ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 7/05 ojú ìwé 1
  • Gbèsè Tá A Jẹ Àwọn Èèyàn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Gbèsè Tá A Jẹ Àwọn Èèyàn
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tí Ẹ Lè Ṣe Nípa Gbèsè
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2012
  • Ǹjẹ́ Bíbélì Lè Ràn Mí Lọ́wọ́ Tí Mo Bá Ní Ìṣòro Owó Tàbí Tí Mo Bá Jẹ Gbèsè?
    Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Kí Ni Ṣíṣe Bá Ò Bá Bá Àwọn Kan Nílé?
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Kí Nìdí Tí Iṣẹ́ Ìwàásù Ilé-dé-Ilé Fi Ṣe Pàtàkì Nísinsìnyí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
km 7/05 ojú ìwé 1

Gbèsè Tá A Jẹ Àwọn Èèyàn

1 Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù rí i pé dandan ni kóun wàásù fáwọn èèyàn. Ó mọ̀ dájú pé Jèhófà ti ṣe ohun tó lè mú kí onírúurú èèyàn rí ìgbàlà nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ ṣíṣeyebíye ti Ọmọkùnrin Rẹ̀ ọ̀wọ́n. (1 Tím. 2:3-6) Ìdí nìyẹn tó fi sọ pé: “Èmi jẹ́ ajigbèsè sí àwọn Gíríìkì àti àwọn Aláìgbédè, sí àwọn ọlọ́gbọ́n àti àwọn òpònú.” Látàrí èyí, Pọ́ọ̀lù fi ìháragàgà àti àìṣàárẹ̀ ṣiṣẹ́ kára kó lè san gbèsè tó jẹ àwọn èèyàn nípa wíwàásù ìhìn rere fún wọn.—Róòmù 1:14, 15.

2 Bíi ti Pọ́ọ̀lù, àwọn Kristẹni òde òní náà ń lo gbogbo àǹfààní tí wọ́n bá ní láti wàásù ìhìn rere fáwọn aládùúgbò wọn. Bí “ìpọ́njú ńlá” ṣe ń yára sún mọ́lé yìí, ó túbọ̀ jẹ́ kánjúkánjú fún wa láti wá àwọn olóòótọ́ èèyàn rí. Ǹjẹ́ kí ojúlówó ìfẹ́ tá a ní fáwọn èèyàn sún wa láti máa fi taratara ṣiṣẹ́ ìgbẹ̀mílà yìí.—Mát. 24:21; Ìsík. 33:8.

3 Bá A Ó Ṣe Máa San Gbèsè Náà: Ọ̀nà pàtàkì tá à ń gbà mú ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ àwọn èèyàn lọ ni nípasẹ̀ ìwàásù ilé-dé-ilé. Láwọn ìpínlẹ̀ ìwàásù táwọn èèyàn kì í bá ti í sí nílé, ohun tá a lè ṣe tí a ó fi lè máa bá àwọn tó pọ̀ nílé ni pé ká kọ àkọsílẹ̀ tó kún rẹ́rẹ́, ká sì máa padà lọ síbẹ̀ lásìkò ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. (1 Kọ́r. 10:33) A tún lè ráwọn èèyàn bá sọ̀rọ̀ tá a bá ń wàásù láwọn ibi táwọn èèyàn ti ń ṣiṣẹ́ ajé, láwọn òpópónà, láwọn ibi ìgbafẹ́, níbi táwọn èèyàn pọ̀ sí, láwọn ibi ìgbọ́kọ̀sí àti nípa lílo fóònù. A wá lè bi ara wa pé, ‘Ǹjẹ́ mò ń sa gbogbo ipá mi láti lo gbogbo ọ̀nà tó bá ṣeé ṣe láti wá àwọn èèyàn rí kí n bàa lè máa wàásù ọ̀rọ̀ ìyè fún wọn?’—Mát. 10:11.

4 Arábìnrin aṣáájú ọ̀nà kan rí i pé ojúṣe òun ni láti mọ bóun ṣe máa wá gbogbo èèyàn tó wà ní ìpínlẹ̀ ìwàásù òun rí. Ilé kan wà tí wíńdò rẹ̀ máa ń wà ní títì pa ní gbogbo ìgbà tí kì í sì í sẹ́nì kankan níbẹ̀. Àmọ́, lọ́jọ́ kan tí aṣáájú ọ̀nà yẹn ò lọ sóde ẹ̀rí, ó gba iwájú ilé tó sábà máa ń wà ní títì pa náà kọjá, ó sì rí ọkọ̀ ayọ́kẹ́lẹ́ kan níwájú ilé náà. Torí pé kò fẹ́ kí àǹfààní yẹn kọjá lọ, ó yà síbẹ̀ ó sì tẹ aago ẹnu ọ̀nà ilé náà. Ọkùnrin kan ló dáhùn, ìfèròwérò tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ lọ́jọ́ yẹn sì mú kí aṣáájú ọ̀nà yẹn àtọkọ rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìpadàbẹ̀wò sọ́dọ̀ ọkùnrin náà léraléra. Lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ ọ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Bá a sì ṣe ń sọ̀rọ̀ yìí, ó ti ṣèrìbọmi, ó sì ti di arákùnrin wa. Ó lóun dúpẹ́ pé arábìnrin yẹn ka iṣẹ́ ìwàásù sí gbèsè tó gbọ́dọ̀ san fáwọn èèyàn.

5 Níwọ̀n bí àkókò ò ti dúró de ẹnì kan, àsìkò tá a wà yìí gan-an la gbọ́dọ̀ san gbèsè tá a jẹ àwọn èèyàn nípa fífi gbogbo ara ṣiṣẹ́ ìwàásù náà.—2 Kọ́r. 6:1, 2.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́