Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Sámúẹ́lì fúnra rẹ̀ ló pa Ágágì. Kò yẹ kí wọ́n fi ojú àánú hàn sí ọba búburú yìí àti ìdílé rẹ̀. Ẹ̀rí tó dájú wà pé ọ̀kan lára àwọn àtọmọdọ́mọ Ágágì ni “Hámánì ọmọ Ágágì.” Ọ̀pọ̀ ọdún lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ló gbé ayé, ó sì gbìyànjú láti pa gbogbo àwọn èèyàn Ọlọ́run run.—Ẹ́sítérì 8:3; wo Orí 15 àti 16 nínú ìwé yìí.