ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 10/01 ojú ìwé 8
  • Ǹjẹ́ O Máa Ń Jẹ Oúnjẹ Tẹ̀mí Dáadáa?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ O Máa Ń Jẹ Oúnjẹ Tẹ̀mí Dáadáa?
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìwọ Ha Ń Jẹun Kánú Nípa Tẹ̀mí Bí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
  • Báwo Ni Mo Ṣe Lè Máa Jẹ Oúnjẹ Tó Ṣara Lóore?
    Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé
  • Ṣé Ò Ń Rí Oúnjẹ Gbà “Ní Àkókò Tí Ó Bẹ́tọ̀ọ́ Mu”?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Ríra Àkókò Padà Láti Kàwé Àti Láti Kẹ́kọ̀ọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
km 10/01 ojú ìwé 8

Ǹjẹ́ O Máa Ń Jẹ Oúnjẹ Tẹ̀mí Dáadáa?

1 Wọ́n máa ń sọ pé ‘oúnjẹ lọ̀rẹ́ àwọ̀.’ Òótọ́ ni. Bí okun àti ìlera wa ṣe rí wà lọ́wọ́ bá a ṣe ń jẹun sí. Níwọ̀n bí Jésù ti sọ pé: “Ènìyàn kì yóò wà láàyè nípasẹ̀ oúnjẹ nìkan ṣoṣo, bí kò ṣe nípasẹ̀ gbogbo àsọjáde tí ń jáde wá láti ẹnu Jèhófà,” ó fi hàn pé bá a ṣe ń jẹun sí nípa tẹ̀mí ń ní ipa lórí wa sí rere tàbí sí búburú. (Mát. 4:4) Nítorí náà, báwo lo ṣe ń jẹ oúnjẹ tẹ̀mí tẹ́rùn tó? Ṣé ńṣe lo máa ń ṣa oúnjẹ jẹ? Ṣé ńṣe lo máa ń kánjú jẹ ẹ́? Àbí inú rẹ máa ń dùn láti fara balẹ̀ jẹ oúnjẹ tẹ̀mí tó dọ́ṣọ̀, tí ń ṣara lóore tí o sì ń jẹ ẹ́ déédéé?

2 Gbé Bí O Ṣe Ń Jẹun Yẹ̀ Wò: Jèhófà ń tipasẹ̀ “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” pèsè ‘oúnjẹ ní àkókò tí ó bẹ́tọ̀ọ́ mu’ àti “àkànṣe àsè tí ó jẹ́ oúnjẹ tí a fi òróró dùn.” (Mát. 24:45; Aísá. 25:6) Láti máa jàǹfààní ní kíkún látinú àwọn ohun tó ń fìfẹ́ pèsè yìí, a gbọ́dọ̀ sapá gan-an láti máa jẹ oúnjẹ tẹ̀mí dáadáa.

3 O lè bi ara rẹ léèrè pé: ‘Ṣé mo máa ń ka ẹsẹ ojoojúmọ́ àti àlàyé rẹ̀ lójoojúmọ́? Ṣé mo máa ń ka Bíbélì tí mo sì máa ń ronú lórí rẹ̀ lójoojúmọ́? Ṣé mo máa ń múra àwọn ìpàdé ìjọ nípa kíka àwọn ohun tí a óò gbọ́ níbẹ̀ ṣáájú àkókò? Ǹjẹ́ mo ti ka àwọn ìtẹ̀jáde wa tó dé kẹ́yìn, títí kan Apá Kìíní ìwé Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé?’

4 Jésù ṣèlérí pé: “Aláyọ̀ ni àwọn tí àìní wọn nípa ti ẹ̀mí ń jẹ lọ́kàn . . . Aláyọ̀ ni àwọn tí ebi ń pa, tí òùngbẹ sì ń gbẹ fún òdodo, níwọ̀n bí a ó ti bọ́ wọn yó.” (Mát. 5:3, 6) Nítorí náà, máa jẹ oúnjẹ tẹ̀mí dáadáa nípa fífi ìmọ̀ Ọlọ́run kún inú àti ọkàn rẹ.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́