-
Ìgbéyàwó Tó Ní Ọlá Lójú Ọlọ́run Àti ÈèyànIlé Ìṣọ́—2006 | October 15
-
-
Ìgbéyàwó Tó Ní Ọlá Lójú Ọlọ́run Àti Èèyàn
“Àsè ìgbéyàwó kan ṣẹlẹ̀ ní Kánà . . . Jésù àti àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ni a ké sí síbi àsè ìgbéyàwó náà pẹ̀lú.”—JÒHÁNÙ 2:1, 2.
1. Kí ni ìtàn tí Bíbélì sọ nípa ibi ìgbéyàwó tí Jésù lọ ní Kánà jẹ́ ká mọ̀?
JÉSÙ, àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ kan àti ìyá rẹ̀ mọ̀ pé táwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run bá ṣe ìgbéyàwó tó ní ọlá, ayẹyẹ ọ̀hún máa ń lárinrin. Kódà, Kristi mú kí ayẹyẹ ìgbéyàwó kan jẹ́ àrà ọ̀tọ̀ nítorí pé ibẹ̀ ló ti ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ àkọ́kọ́ tí Bíbélì sọ, èyí tó mú káwọn èèyàn túbọ̀ gbádùn ayẹyẹ náà. (Jòhánù 2:1-11) Ó ṣeé ṣe kó o ti lọ síbi ìgbéyàwó àwọn Kristẹni tí wọ́n fẹ́ jọ máa fi ayọ̀ sin Jèhófà gẹ́gẹ́ bí tọkọtaya, kó o sì gbádùn rẹ̀ gan-an. Ó sì lè jẹ́ pé ńṣe ni ìwọ fúnra rẹ ń fojú sọ́nà fún irú ìgbéyàwó bẹ́ẹ̀ tàbí kó jẹ́ pé o fẹ́ bá ọ̀rẹ́ rẹ kan múra ìgbéyàwó rẹ̀ sílẹ̀ kí nǹkan lè lọ bó ṣe yẹ. Kí lo lè ṣe kí ayẹyẹ náà lè lọ bó ṣe yẹ?
2. Kí ni Bíbélì sọ nípa ìgbéyàwó?
2 Àwọn Kristẹni mọ̀ pé ìmọ̀ràn tó wà nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run máa ń ṣèrànwọ́ gan-an fún ọkùnrin àti obìnrin tó ń múra àtiṣe ìgbéyàwó. (2 Tímótì 3:16, 17) Ká sòótọ́, Bíbélì ò ṣe kúlẹ̀kúlẹ̀ àlàyé nípa gbogbo ètò táwọn Kristẹni gbọ́dọ̀ tẹ̀ lé nígbà tí wọ́n bá fẹ́ ṣe ìgbéyàwó. Àwa náà yóò sì gbà pé kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀ torí pé àṣà ìbílẹ̀ àtàwọn ohun tí ìjọba ń béèrè máa ń yàtọ̀ láti ibì kan sí ibòmíràn àti láti àkókò kan sí àkókò mìíràn. Bí àpẹẹrẹ, nígbà ayé àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, kò sí ọ̀nà kan pàtó táwọn èèyàn gbà ń ṣe ìgbéyàwó. Lọ́jọ́ ìgbéyàwó, ọkọ ìyàwó yóò kàn mú aya rẹ̀ wá sílé rẹ̀ tàbí sílé bàbá rẹ̀ ni. (Jẹ́nẹ́sísì 24:67; Aísáyà 61:10; Mátíù 1:24) Mímú tí ọkọ ìyàwó mú ìyàwó rẹ̀ níṣojú gbogbo èèyàn yìí gan-an ni ìgbéyàwó wọn, láìsí pé wọ́n ń ṣe gbogbo ètò tí wọ́n máa ń ṣe nínú ọ̀pọ̀ jù lọ ìgbéyàwó lónìí.
