Tuesday, August 5
Ẹni tó bá ń wo ṣíṣú òjò kò ní kórè.—Oníw. 11:4.
Ẹni tó bá ń kó ara ẹ̀ níjàánu máa ń ṣe gbogbo ohun tó lè ṣe kó má bàa ṣe ohun tí ò dáa. A gbọ́dọ̀ kó ara wa níjàánu kọ́wọ́ wa lè tẹ àfojúsùn wa, pàápàá tí ohun tá a fẹ́ ṣe yẹn ò bá rọrùn tàbí tí kò bá wù wá. Máa rántí pé ìkóra-ẹni-níjàánu wà lára àwọn ìwà tí ẹ̀mí Ọlọ́run máa ń jẹ́ ká ní, torí náà bẹ Jèhófà pé kó fún ẹ ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀ kó o lè túbọ̀ máa kó ara ẹ níjàánu. (Lúùkù 11:13; Gál. 5:22, 23) Má dúró dìgbà tí gbogbo nǹkan máa dán mọ́rán. Kò dájú pé ìgbà kan máa wà tí gbogbo nǹkan á dán mọ́rán fún wa nínú ayé yìí. Torí náà, tá a bá sọ pé a fẹ́ dúró dìgbà tí gbogbo nǹkan máa dáa, ọwọ́ wa lè má tẹ àfojúsùn wa. A lè rẹ̀wẹ̀sì torí ó lè máa ṣe wá bíi pé ohun tá a fẹ́ ṣe yẹn ti le jù, ọwọ́ wa ò sì ní lè tẹ̀ ẹ́. Tó bá jẹ́ ohun tó ń ṣẹlẹ̀ sí ẹ nìyẹn, ṣé o lè ronú nípa àwọn àfojúsùn míì tọ́wọ́ ẹ lè tètè tẹ̀? Tó bá jẹ́ pé ànímọ́ kan ló wù ẹ́ kó o ní, o ò ṣe kọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ sí í fi ànímọ́ náà hàn díẹ̀díẹ̀? Tó bá jẹ́ àfojúsùn ẹ ni pé kó o ka gbogbo Bíbélì parí, á dáa kó o kọ́kọ́ máa fi àkókò díẹ̀ kà á lójoojúmọ́. w23.05 29 ¶11-13
Wednesday, August 6
Ipa ọ̀nà àwọn olódodo dà bí ìmọ́lẹ̀ àárọ̀ tó ń mọ́lẹ̀ sí i títí di ọ̀sán gangan.—Òwe 4:18.
Láwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí, Jèhófà ń lo ètò rẹ̀ láti fi Ọ̀rọ̀ rẹ̀ tọ́ wa sọ́nà ká lè máa rìn ní “Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́” nìṣó. (Àìsá. 35:8; 48:17; 60:17) A lè sọ pé ìgbàkigbà tí ẹnì kan bá ti ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ló ti bẹ̀rẹ̀ sí í rìn ní “Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́.” Àwọn kan á rìn díẹ̀, wọ́n á sì kúrò lójú ọ̀nà náà. Àmọ́, àwọn míì pinnu pé àwọn á máa rìn lójú ọ̀nà náà títí wọ́n á fi dé ibi tí wọ́n ń lọ. Ibo ni wọ́n ń lọ? Ibi tí “Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́” máa gbé àwọn tó ń lọ sí ọ̀run dé ni “párádísè Ọlọ́run” tó wà ní ọ̀run. (Ìfi. 2:7) Àmọ́ ọ̀nà náà máa jẹ́ káwọn tó fẹ́ gbé ayé di pípé nígbà tí Ẹgbẹ̀rún Ọdún Ìṣàkóso Kristi bá máa fi parí. Tó o bá ń rìn ní ọ̀nà yẹn lónìí, má wẹ̀yìn o. Má sì kúrò lójú ọ̀nà náà títí tó o fi máa dénú ayé tuntun! w23.05 17 ¶15; 19 ¶16-18
Thursday, August 7
A nífẹ̀ẹ́ torí òun ló kọ́kọ́ nífẹ̀ẹ́ wa.—1 Jòh. 4:19.
Tó o bá ronú nípa àwọn nǹkan tí Jèhófà ṣe fún ẹ, wàá túbọ̀ mọyì Jèhófà, wàá sì ya ara ẹ sí mímọ́ fún un. (Sm. 116:12-14) Bíbélì sọ pé Jèhófà ló ń fún wa ní “gbogbo ẹ̀bùn rere àti gbogbo ọrẹ pípé.” (Jém. 1:17) Èyí tó tóbi jù lọ nínú gbogbo ẹ̀bùn tó fún wa ni Jésù Ọmọ ẹ̀ tó fi rúbọ nítorí wa. Ẹ̀yin náà ẹ wo àǹfààní tíyẹn ṣe wá! Ìràpadà ló jẹ́ kó ṣeé ṣe fún wa láti sún mọ́ Jèhófà, ká sì di ọ̀rẹ́ ẹ̀. Yàtọ̀ síyẹn, ohun tí Jèhófà ṣe yìí ló jẹ́ kó ṣeé ṣe fún wa láti wà láàyè títí láé. (1 Jòh. 4:9, 10) Torí náà, ọ̀nà kan tó o lè gbà fi hàn pé o mọyì ẹ̀bùn tó ga jù lọ tí Jèhófà fún ẹ àtàwọn nǹkan rere míì tó ṣe fún ẹ ni pé kó o ya ara ẹ sí mímọ́ fún un.—Diu. 16:17; 2 Kọ́r. 5:15. w24.03 5 ¶8