Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Bó tilẹ̀ jẹ́ pé èrò àwọn èèyàn yàtọ̀ síra nípa rẹ̀, síbẹ̀ àwọn kan sọ pé tẹ́ńpìlì Dagan ni tẹ́ńpìlì El. Ọ̀gbẹ́ni Roland de Vaux, tó jẹ́ ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀ ní Ilẹ̀ Faransé àti ọ̀jọ̀gbọ́n ní Ilé Ìwé Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ní Jerúsálẹ́mù, sọ pé Dagan—ìyẹn Dágónì tó wà nínú ìwé Àwọn Onídàájọ́ 16:23 àti ìwé 1 Sámúẹ́lì 5:1-5—ni orúkọ tí El ń jẹ́ gan-an. Ìwé gbédègbẹ́yọ̀, The Encyclopedia of Religion sọ pé ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé “Dagan dà pọ̀ mọ́ [El] lọ́nà kan ṣáá tàbí kó wà nínú rẹ̀.” Ọmọ Báálì ni wọ́n pe Dagan nínú àwọn ìwé Ras Shamra, àmọ́ ohun tí “ọmọ” túmọ̀ sí níhìn-ín kò fi bẹ́ẹ̀ dáni lójú.