3. Ayẹyẹ wo ni wọ́n ṣe ní Kánà tí Jésù mú kó túbọ̀ lárinrin?
3 Lójú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ìgbéyàwó lohun tí wọ́n ṣe yẹn jẹ́. Lẹ́yìn èyí, wọ́n lè wá pe àpèjẹ, irú èyí tí Jòhánù 2:1 mẹ́nu kàn. Bí wọ́n ṣe túmọ̀ ẹsẹ yẹn nínú ọ̀pọ̀ Bíbélì nìyí: “Wọ́n ṣe ìgbéyàwó kan ní Kánà.” Àmọ́, ìtúmọ̀ tó bá ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí wọ́n tú sí ìgbéyàwó mu jù lọ ni “àsè ìgbéyàwó.”a (Mátíù 22:2-10; 25:10; Lúùkù 14:8) Ìtàn yẹn fi hàn kedere pé Jésù lọ síbi àsè ìgbéyàwó àwọn Júù kan, ó sì ṣe ohun tó mú káwọn èèyàn túbọ̀ gbádùn ayẹyẹ náà. Àmọ́ o, kókó pàtàkì kan tó yẹ ká rántí ni pé ọ̀nà tí wọ́n gbà ń ṣe ìgbéyàwó láyé ìgbà yẹn yàtọ̀ sí ti ìsinsìnyí.
4. Irú ìgbéyàwó wo làwọn Kristẹni kan fẹ́, kí sì nìdí rẹ̀?
4 Ní ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè lóde òní, àwọn ohun kan wà tí òfin là kalẹ̀ táwọn Kristẹni tó bá fẹ́ ṣègbéyàwó gbọ́dọ̀ ṣe. Bí wọ́n bá ti ṣe é, wọ́n lè wá ṣègbéyàwó wọn lọ́nà èyíkéyìí tó bófin mu. Èyí lè jẹ́ ètò ráńpẹ́ kan tí adájọ́, olórí ìlú tàbí òjíṣẹ́ ìsìn kan tí Ìjọba Àpapọ̀ fún láṣẹ máa ṣe fáwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó náà. Irú ìgbéyàwó táwọn kan fẹ́ nìyẹn. Wọ́n lè sọ pé káwọn mélòó kan lára àwọn mọ̀lẹ́bí wọn tàbí àwọn ọ̀rẹ́ wọn tí wọ́n jẹ́ Ẹlẹ́rìí wà níbẹ̀ láti bá wọn tọwọ́ bọ̀wé tàbí kí wọ́n kàn wá bá wọn yọ̀ lọ́jọ́ ayẹyẹ pàtàkì náà. (Jeremáyà 33:11; Jòhánù 3:29) Bákan náà, àwọn Kristẹni mìíràn lè pinnu pé àwọn ò ní se àsè bẹ́ẹ̀ làwọn ò ní pe àpèjẹ ńlá tí wàhálà àti ìnáwó rẹ̀ máa ń pọ̀ gan-an. Dípò ìyẹn, wọ́n kàn lè se oúnjẹ níwọ̀nba fáwọn mọ̀lẹ́bí àtàwọn ọ̀rẹ́ wọn mélòó kan. Èyí tó wù kéèyàn ṣe níbẹ̀, ó yẹ ká rántí pé èrò àwọn Kristẹni mìíràn tí wọ́n dàgbà dénú lórí ọ̀rọ̀ yìí lè yàtọ̀ sí tiwa.—Róòmù 14:3, 4.
5. Kí nìdí tí ọ̀pọ̀ àwọn Kristẹni fi máa ń fẹ́ kí wọ́n sọ àsọyé nígbà ìgbéyàwó àwọn, kí ni àsọyé yìí sì máa ń dá lé lórí?
5 Èyí tó pọ̀ jù lọ lára àwọn Kristẹni tó fẹ́ ṣègbéyàwó ló máa ń fẹ́ kí wọ́n sọ àsọyé tó dá lórí Bíbélì nígbà ìgbéyàwó wọn.b Wọ́n mọ̀ pé Jèhófà ló dá ètò ìgbéyàwó sílẹ̀, ó sì ti pèsè ìmọ̀ràn ọlọgbọ́n sínú Ọ̀rọ̀ rẹ̀, èyí tó lè jẹ́ kí àárín tọkọtaya gún káwọn méjèèjì sì láyọ̀. (Jẹ́nẹ́sísì 2:22-24; Máàkù 10:6-9; Éfésù 5:22-33) Ọ̀pọ̀ tọkọtaya ló sì máa ń fẹ́ kí tẹbí-tọ̀rẹ́ tí wọ́n jẹ́ Kristẹni bá wọn nípìn-ín nínú ayọ̀ ọjọ́ náà. Síbẹ̀, ojú wo ló yẹ ká fi wo onírúurú òfin ìjọba, àwọn ọ̀nà tí wọ́n gbà ń ṣe ìgbéyàwó àtàwọn àṣà ìbílẹ̀ tó ti wà tipẹ́tipẹ́? A óò jíròrò bí wọ́n ṣe ń ṣe ètò ìgbéyàwó níbi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ nínú àpilẹ̀kọ yìí. Àwọn kan lè yàtọ̀ pátápátá sóhun tó o mọ̀ tàbí sóhun tí wọ́n ń ṣe lágbègbè rẹ. Síbẹ̀, wàá rí àwọn ìlànà tàbí àwọn ohun kan tó bára mu nínú wọn, èyí tó ṣe pàtàkì fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run.
