ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w14 3/1 ojú ìwé 16
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Kí Nìdí Tí Jésù Fi Jìyà Tó sì Kú?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2016
  • Ìbéèrè Kejì: Kí Ló Máa Ṣẹlẹ̀ sí Mi Nígbà Tí Mo Bá Kú?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2012
  • Ikú àti Àjíǹde Jésù—Àǹfààní Tó Ṣe fún Ẹ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
w14 3/1 ojú ìwé 16
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 16]

OHUN TÍ BÍBÉLÌ SỌ

Àǹfààní wo ni ikú Jésù ṣe fún wa?

Nígbà tí Ọlọ́run dá èèyàn, ohun tó ní lọ́kàn ni pé kí wọ́n máa gbádùn títí láé lórí ilẹ̀ ayé láìsí àìsàn àti ikú. Ṣùgbọ́n, Ádámù tó jẹ́ èèyàn àkọ́kọ́ tí Ọlọ́run dá ṣàìgbọràn sí Ẹlẹ́dàá, bó ṣe pàdánù àǹfààní láti wà láàyè títí láé nìyẹn. Nítorí pé àtọmọdọ́mọ Ádámù ni wá, a ti jogún ikú láti ọ̀dọ̀ rẹ̀. (Róòmù 5:8, 12; 6:23) Jèhófà, Ọlọ́run tòótọ́ náà, wá rán Jésù Ọmọ rẹ̀ wá sáyé láti fi ikú rẹ̀ ra ohun ti Ádámù pàdánù pa dà.—Ka Jòhánù 3:16.

Jésù kú kí àwa èèyàn lè gbádùn ìyè ayérayé. Ronú nípa bí ìgbésí ayé ṣe máa rí nígbà tí a bá wà láàyè títí láé

Ikú Jésù ló mú kí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ wa àti ìrètí láti wà láàyè títí láé ṣeé ṣe. Bíbélì sọ bí ìgbésí ayé ṣe máa rí lórí ilẹ̀ ayé nígbà tí àìsàn, ọjọ́ ogbó àti ikú kò bá sí mọ́.—Ka Aísáyà 25:8; 33:24; Ìṣípayá 21:4, 5.

Báwo ló ṣe yẹ ká máa rántí ikú Jésù?

Ní alẹ́ tó ṣáájú ikú Jésù, ó sọ fún àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ pé kí wọ́n máa fi ètò ráńpẹ́ kan rántí ikú òun. Bá a ṣe ń rántí ikú Jésù lọ́nà yìí ní ọdọọdún máa ń jẹ́ ká lè ronú jinlẹ̀ nípa bí Jésù àti Jèhófà ṣe nífẹ̀ẹ́ wa tó.—Ka Lúùkù 22:19, 20; 1 Jòhánù 4:9, 10.

Ọjọ́ Monday, April 14 ní a máa ṣe Ìrántí ikú Jésù lọ́dún yìí, lẹ́yìn tí oòrùn bá ti wọ̀. A ké sí ọ́ pé kó o dara pọ̀ mọ́ àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà tó wà ládùúgbò rẹ̀.—Ka Róòmù 1:11, 12.

Tó o bá fẹ́ ìsọfúnni síwájú sí i, ka orí 4 àti 5 nínú ìwé yìí Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an? Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é

O lè wà á jáde lórí at www.jw.org/yo

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́