ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • wp20 No. 3 ojú ìwé 10
  • Máa Gbàdúrà Kó O Lè Rí Ojú Rere Ọlọ́run

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Gbàdúrà Kó O Lè Rí Ojú Rere Ọlọ́run
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2020
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • FI ÌRẸ̀LẸ̀ GBÀDÚRÀ LÁTỌKÀN WÁ
  • MÁA LO ORÚKỌ ỌLỌ́RUN NÍNÚ ÀDÚRÀ RẸ
  • O LÈ GBÀDÚRÀ NÍ ÈDÈ ÀBÍNIBÍ RẸ
  • Sún Mọ́ Ọlọ́run Nípasẹ̀ Àdúrà
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
  • Àǹfààní Pàtàkì Ni Àdúrà Jẹ́
    Kí Ni Bíbélì Kọ́ Wa?
  • Máa Gbàdúrà Kó O Lè Túbọ̀ Sún Mọ́ Ọlọ́run
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
  • Sísún Mọ́ Ọlọrun Nínú Àdúrà
    Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2020
wp20 No. 3 ojú ìwé 10
Ọkùnrin kan tó jẹ́ Árábù ń gbàdúrà.

Inú Ọlọ́run tó jẹ́ “Olùgbọ́ àdúrà” máa ń dùn láti gbọ́ wa.​—SÁÀMÙ 65:2

Máa Gbàdúrà Kó O Lè Rí Ojú Rere Ọlọ́run

Ọlọ́run fún àwa èèyàn ní ẹ̀bùn kan tó ṣàrà ọ̀tọ̀. Ẹ̀bùn náà ni pé a lè bá a sọ̀rọ̀, a sì lè sọ bí nǹkan ṣe rí lára wa fún un. Wòlíì Dáfídì gbàdúrà pé: “Ìwọ Olùgbọ́ àdúrà, ọ̀dọ̀ rẹ ni onírúurú èèyàn yóò wá.” (Sáàmù 65:2) Àmọ́ báwo la ṣe lè gbàdúrà tí Ọlọ́run á gbọ́ àdúrà wa, tí á sì bù kún wa?

FI ÌRẸ̀LẸ̀ GBÀDÚRÀ LÁTỌKÀN WÁ

Tó o bá ń dá gbàdúrà, wàá láǹfààní láti tú ọkàn rẹ jáde níwájú Ọlọ́run, wàá sì sọ bí ọ̀rọ̀ ṣe rí lára rẹ fún un. (Sáàmù 62:8) Ohun tí Olódùmarè fẹ́ ni pé ká máa fi òótọ́ inú gbàdúrà látọkàn wá.

MÁA LO ORÚKỌ ỌLỌ́RUN NÍNÚ ÀDÚRÀ RẸ

Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Ọlọ́run ní ọ̀pọ̀ orúkọ oyè, orúkọ kan ṣoṣo ló ní. Òun fúnra rẹ̀ sọ pé: “Èmi ni Jèhófà. Orúkọ mi nìyẹn.” (Àìsáyà 42:8) Orúkọ náà Jèhófà fara hàn nínú Ìwé Mímọ́ ní nǹkan bí ẹgbẹ̀rún méje (7,000) ìgbà. Ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì lo orúkọ Ọlọ́run. Ábúráhámù sọ pé: “Jèhófà jọ̀ọ́, . . . jẹ́ kí n máa bá ọ̀rọ̀ mi lọ [pẹ̀lú rẹ].” (Jẹ́nẹ́sísì 18:30) Ó yẹ káwa náà máa lo orúkọ Ọlọ́run, ìyẹn Jèhófà, nínú àdúrà wa.

O LÈ GBÀDÚRÀ NÍ ÈDÈ ÀBÍNIBÍ RẸ

Èdè yòówù ká fi gbàdúrà, Ọlọ́run mọ èrò ọkàn wa àti bọ́rọ̀ ṣe rí lára wa. Ọ̀rọ̀ rẹ̀ fi dá wa lójú pé: “Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú, àmọ́ ní gbogbo orílẹ̀-èdè, ẹni tó bá bẹ̀rù rẹ̀, tó sì ń ṣe ohun tí ó tọ́ ni ẹni ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.”​—Ìṣe 10:​34, 35.

Àmọ́, tá a bá fẹ́ kí Ọlọ́run bù kún wa, àdúrà nìkan kò tó. Nínú àwọn àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé e, a máa mọ ohun tó yẹ ká ṣe.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́