Ìgbéyàwó Tó Ní Ọlá Gbọ́dọ̀ Bá Òfin Mu
6, 7. Kí nìdí tó fi yẹ ká fojú pàtàkì wo àwọn ohun tí òfin sọ nípa ìgbéyàwó ṣíṣe, báwo la sì ṣe lè fi hàn pé à ń ṣe èyí?
6 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Jèhófà lẹni tó dá ètò ìgbéyàwó sílẹ̀, ìjọba èèyàn ṣì láṣẹ, lọ́nà kan tàbí òmíràn, lórí ohun táwọn tó fẹ́ di tọkọtaya ń ṣe. Kò sì sóhun tó burú nínú èyí. Jésù sọ pé: “Ẹ san àwọn ohun ti Késárì padà fún Késárì, ṣùgbọ́n àwọn ohun ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.” (Máàkù 12:17) Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù náà sì sọ pé: “Kí olúkúlùkù ọkàn wà lábẹ́ àwọn aláṣẹ onípò gíga, nítorí kò sí ọlá àṣẹ kankan bí kò ṣe láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run; àwọn ọlá àṣẹ tí ó wà ni a gbé dúró sí àwọn ipò wọn aláàlà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”—Róòmù 13:1; Títù 3:1.
7 Ní ọ̀pọ̀ jù lọ orílẹ̀-èdè, Késárì, ìyẹn àwọn aláṣẹ, ló ń pinnu ẹni tó lè ṣègbéyàwó. Ìyẹn ló fi jẹ́ pé, táwọn Kristẹni méjì tí wọ́n lómìnira láti ṣègbéyàwó lójú ohun tí Ìwé Mímọ́ sọ bá fẹ́ ṣègbéyàwó, wọ́n máa ń rí i dájú pé àwọn ṣe ohun tí òfin ìjọba àgbègbè wọn sọ, bóyá kí wọ́n lọ gbàwé àṣẹ, kí wọ́n lo aṣojú ìjọba láti so wọ́n pọ̀, tàbí kí wọ́n lọ forúkọ ìgbéyàwó tí wọ́n ti ṣe sílẹ̀ lọ́dọ̀ ìjọba. Nígbà tí Késárì Ọ̀gọ́sítọ́sì sọ pé káwọn èèyàn lọ “forúkọ sílẹ̀,” Màríà àti Jósẹ́fù ṣègbọràn, ìyẹn ni wọ́n fi rìnrìn àjò lọ sí Bẹ́tílẹ́hẹ́mù “láti forúkọ sílẹ̀.”—Lúùkù 2:1-5.
8. Kí làwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà kì í ṣe, kí sì nìdí rẹ̀?
8 Báwọn Kristẹni méjì bá ti ṣègbéyàwó tó bófin mu tó sì jẹ́ èyí táwọn èèyàn tẹ́wọ́ gbà, wọ́n ti di ọ̀kan nìyẹn lójú Ọlọ́run. Ìdí nìyẹn táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà kì í fi í tún ìgbéyàwó tó bófin mu tí wọ́n ti ṣe tẹ́lẹ̀ ṣe ní Gbọ̀ngàn Ìjọba. Bákan náà, a kì í tún ẹ̀jẹ́ ìgbéyàwó kà nígbà tí a bá ń ṣe àyájọ́ ìgbéyàwó wa, irú bíi nígbà ọdún kẹẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n tàbí àádọ́ta ọdún ìgbéyàwó. (Mátíù 5:37) (Àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì kan kì í fojú pàtàkì wo ìgbéyàwó tí wọ́n bá ṣe lọ́dọ̀ ìjọba bó tiẹ̀ jẹ́ pé ó bófin mu. Wọ́n sọ pé irú ìgbéyàwó bẹ́ẹ̀ kò lẹ́sẹ̀ ńlẹ̀ torí pé àlùfáà tàbí olórí ìsìn kan kọ́ ló darí ètò náà tàbí ló so àwọn méjèèjì pọ̀.) Ní ọ̀pọ̀ ilẹ̀, ìjọba fún àwọn kan lára àwọn òjíṣẹ́ tó jẹ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà láṣẹ láti so ọkùnrin àti obìnrin pọ̀ gẹ́gẹ́ bíi tọkọtaya. Níbi tí ìjọba bá ti yọ̀ọ̀da irú nǹkan bẹ́ẹ̀, òjíṣẹ́ náà lè ṣe èyí pa pọ̀ pẹ̀lú àsọyé ìgbéyàwó ní Gbọ̀ngàn Ìjọba, ìyẹn ibi táwọn Ẹlẹ́rìí ti ń pàdé fún ìjọsìn tòótọ́ ládùúgbò kọ̀ọ̀kan. Ibẹ̀ jẹ́ ibi tó yẹ fún sísọ àsọyé lórí ètò ìgbéyàwó tí Jèhófà Ọlọ́run dá sílẹ̀.
