ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • ijwbq àpilẹ̀kọ 29
  • Ṣó Yẹ Kí N Máa Gbàdúrà sí Àwọn Ẹni Mímọ́

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ṣó Yẹ Kí N Máa Gbàdúrà sí Àwọn Ẹni Mímọ́
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun tí Bíbélì sọ
  • Ǹjẹ́ Ó Yẹ Ká Máa Gbàdúrà sí Àwọn Ẹni Mímọ́?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Ṣé Ó Yẹ Ká Máa Gbàdúrà sí “Àwọn Ẹni Mímọ́”?
    Jí!—2011
  • Báwo Làwọn Ẹni Mímọ́ Tòótọ́ Ṣe Lè Ràn Ọ́ Lọ́wọ́?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
  • Ṣé Jésù Ló Yẹ Ká Máa Gbàdúrà Sí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
Àwọn Míì
Ohun Tí Bíbélì Sọ
ijwbq àpilẹ̀kọ 29

Ṣó Yẹ Kí N Máa Gbàdúrà Sáwọn Ẹni Mímọ́?

Ohun tí Bíbélì sọ

Rárá o. Bíbélì fi hàn pé Ọlọ́run nìkan ló yẹ ká gbàdúrà sí, ká sì máa gbà á lórúkọ Jésù. Jésù sọ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé: “Nitorina bayi ni ki ẹnyin mã gbadura: Baba wa ti mbe li ọrun; Ki a bọ̀wọ fun orukọ rẹ.” (Mátíù 6:9, Bíbélì Mímọ́) Jésù ò fìgbà kan rí sọ fáwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ kí wọ́n máa gbàdúrà sí àwọn ẹni mímọ́, àwọn áńgẹ́lì tàbí ẹlòmíì yàtọ̀ sí Ọlọ́run.

Jésù tún sọ fáwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ pé: “Èmi ni ọ̀nà àti òtítọ́ àti ìyè. Kò sí ẹni tí ń wá sọ́dọ̀ Baba bí kò ṣe nípasẹ̀ mi.” (Jòhánù 14:6) Jésù nìkan ni Ọlọ́run yàn gẹ́gẹ́ bí alágbàwí wa.—Hébérù 7:25.

Ṣó buru tí mo bá ń gbàdúrà sí Ọlọ́run tí mo sì ń gbà á sáwọn ẹni mímọ́?

Nínú Òfin Mẹ́wàá, Ọlọ́run sọ pé: “Emi li OLUWA Ọlọrun rẹ, Olọrun owú ni mi.” (Ẹ́kísódù 20:5, Bíbélì Mímọ́) Ọ̀nà wo ni Ọlọ́run gbà jẹ́ Ọlọ́urn owú? Bó ṣe jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni pé ó ń “béèrè ìfọkànsìn tí a yà sọ́tọ̀ gedegbe.” Ọlọ́run ń fẹ́ ká máa darí gbogbo ohun tó bá jẹ́ mọ́ ìjọsìn, tó fi mọ́ àdúrà, sọ́dọ̀ òun nìkan.—Aísáyà 48:11.

Ó máa bí Ọlọ́run nínú tá a bá lọ ń gbàdúrà sí ẹlòmíì, ì báà jẹ́ ẹni mímọ́ tàbí áńgẹ́lì kan mímọ́ kan. Nígbà tí àpọ́sítélì Jòhánù fẹ́ jọ́sìn áńgẹ́lì kan, áńgẹ́lì ò gbà á láyè, ńṣe ló sọ pé: ‘Wò ó, má ṣe bẹ́ẹ̀: ìránṣẹ́ ẹlẹ́gbẹ́ rẹ ni èmi, àti ti àwọn arákùnrin rẹ tí wọ́n di ẹ̀rí Jésù mú; forí balẹ̀ fún Ọlọ́run.”—Ìfihàn 19:10, Bíbélì Mímọ́.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́