ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 7/97 ojú ìwé 1
  • A San Èrè fún Ìṣòtítọ́

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • A San Èrè fún Ìṣòtítọ́
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ǹjẹ́ Ò Ń Ṣe Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Láṣeyanjú?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2019
  • Jèhófà Máa Ń Sẹ̀san fún Àwọn Tó Ń Fi Taratara Wá A
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016
  • Bá A Ṣe Lè Túbọ̀ Tẹra Mọ́ Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Wa
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Ǹjẹ́ o Máa Ń ṣòótọ́ Nínú Gbogbo Nǹkan?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
km 7/97 ojú ìwé 1

A San Èrè fún Ìṣòtítọ́

1 Ní Hébérù 11:6, a sọ fún wa pé Ọlọ́run “di olùsẹ̀san fún àwọn wọnnì tí ń fi taratara wá a.” Ọ̀nà kan tí ó gbà ń san èrè fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ olùfọkànsìn tí wọ́n ti jẹ́ ‘olùṣòtítọ́ nínú ìwọ̀nba ohun díẹ̀’ ni nípa ‘yíyàn wọ́n sípò lórí ohun púpọ̀.’ (Mát. 25:23) Lédè míràn, Jèhófà sábà máa ń san èrè fún iṣẹ́ aláápọn nípa fífún àwọn ẹlẹ́rìí rẹ̀ olùṣòtítọ́ ní àfikún ẹrù iṣẹ́ ìsìn.

2 A san èrè fún ìṣòtítọ́ àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù nípa yíyàn án sẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ tí ó mú kí ó lọ sí àwọn ìlú àti abúlé tí ó wà ní Europe àti Éṣíà Kékeré. (1 Tím. 1:12) Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ṣíṣàṣeparí iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ lẹ́kùn-ún rẹ́rẹ́ gba ìsapá púpọ̀, Pọ́ọ̀lù fọwọ́ daindain mú àǹfààní tí ó rí gbà. (Róòmù 11:13; Kól. 1:25) Ó fi ìmọrírì rẹ̀ àtọkànwá hàn nípa wíwá àǹfààní taratara láti wàásù. Nípasẹ̀ iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ onítara, ó fi ìgbàgbọ́ rẹ̀ hàn kedere nípa iṣẹ́. Àpẹẹrẹ rẹ̀ ń sún wa láti máa ṣìkẹ́ àwọn àǹfààní iṣẹ́ ìsìn tí a ní.

3 Jèhófà Ti Fún Wa Ní Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kan: Báwo ni a ṣe ń fi ojú ìwòye kan náà hàn nípa àǹfààní iṣẹ́ ìsìn yí bí Pọ́ọ̀lù ti fi hàn? A ń wá ọ̀nà láti mú kí ipa tí a ń kó nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ pọ̀ sí i. A ń lo gbogbo àǹfààní tí ó bá ṣí sílẹ̀ láti jẹ́rìí láìjẹ́ bí àṣà àti láti ilé dé ilé. A ń pa dà sọ́dọ̀ gbogbo ẹni tí kò bá sí nílé, a sì ń ṣe ìpadàbẹ̀wò sọ́dọ̀ gbogbo ẹni tí ó bá fi ọkàn ìfẹ́ hàn. A sì ń pa àdéhùn tí a bá ṣe mọ́ láti darí àwọn ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì inú ilé.

4 Ní ti iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa, Pọ́ọ̀lù gbà wá nímọ̀ràn pé: ‘Ẹ wà lẹ́nu rẹ̀ ní kánjúkánjú.’ (2 Tím. 4:2) Ohun kan tí ó jẹ́ kánjúkánjú ń béèrè fún àfiyèsí lọ́gán. A ha ń ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa lọ́nà tí ó fi ìjẹ́kánjúkánjú hàn, ní fífún un ní ipò àkọ́kọ́ nínú ìgbésí ayé wa bí? Fún àpẹẹrẹ, a kì yóò fẹ́ kí àwọn ìgbòkègbodò eré ìtura wa àti àwọn ìlépa ti ara ẹni mìíràn ní òpin ọ̀sẹ̀ ṣèdíwọ́ fún àkókò tí ó yẹ kí a yà sọ́tọ̀ fún iṣẹ́ òjíṣẹ́ pápá. Níwọ̀n bí ó ti dá wa lójú pé òpin ètò ìgbékalẹ̀ nǹkan yìí ń yára sún mọ́lé, ó dá wa lójú pẹ̀lú pé wíwàásù ìhìn rere Ìjọba náà ni iṣẹ́ tí ó ṣe pàtàkì jù lọ tí a lè ṣe.

5 A ń fi ìṣòtítọ́ wa sí Ọlọ́run hàn nípa jíjẹ́ tí a jẹ́ adúróṣinṣin àti aláìyẹhùn sí i àti nípa dídúró tí a dúró gangan nínú iṣẹ́ tí òun ti yàn fún wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣàṣeparí iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa lẹ́kùn-ún rẹ́rẹ́, kí Jèhófà baà lè san èrè fún ìṣòtítọ́ wa lọ́nà púpọ̀ jaburata.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́