ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 12/09 ojú ìwé 1
  • Wàásù Pẹ̀lú Ìjẹ́kánjúkánjú!

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Wàásù Pẹ̀lú Ìjẹ́kánjúkánjú!
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2009
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Máa Fi Sọ́kàn Pé Iṣẹ́ Ìwàásù Jẹ́ Kánjúkánjú
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2012
  • Pa Òye Ìjẹ́kánjúkánjú Rẹ Mọ́
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
  • Bí A Ṣe Lè Máa Fi Sọ́kàn Pé Iṣẹ́ Ìwàásù Jẹ́ Kánjúkánjú
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
  • “Ọjọ́ Ńlá Jèhófà Sún Mọ́lé”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2006
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2009
km 12/09 ojú ìwé 1

Wàásù Pẹ̀lú Ìjẹ́kánjúkánjú!

1. Ọ̀rọ̀ ìyànjú Pọ́ọ̀lù wo ló yẹ ká fún láfiyèsí lóde òní?

1 “Wàásù ọ̀rọ̀ náà, wà lẹ́nu rẹ̀ ní kánjúkánjú.” (2 Tím. 4:2) Kí nìdí tí ọ̀rọ̀ ìyànjú Pọ́ọ̀lù yìí fi ṣe pàtàkì fún wa lónìí? Báwo ni ọ̀rọ̀ yìí ṣe lè nípa lórí ìgbésí ayé wa àti tàwọn ẹlòmíì?

2. Kí nìdí tá a fi ń sapá láti wá àwọn tí kò tíì gbọ́ ìhìn rere?

2 Ọ̀ràn Ẹ̀mí Ni: Ọ̀kẹ́ àìmọye èèyàn kárí ayé ni kò tíì gbọ́ ìhìn rere tó lè mú kí wọ́n rí ìgbàlà. (Róòmù. 10:13-15; 1 Tím. 4:16) A máa ń rí ọ̀pọ̀ àwọn olóòótọ́ ọkàn láwọn ìpínlẹ̀ tá a ti máa ń wàásù déédéé. Tá a bá lọ wàásù nírú ìpínlẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ọjọ́ tàbí àkókò tó yàtọ̀ sí èyí tá a máa ń lọ wàásù níbẹ̀, ó ṣeé ṣe ká pàdé àwọn tá a kì í sábà rí níbẹ̀ tẹ́lẹ̀. Tá a bá sapá láti wá àwọn èèyàn lọ́nà yìí, ẹ̀rí ọkàn wa kò ní máa dá wa lẹ́bi, a ò sì ní jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀.—Ìṣe 20:26.

3. Báwo la ṣe lè fi ọgbọ́n lo àkókò wa lóde ẹ̀rí?

3 Bó tiẹ̀ jẹ́ pé àwọn Kristẹni ọ̀rúndún kìíní dojú kọ àtakò gbígbóná janjan, síbẹ̀ wọ́n ‘fi ẹ̀kọ́ wọn kún Jerúsálẹ́mù.’ (Ìṣe 5:28) Ṣé àwa náà ti pinnu “láti jẹ́rìí kúnnákúnná”? (Ìṣe 10:42) Tá a bá wà lóde ẹ̀rí, ṣé a máa ń fọgbọ́n lo àkókò wa? Tó bá ṣẹlẹ̀ pé à ń dúró de àwọn ará tó kù nítorí àwọn ìdí kan, ǹjẹ́ a máa ń lo ìdánúṣe láti fi àkókò yẹn bá àwọn tó ń kọjá lọ sọ̀rọ̀?

4. Báwo ni wíwàásù pẹ̀lú ìjẹ́kánjúkánjú ṣe ń mú ká máa ṣọ́nà?

4 Ó Ń Jẹ́ Ká Túbọ̀ Wà Lójúfò: Bí òpin ètò àwọn nǹkan ìsinsìnyí ti ń sún mọ́lé, a gbọ́dọ̀ wà lójúfò, ká sì máa ṣọ́nà. (1 Tẹs. 5:1-6) Tá a bá ń fìgbà gbogbo bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ nípa ìrètí Ìjọba Ọlọ́run, ìyẹn kò ní jẹ́ ká dẹni tí ètò àwọn nǹkan ìsinsìnyí dẹrù pa. (Lúùkù 21:34-36) Kàkà bẹ́ẹ̀, bá a bá ń fi ọjọ́ Jèhófà “sọ́kàn pẹ́kípẹ́kí,” èyí á mú ká lè máa fi kún ipa tá à ń kó nínú iṣẹ́ ìwàásù tó jẹ́ iṣẹ́ ìgbẹ̀mílà.—2 Pét. 3:11, 12.

5. Báwo ni ọ̀wọ̀ fún ìwàláàyè ṣe ń nípa lórí iṣẹ́ ìwàásù wa?

5 Tá a bá ń wàásù pẹ̀lú ìjẹ́kánjúkánjú, ìyẹn ń fi hàn pé ojú tí Jèhófà fi ń wo ìwàláàyè làwa náà fi ń wò ó. Bíbélì sọ pé: “Kò fẹ́ kí ẹnikẹ́ni pa run ṣùgbọ́n ó fẹ́ kí gbogbo ènìyàn wá sí ìrònúpìwàdà.” (2 Pét. 3:9; Ìsík. 33:11) Ǹjẹ́ ká fi ṣe àfojúsùn wa pé a óò wá gbogbo àwọn tó bá ṣeé ṣe fún wa láti rí kàn ní ìpínlẹ̀ ìwàásù wa, sí ìyìn Jèhófà!—Sm. 109:30.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́