9. (a) Tó bá dọ̀rọ̀ ìgbéyàwó lọ́dọ̀ ìjọba, kí làwọn Kristẹni tí wọ́n fẹ́ ṣègbéyàwó lè ṣe tó bá wù wọ́n? (b) Báwo ni ètò ìgbéyàwó ṣe lè kan àwọn alàgbà?
9 Láwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ohun tí òfin sọ ni pé káwọn tó bá fẹ́ ṣègbéyàwó lọ ṣe é ní ọ́fíìsì ìjọba tàbí kí aṣojú tí ìjọba yàn so wọ́n pọ̀. Lẹ́yìn èyí, àwọn Kristẹni sábà máa ń ṣètò àsọyé ìgbéyàwó nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba lọ́jọ́ kan náà tàbí lọ́jọ́ tó tẹ̀ lé e. (Kò yẹ kí wọ́n jẹ́ kí ọjọ́ púpọ̀ wà láàárín ọjọ́ tí wọ́n ṣe ìgbéyàwó lọ́dọ̀ ìjọba àti ọjọ́ tí wọ́n máa sọ àsọyé ìgbéyàwó, nítorí pé ìgbéyàwó tí wọ́n ṣe lọ́dọ̀ ìjọba ti sọ wọ́n di tọkọtaya lójú Ọlọ́run àti èèyàn, títí kan ìjọ Kristẹni.) Bó bá wu àwọn tó fẹ́ ṣe ìgbéyàwó lọ́dọ̀ ìjọba (ìyẹn Ìgbéyàwó Níbàámu Pẹ̀lú Òfin Ìgbéyàwó) pé kí wọ́n gbọ́ àsọyé ìgbéyàwó ní Gbọ̀ngàn Ìjọba kan, wọ́n ní láti gbàṣẹ lọ́wọ́ àwọn alàgbà tí wọ́n jẹ́ Ìgbìmọ̀ Iṣẹ́ Ìsìn Ìjọ ibẹ̀ ṣáájú. Yàtọ̀ sí pé àwọn alàgbà wọ̀nyí á rí i dájú pé àwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó náà jẹ́ ẹni tó ní orúkọ rere, wọ́n á tún rí i dájú pé àkókò tí ìgbéyàwó náà máa bọ́ sí kò forí gbárí pẹ̀lú àkókò ìpàdé àtàwọn ètò mìíràn tí wọ́n fẹ́ ṣe nínú gbọ̀ngàn yẹn. (1 Kọ́ríńtì 14:33, 40) Àwọn alàgbà náà á tún gbé àwọn ohun táwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó fẹ́ ṣe nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba lọ́jọ́ náà yẹ̀ wò, wọ́n á sì pinnu bóyá kí wọ́n ṣèfilọ̀ fáwọn ará pé àwọn kan fẹ́ lo gbọ̀ngàn náà.
10. Bó bá jẹ́ pé ìgbéyàwó lọ́dọ̀ ìjọba làwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó fẹ́ ṣe, báwo nìyẹn ṣe máa kan àsọyé ìgbéyàwó?
