ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb21 July ojú ìwé 11
  • Máa Hùwà Sáwọn Àgbà Obìnrin Bí Ìyá, Àwọn Ọ̀dọ́bìnrin Bí Ọmọ Ìyá

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Hùwà Sáwọn Àgbà Obìnrin Bí Ìyá, Àwọn Ọ̀dọ́bìnrin Bí Ọmọ Ìyá
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣé Ojú Tí Jèhófà Fi Ń Wo Àwọn Obìnrin Lo Fi Ń Wò Wọ́n?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2024
  • Ẹ Máa Fún Àwọn Arábìnrin Níṣìírí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • Mọyì Ipò Orí Tí Jèhófà Ṣètò Nínú Ìjọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021
  • Mọyì Àwọn Míì Nínú Ìjọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
mwb21 July ojú ìwé 11
Arákùnrin kan ń mú ìyá àgbàlagbà kan wọnú ọkọ̀, ọ̀dọ́bìnrin kan sì ń rìn tẹ̀ lé wọn.

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Máa Hùwà Sáwọn Àgbà Obìnrin Bí Ìyá, Àwọn Ọ̀dọ́bìnrin Bí Ọmọ Ìyá

Bíbélì sọ pé ó yẹ ká máa hùwà sáwọn àgbàlagbà bíi pé bàbá àti ìyá wa ni wọ́n jẹ́, ká sì mú àwọn tó kéré sí wa bí àbúrò. (Ka 1 Tímótì 5:1, 2.) Ní pàtàkì, àwọn arákùnrin tún gbọ́dọ̀ máa bọlá fáwọn arábìnrin, kí wọ́n sì máa bọ̀wọ̀ fún wọn.

Arákùnrin kan ò gbọ́dọ̀ máa sọ̀rọ̀ tàbí ṣe ohun tí ò ní jẹ́ kọ́kàn arábìnrin kan balẹ̀. (Job 31:1) Tí arákùnrin kan ò bá ní i lọ́kàn láti fẹ́ arábìnrin kan, kò gbọ́dọ̀ máa ṣe ohun tá mú kí arábìnrin yẹn rò pé ó fẹ́ fẹ́ òun.

Àwọn alàgbà gbọ́dọ̀ máa gba tàwọn arábìnrin rò, kí wọ́n sì máa bọ̀wọ̀ fún wọn nígbàkigbà tí wọ́n bá béèrè ìbéèrè tàbí tí wọ́n bá sọ ohun tó yẹ káwọn alàgbà kíyè sí. Ní pàtàkì, ó tún yẹ káwọn alàgbà máa gba tàwọn arábìnrin tí ò lọ́kọ rò.​—Rut 2:8, 9.

Ẹ WO FÍDÍÒ NÁÀ MÁA FI ÌFẸ́ TÍ KÌ Í YẸ̀ HÀN SÁWỌN​—OPÓ ÀTÀWỌN ỌMỌ ALÁÌNÍBABA, KẸ́ Ẹ SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Máa Fi Ìfẹ́ Tí Kì Í Yẹ̀ Hàn Sáwọn—Opó Àtàwọn Ọmọ Aláìníbaba.’ Àwọn ará wá tu Arábìnrin Myint àtàwọn ọmọ ẹ̀ nínú lẹ́yìn tí ọkọ ẹ̀ kú.

    Báwo làwọn ará ṣe fìfẹ́ hàn sí Arábìnrin Myint?

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Máa Fi Ìfẹ́ Tí Kì Í Yẹ̀ Hàn Sáwọn—Opó Àtàwọn Ọmọ Aláìníbaba.’ Ọ̀kan lára àwọn aládùúgbò Arábìnrin Myint ń wò tọkọtaya kan bí wọ́n ṣe ń wọlé Arábìnrin Myint láti kí òun àtàwọn ọmọ ẹ̀.

    Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà táwọn ará abúlé rí ìfẹ́ táwọn ará fi hàn sí Arábìnrin Myint?

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Máa Fi Ìfẹ́ Tí Kì Í Yẹ̀ Hàn Sáwọn—Opó Àtàwọn Ọmọ Aláìníbaba.’ Arábìnrin Myint àti ọmọbìnrin ẹ̀ wà nípàdé.

    Báwo ni ìfẹ́ táwọn ará fi hàn sí Arábìnrin Myint ṣe ran àwọn ọmọ ẹ̀ lọ́wọ́?

Àwọn ọ̀nà wo lo lè gbà fìfẹ́ hàn sáwọn arábìnrin nínú ìjọ?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́