Wednesday, August 6
Ipa ọ̀nà àwọn olódodo dà bí ìmọ́lẹ̀ àárọ̀ tó ń mọ́lẹ̀ sí i títí di ọ̀sán gangan.—Òwe 4:18.
Láwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí, Jèhófà ń lo ètò rẹ̀ láti fi Ọ̀rọ̀ rẹ̀ tọ́ wa sọ́nà ká lè máa rìn ní “Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́” nìṣó. (Àìsá. 35:8; 48:17; 60:17) A lè sọ pé ìgbàkigbà tí ẹnì kan bá ti ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ló ti bẹ̀rẹ̀ sí í rìn ní “Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́.” Àwọn kan á rìn díẹ̀, wọ́n á sì kúrò lójú ọ̀nà náà. Àmọ́, àwọn míì pinnu pé àwọn á máa rìn lójú ọ̀nà náà títí wọ́n á fi dé ibi tí wọ́n ń lọ. Ibo ni wọ́n ń lọ? Ibi tí “Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́” máa gbé àwọn tó ń lọ sí ọ̀run dé ni “párádísè Ọlọ́run” tó wà ní ọ̀run. (Ìfi. 2:7) Àmọ́ ọ̀nà náà máa jẹ́ káwọn tó fẹ́ gbé ayé di pípé nígbà tí Ẹgbẹ̀rún Ọdún Ìṣàkóso Kristi bá máa fi parí. Tó o bá ń rìn ní ọ̀nà yẹn lónìí, má wẹ̀yìn o. Má sì kúrò lójú ọ̀nà náà títí tó o fi máa dénú ayé tuntun! w23.05 17 ¶15; 19 ¶16-18
Thursday, August 7
A nífẹ̀ẹ́ torí òun ló kọ́kọ́ nífẹ̀ẹ́ wa.—1 Jòh. 4:19.
Tó o bá ronú nípa àwọn nǹkan tí Jèhófà ṣe fún ẹ, wàá túbọ̀ mọyì Jèhófà, wàá sì ya ara ẹ sí mímọ́ fún un. (Sm. 116:12-14) Bíbélì sọ pé Jèhófà ló ń fún wa ní “gbogbo ẹ̀bùn rere àti gbogbo ọrẹ pípé.” (Jém. 1:17) Èyí tó tóbi jù lọ nínú gbogbo ẹ̀bùn tó fún wa ni Jésù Ọmọ ẹ̀ tó fi rúbọ nítorí wa. Ẹ̀yin náà ẹ wo àǹfààní tíyẹn ṣe wá! Ìràpadà ló jẹ́ kó ṣeé ṣe fún wa láti sún mọ́ Jèhófà, ká sì di ọ̀rẹ́ ẹ̀. Yàtọ̀ síyẹn, ohun tí Jèhófà ṣe yìí ló jẹ́ kó ṣeé ṣe fún wa láti wà láàyè títí láé. (1 Jòh. 4:9, 10) Torí náà, ọ̀nà kan tó o lè gbà fi hàn pé o mọyì ẹ̀bùn tó ga jù lọ tí Jèhófà fún ẹ àtàwọn nǹkan rere míì tó ṣe fún ẹ ni pé kó o ya ara ẹ sí mímọ́ fún un.—Diu. 16:17; 2 Kọ́r. 5:15. w24.03 5 ¶8
Friday, August 8
Ẹni tó ń rìn nínú ìdúróṣinṣin ń bẹ̀rù Jèhófà.—Òwe 14:2.
Tá a bá wo bí ìwàkiwà ṣe kún inú ayé lónìí, ó dájú pé bí nǹkan ṣe rí lára Lọ́ọ̀tì náà ló rí lára wa. Bíbélì sọ pé ó “banú jẹ́ gidigidi nítorí ìwà àìnítìjú àwọn arúfin èèyàn” torí ó mọ̀ pé Baba wa ọ̀run kórìíra ìwà burúkú. (2 Pét. 2:7, 8) Kí nìdí tí Lọ́ọ̀tì fi kórìíra ìwà burúkú ìgbà ayé ẹ̀? Ìdí ni pé ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ó sì nífẹ̀ẹ́ ẹ̀. Bákan náà lónìí, ìwà burúkú ló gba ayé kan torí pé àwọn èèyàn ò bẹ̀rù Ọlọ́run. Bó ti wù kó rí, àwa Kristẹni ṣì lè jẹ́ oníwà mímọ́ tá a bá nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run, tá a sì ń bẹ̀rù ẹ̀ tọkàntọkàn. Kíyẹn lè ṣeé ṣe, Jèhófà jẹ́ kí wọ́n kọ àwọn ohun tó yẹ ká ṣe àtàwọn ohun tí ò yẹ ká ṣe sínú ìwé Òwe, ó sì rọ̀ wá pé ká máa ṣe ohun tó tọ́. Torí náà, gbogbo àwa Kristẹni pátápátá lọ́mọdé lágbà, lọ́kùnrin àti lóbìnrin la máa jàǹfààní tá a bá ń fi ìmọ̀ràn inú ẹ̀ sílò. Tá a bá bẹ̀rù Jèhófà lóòótọ́, kò yẹ ká máa kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú àwọn tó ń hùwàkiwà. w23.06 20 ¶1-2; 21 ¶5