10 Alàgbà tó máa sọ àsọyé náà yóò gbìyànjú láti rí i pé ọ̀rọ̀ náà tuni lára, ó gbéni ró, ó sì buyì kúnni. Bí wọ́n bá ti ṣègbéyàwó lọ́dọ̀ ìjọba, alàgbà náà yóò sọ fáwọn olùgbọ́ pé wọ́n ti ṣègbéyàwó lọ́nà tó bá òfin Késárì mu ṣáájú. Bí wọn ò bá ka ẹ̀jẹ́ ìgbéyàwó nígbà yẹn, wọ́n lè ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà àsọyé náà.c Bí wọ́n bá sì ti ka ẹ̀jẹ́ nígbà tí wọ́n ṣègbéyàwó níwájú aṣojú ìjọba ṣùgbọ́n tí wọ́n fẹ́ ka ẹ̀jẹ́ níwájú Jèhófà àti ìjọ, kí wọ́n fi ọ̀rọ̀ tó tẹ̀ lé e yìí bẹ̀rẹ̀ ẹ̀jẹ́ náà: “Mo ti jẹ́jẹ̀ẹ́ ní [sọ àkókò tàbí ọjọ́] pé . . . ,” kí èyí lè fi hàn pé a “ti so [wọ́n] pọ̀” gẹ́gẹ́ bí tọkọtaya ṣáájú àkókò yẹn.—Mátíù 19:6; 22:21.
11. Láwọn ibì kan, báwo ni wọ́n ṣe ń ṣe ìgbéyàwó, báwo lèyí yóò sì ṣe kan àsọyé ìgbéyàwó?
11 Láwọn ibì kan, òfin lè má sọ ọ́ di dandan pé kí ẹnì kan ṣẹ̀ṣẹ̀ so àwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó pọ̀ lọ́nà pàtó kan, ì báà tiẹ̀ jẹ́ aṣojú ìjọba pàápàá. Bí wọ́n bá ti lè mú fọ́ọ̀mù ìforúkọsílẹ̀ ìgbéyàwó tí wọ́n ti buwọ́ lù fún aṣojú ìjọba, tí aṣojú ìjọba sì fún wọn ní ìwé ẹ̀rí ìgbéyàwó wọn, wọ́n ti ṣègbéyàwó nìyẹn. Ohun tí wọ́n ṣe yìí ló máa jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé wọ́n ti di tọkọtaya, ọjọ́ tó sì wà lórí ìwé ẹ̀rí náà ni yóò jẹ́ ọjọ́ ìgbéyàwó wọn. Bá a ṣe sọ lókè, àwọn tí wọ́n bá ṣègbéyàwó lọ́nà yìí lè ṣètò pé kété lẹ́yìn gbígba ìwé ẹ̀rí yẹn, àwọn á lọ gbọ́ àsọyé ìgbéyàwó ní Gbọ̀ngàn Ìjọba. Arákùnrin tó dàgbà dénú tí wọ́n yàn pé kó sọ àsọyé náà yóò sọ fún àwọn tó wà nínú gbọ̀ngàn náà pé ìwé ẹ̀rí ìgbéyàwó tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ gbà ti fi hàn pé wọ́n ti di tọkọtaya ṣáájú ìgbà àsọyé náà. Tí wọ́n bá máa ka ẹ̀jẹ́ rárá, wọ́n ní láti jẹ́ kó bá ohun tá a sọ ní ìpínrọ̀ 10 àti àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé ibẹ̀ mu. Àwọn tó wà ní Gbọ̀ngàn Ìjọba yóò bá tọkọtaya náà yọ̀ wọn yóò sì jàǹfààní nínú ìmọ̀ràn Ìwé Mímọ́.—Orin Sólómọ́nì 3:11.
