Monday, August 4
Gbé àwo ìgbàyà wọ̀, kí o sì dé akoto.—1 Tẹs. 5:8.
Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fi àwa Kristẹni wé àwọn sójà tó máa ń wà lójúfò, tí wọ́n sì máa ń múra sílẹ̀ de ogun. Àwọn èèyàn gbà pé ó yẹ kí sójà kan múra sílẹ̀ láti jà torí ìgbàkigbà ni ogun lè dé. Bọ́rọ̀ tiwa náà ṣe rí nìyẹn. Tá a bá fẹ́ fi hàn pé lóòótọ́ là ń múra sílẹ̀ de ọjọ́ Jèhófà, ó yẹ ká gbé àwo ìgbàyà wọ̀, ìyẹn ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́, ká sì dé akoto, ìyẹn ìrètí tá a ní. Àwo ìgbàyà máa ń dáàbò bo àyà sójà kan. Bẹ́ẹ̀ náà ni ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ ṣe máa ń dáàbò bo ọkàn ìṣàpẹẹrẹ wa. Àwọn ànímọ́ yìí máa ń jẹ́ ká sin Jèhófà nìṣó, ká sì máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù. Ìgbàgbọ́ tá a ní máa ń jẹ́ kó dá wa lójú pé Jèhófà máa san èrè fún wa tá a bá sìn ín tọkàntọkàn. (Héb. 11:6) Ó máa ń jẹ́ ká jẹ́ olóòótọ́ sí Jésù Aṣáájú wa kódà bá a tiẹ̀ ń fara da ọ̀pọ̀ ìṣòro. A lè mú kí ìgbàgbọ́ wa túbọ̀ lágbára tá a bá ń kẹ́kọ̀ọ́ nípa àpẹẹrẹ àwọn tó jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà lásìkò wa yìí bó tiẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ń fara da inúnibíni tàbí ìṣòro àìlówó lọ́wọ́. Yàtọ̀ síyẹn, tá ò bá fẹ́ kó sínú ìdẹkùn kíkó ohun ìní jọ, ó yẹ ká máa fara wé àwọn tí wọ́n jẹ́ kí ohun ìní díẹ̀ tẹ́ wọn lọ́rùn kí wọ́n lè fi Ìjọba Ọlọ́run sípò àkọ́kọ́. w23.06 10 ¶8-9
Tuesday, August 5
Ẹni tó bá ń wo ṣíṣú òjò kò ní kórè.—Oníw. 11:4.
Ẹni tó bá ń kó ara ẹ̀ níjàánu máa ń ṣe gbogbo ohun tó lè ṣe kó má bàa ṣe ohun tí ò dáa. A gbọ́dọ̀ kó ara wa níjàánu kọ́wọ́ wa lè tẹ àfojúsùn wa, pàápàá tí ohun tá a fẹ́ ṣe yẹn ò bá rọrùn tàbí tí kò bá wù wá. Máa rántí pé ìkóra-ẹni-níjàánu wà lára àwọn ìwà tí ẹ̀mí Ọlọ́run máa ń jẹ́ ká ní, torí náà bẹ Jèhófà pé kó fún ẹ ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀ kó o lè túbọ̀ máa kó ara ẹ níjàánu. (Lúùkù 11:13; Gál. 5:22, 23) Má dúró dìgbà tí gbogbo nǹkan máa dán mọ́rán. Kò dájú pé ìgbà kan máa wà tí gbogbo nǹkan á dán mọ́rán fún wa nínú ayé yìí. Torí náà, tá a bá sọ pé a fẹ́ dúró dìgbà tí gbogbo nǹkan máa dáa, ọwọ́ wa lè má tẹ àfojúsùn wa. A lè rẹ̀wẹ̀sì torí ó lè máa ṣe wá bíi pé ohun tá a fẹ́ ṣe yẹn ti le jù, ọwọ́ wa ò sì ní lè tẹ̀ ẹ́. Tó bá jẹ́ ohun tó ń ṣẹlẹ̀ sí ẹ nìyẹn, ṣé o lè ronú nípa àwọn àfojúsùn míì tọ́wọ́ ẹ lè tètè tẹ̀? Tó bá jẹ́ pé ànímọ́ kan ló wù ẹ́ kó o ní, o ò ṣe kọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ sí í fi ànímọ́ náà hàn díẹ̀díẹ̀? Tó bá jẹ́ àfojúsùn ẹ ni pé kó o ka gbogbo Bíbélì parí, á dáa kó o kọ́kọ́ máa fi àkókò díẹ̀ kà á lójoojúmọ́. w23.05 29 ¶11-13
Wednesday, August 6
Ipa ọ̀nà àwọn olódodo dà bí ìmọ́lẹ̀ àárọ̀ tó ń mọ́lẹ̀ sí i títí di ọ̀sán gangan.—Òwe 4:18.
Láwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí, Jèhófà ń lo ètò rẹ̀ láti fi Ọ̀rọ̀ rẹ̀ tọ́ wa sọ́nà ká lè máa rìn ní “Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́” nìṣó. (Àìsá. 35:8; 48:17; 60:17) A lè sọ pé ìgbàkigbà tí ẹnì kan bá ti ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ló ti bẹ̀rẹ̀ sí í rìn ní “Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́.” Àwọn kan á rìn díẹ̀, wọ́n á sì kúrò lójú ọ̀nà náà. Àmọ́, àwọn míì pinnu pé àwọn á máa rìn lójú ọ̀nà náà títí wọ́n á fi dé ibi tí wọ́n ń lọ. Ibo ni wọ́n ń lọ? Ibi tí “Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́” máa gbé àwọn tó ń lọ sí ọ̀run dé ni “párádísè Ọlọ́run” tó wà ní ọ̀run. (Ìfi. 2:7) Àmọ́ ọ̀nà náà máa jẹ́ káwọn tó fẹ́ gbé ayé di pípé nígbà tí Ẹgbẹ̀rún Ọdún Ìṣàkóso Kristi bá máa fi parí. Tó o bá ń rìn ní ọ̀nà yẹn lónìí, má wẹ̀yìn o. Má sì kúrò lójú ọ̀nà náà títí tó o fi máa dénú ayé tuntun! w23.05 17 ¶15; 19 ¶16-18