sì batisí olúkúlùkù yín ní orúkọ Jésù Kristi fún ìdáríjì àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì gba ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ ẹ̀mí mímọ́.” Kí làwọn èèyàn náà ṣe? Bíbélì sọ pé: “Àwọn tí wọ́n fi tọkàntọkàn gba ọ̀rọ̀ rẹ̀ ni a batisí, ní ọjọ́ yẹn nǹkan bí ẹgbẹ̀ẹ́dógún [3,000] ọkàn ni a sì fi kún wọn.”—Ìṣe 2:38, 41.

Batisí Méjì Ló Ń Sọ Èèyàn Di Àtúnbí

Kí làwọn batisí méjèèjì yìí jẹ́ ká mọ̀ nípa dídi àtúnbí? Wọ́n jẹ́ ká mọ̀ pé èèyàn ní láti ṣe batisí méjì kó tó lè di àtúnbí. Kíyè sí i pé Jésù kọ́kọ́ ṣe batisí nínú omi. Lẹ́yìn náà ló tó wa gba ẹ̀mí mímọ́. Bákan náà, àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù ti kọ́kọ́ ṣe batisí nínú omi (Jòhánù Olùbatisí ló batisí àwọn kan), lẹ́yìn ìgbà yẹn ni wọ́n tó wá gba ẹ̀mí mímọ́. (Jòhánù 1:26-36) Àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́ta [3,000] èèyàn tí wọ́n wá di ọmọ ẹ̀yìn nígbà tó yá náà kọ́kọ́ ṣe batisí nínú omi, lẹ́yìn náà wọ́n gba ẹ̀mí mímọ́.

Tá a bá ronú lórí batisí tó wáyé nígbà Pẹ́ńtíkọ́sì ọdún 33 Sànmánì Kristẹni, a lè béèrè pé, báwo lèèyàn ṣe lè di àtúnbí lóde òní? Bó ṣe ṣẹlẹ̀ sáwọn ọmọlẹ́yìn Jésù àtàwọn míì tó dọmọ ẹ̀yìn nígbà yẹn náà ló ṣe máa rí. Onítọ̀hún máa kọ́kọ́ ronú pìwà dà àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ó máa jáwọ nínú ìwà búburú, ó máa ya ìgbésí ayé ara ẹ̀ sí mímọ́ fún Jèhófà láti máa jọ́sìn rẹ̀ àti láti máa ṣiṣẹ́ sìn ín, ó sì máa wá jẹ́ kí gbogbo èèyàn mọ̀ pé òun ti ya ara òun sí mímọ́ nípa ṣíṣe batisí nínú omi. Lẹ́yìn náà, tí Ọlọ́run bá yan onítọ̀hún láti jọba nínú Ìjọba ọ̀run, Ọlọ́run á fi ẹ̀mí mímọ́ yàn án. Kálukú ló máa pinnu láti ṣe apá àkọ́kọ́ (ìyẹn batisí nínú omi), àmọ́ Ọlọ́run ló máa pinnu apá kéji (ìyẹn batisí nínú ẹ̀mí). Tẹ́nì kan bá ṣe batisí méjèèjì, onítọ̀hún ti di àtúnbí nìyẹn.

Kí wá nìdí tí Jésù fi sọ fún Nikodémù pé “láìjẹ́ pé a bí ẹnikẹ́ni láti inú omi àti ẹ̀mí kò lè wọ ìjọba Ọlọ́run”? Ó fẹ́ ko ṣe kedere pé ìyípadà pàtàkì ló máa wáyé nígbésí ayé àwọn tó bá ṣe batisí nínú omi àti nípasẹ̀ ẹ̀mí. Àpilẹ̀kọ tó kàn báyìí máa sọ̀rọ̀ nípa ìyípadà pàtàkì yìí.

[Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]

a Nígbà kan, àpọ́sítélì Pétérù náà sọ ohun kan tó jọ èyí níbi batisí kan, ó ní: “Ẹnikẹ́ni ha lè ka omi léèwọ̀?”—Ìṣe 10:47.

[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 9]

Jòhánù fi omi batisí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tó ti ronú pìwà dà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́