ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 12/15 ojú ìwé 1
  • Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Àwọn Wòlíì​—Hábákúkù

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Àwọn Wòlíì​—Hábákúkù
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2015
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Gbẹ́kẹ̀ Lé Jèhófà Kó O Lè Wà Láàyè!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2018
  • Kíkún Fún Ìdùnnú Nínú Ọlọ́run Ìgbàlà Wa
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
  • Báwo Ni Àkókò Tó Ṣẹ́ Kù Fún Àwọn Olubi Ti Pọ̀ Tó?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
  • Jèhófà Kò Ní Fi Nǹkan Falẹ̀
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2015
km 12/15 ojú ìwé 1

Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Àwọn Wòlíì​—Hábákúkù

1. Báwo lọ̀rọ̀ àwa àti wòlíì Hábákúkù ṣe jọra?

1 Bá a ṣe ń rí bí ìwà ibi ṣe ń gbèrú sí i láyé, ó lè máa ṣe wá bíi ti Hábákúkù tó bi Jèhófà pé: “Èé ṣe tí ìwọ fi mú kí n rí ohun tí ń ṣeni lọ́ṣẹ́, tí ìwọ sì ń wo èkìdá ìdààmú?” (Háb. 1:3; 2 Tím. 3:​1, 13) Tá a ba ń ronú lórí ọ̀rọ̀ Hábákúkù, tá a sì ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ìṣòtítọ́ rẹ̀, èyí á máa fún wa lókun bá a ṣe ń dúró de ọjọ́ ìdájọ́ Jèhófà.​—2 Pét. 3:7.

2. Báwo la ṣe lè fi hàn pé a jẹ́ olóòótọ́?

2 Jẹ́ Olóòótọ́: Dípò tí Hábákúkù á fi jẹ́ kí àwọn nǹkan burúkú tó ń ṣẹlẹ̀ kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá a, ńṣe ló túbọ̀ wà lójúfò nípa tẹ̀mí, tó sì ń bá iṣẹ́ wòlíì rẹ̀ lọ. (Háb. 2:1) Jèhófà fi í lọ́kàn balẹ̀ pé ọ̀rọ̀ Òun máa tó ṣẹ àti pé ‘olódodo yóò máa wà láàyè nìṣó nípa ìṣòtítọ́ rẹ̀.’ (Háb. 2:​2-4) Kí lèyí túmọ̀ sí fún àwa Kristẹni tá à ń gbé ní àkókò tí òpin ti sún mọ́lé gan-an yìí? Ìdánilójú tá a ní pé òpin máa dé ṣe pàtàkì ju ìgbà tí òpin máa dé lọ. Ìgbàgbọ́ máa ń jẹ́ ká wà lójúfò, ká sì máa fi iṣẹ́ ìwàásù sí ipò àkọ́kọ́.​—Héb. 10:​38, 39.

3. Kí nìdí tó fi yẹ ká máa fi ìdùnnú sin Jèhófà?

3 Máa Yọ Ayọ̀ Ńláǹlà Nínú Jèhófà: Nígbà tí Gọ́ọ̀gù ti ilẹ̀ Mágọ́gù bá gbógun tí àwa èèyàn Jèhófà, èyí máa dán ìgbàgbọ́ wa wò. (Ìsík. 38:​2, 10-12) Ogun máa ń fa ìnira, kódà fáwọn tó bá ṣẹ́gun lẹ́yìn-ọ̀-rẹ́yìn pàápàá. Ọ̀wọ́n gógó oúnjẹ lè wà, a lè pàdánù dúkìá, sànmánì sì lè lọ́ tín-ín-rín fún wa. Tí irú àwọn ìṣòro yìí bá dé, kí la máa ṣe? Torí pé Hábákúkù ń retí ìṣòro, ó pinnu pé òun á máa bá a lọ ní fífi ayọ̀ sin Jèhófà. (Háb. 3:​16-19) “Ìdùnnú Jèhófà” máa ràn wá lọ́wọ́ láti fara da àwọn àdánwò ọjọ́ iwájú.​—Neh. 8:10; Héb. 12:2.

4. Ayọ̀ wo lá máa ní báyìí àti lọ́jọ́ iwájú?

4 Jèhófà á máa bá a lọ láti kọ́ àwọn tó bá la ọjọ́ ìdájọ́ rẹ̀ tó ń bọ̀ já ní ọ̀nà ìgbésí ayé tó bá ìfẹ́ rẹ̀ mu. (Háb. 2:14) Àwọn tí Ọlọ́run bá jí dìde náà máa kẹ́kọ̀ọ́ nípa Jèhófà. Ní báyìí ná, ẹ jẹ́ ká máa lo gbogbo àǹfààní tá a bá ní láti sọ̀rọ̀ nípa Jèhófà àtàwọn ìṣẹ́ àgbàyanu rẹ̀ fáwọn èèyàn!​—Sm. 34:1; 71:17.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́