Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Ẹ̀rí fi hàn pé ẹ̀gbọ́n tàbí àbúrò ẹni tó kú náà ni wọ́n máa ń kọ́kọ́ fún ní ẹ̀tọ́ láti fi opó náà ṣe aya, ìyẹn láti ṣú u lópó. Tí wọn ò bá wá fẹ́ ẹ, á ṣẹ̀ṣẹ̀ wá kan mọ̀lẹ́bí rẹ̀ míì tó jẹ́ ọkùnrin. Bí wọ́n sì ṣe máa ṣe ogún rẹ̀ náà nìyẹn.—Númérì 27:5-11.