Ìgbéyàwó Ti Ìbílẹ̀ àti Ìgbéyàwó Lọ́dọ̀ Ìjọba
12. Kí ni ìgbéyàwó ti ìbílẹ̀, kí ló sì bọ́gbọ́n mu kí tọkọtaya ṣe lẹ́yìn irú ìgbéyàwó bẹ́ẹ̀?
12 Láwọn orílẹ̀-èdè kan, ìgbéyàwó ti ìbílẹ̀ làwọn èèyàn máa ń ṣe. Kì í ṣe pé kí ọkùnrin àtobìnrin máa jọ gbé pa pọ̀ là ń sọ o, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe pé káwọn méjì kàn mú ara wọn ní ọkọ àtìyàwó, èyí tí wọ́n fàyè gbà láwọn ibì kan àmọ́ tí kò bá òfin mu délẹ̀délẹ̀.d Ìgbéyàwó ti ìbílẹ̀ tí à ń sọ níbí ni ìgbéyàwó tó bá àṣà ìbílẹ̀ táwọn èèyàn mọ̀ dáadáa lágbègbè kan mu. Nínú irú ìgbéyàwó yìí, wọ́n lè ní kí ọkọ kọ́kọ́ san owó orí ìyàwó fún àna rẹ̀. Èyí ló máa fi hàn pé àwọn méjèèjì ti ṣègbéyàwó tó bófin mu tó sì bá ìlànà Ìwé Mímọ́ mu. Ìjọba ka irú ìgbéyàwó ti ìbílẹ̀ bẹ́ẹ̀ sí ìgbéyàwó tó lẹ́sẹ̀ ńlẹ̀, tó bófin mu, tó sì ti sọ àwọn méjèèjì di tọkọtaya. Lẹ́yìn èyí, wọ́n lè lọ forúkọ ìgbéyàwó wọn sílẹ̀ lọ́dọ̀ ìjọba, kí wọ́n sì gba ìwé ẹ̀rí. Fífi orúkọ ìgbéyàwó sílẹ̀ lọ́dọ̀ ìjọba lọ́nà yìí yóò ṣàǹfààní fún tọkọtaya náà lọ́jọ́ iwájú, tàbí fún ìyàwó bó bá di pé ọkọ kú, tàbí fáwọn ọmọ tí wọ́n máa bí. Ìjọ yóò gba ẹnikẹ́ni tó bá ṣe ìgbéyàwó ìbílẹ̀ nímọ̀ràn láti lọ forúkọ ìgbéyàwó rẹ̀ sílẹ̀ láìjáfara. Àní nínú Òfin Mósè pàápàá, ó jọ pé àwọn èèyàn máa ń lọ forúkọ ìgbéyàwó tàbí ọmọ tí wọ́n bá bí sílẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn aláṣẹ.—Mátíù 1:1-16.
13. Lẹ́yìn ìgbéyàwó ti ìbílẹ̀, àwọn ìlànà wo ló yẹ ká tẹ̀ lé tí wọ́n bá máa sọ àsọyé ìgbéyàwó?
13 Gbàrà tí wọ́n bá ti so ọkùnrin àti obìnrin pọ̀ nígbà ìgbéyàwó ìbílẹ̀ ni wọ́n ti di tọkọtaya. Bá a ṣe sọ lókè, àwọn Kristẹni tí wọ́n bá ṣe irú ìgbéyàwó tó bófin mu bẹ́ẹ̀ lè fẹ́ gbọ́ àsọyé ìgbéyàwó kí wọ́n sì ka ẹ̀jẹ́ ìgbéyàwó ní Gbọ̀ngàn Ìjọba. Bí wọ́n bá máa ṣe bẹ́ẹ̀, alásọyé yóò sọ nígbà àsọyé náà pé tọkọtaya náà ti di ọkọ àti aya ṣáájú àkókò yẹn níbàámu pẹ̀lú òfin Késárì. Ìgbéyàwó kan ṣoṣo ni wọ́n ṣe, ìyẹn ni ìgbéyàwó ti ìbílẹ̀. Ìgbéyàwó yìí bá òfin mu ó sì lẹ́sẹ̀ ńlẹ̀, àsọyé ìgbéyàwó kan ṣoṣo la ó sì sọ. Bá ò bá jẹ́ kí ọjọ́ ìgbéyàwó àti àsọyé yìí jìn síra wọn, tó bá ṣeé ṣe kó jẹ́ ọjọ́ kan náà, á jẹ́ kí ìgbéyàwó àwa Kristẹni túbọ̀ ní ọlá lójú àwọn èèyàn.
14. Kí ni Kristẹni kan lè ṣe tí òfin bá yọ̀ọ̀da pé èèyàn lè ṣègbéyàwó ti ìbílẹ̀ tàbí ti ìjọba?
14 Láwọn ilẹ̀ kan tí wọ́n ti ka ìgbéyàwó ti ìbílẹ̀ sóhun tó bófin mu, òfin tún sọ pé èèyàn lè ṣe ìgbéyàwó lọ́dọ̀ ìjọba. Aṣojú ìjọba kan ló sábà máa ń so tọkọtaya pọ̀ nínú irú ìgbéyàwó yìí, wọ́n sì lè sọ pé káwọn méjèèjì ka ẹ̀jẹ́ kí wọ́n sì tọwọ́ bọ̀wé. Àwọn Kristẹni kan fẹ́ràn ìgbéyàwó tí wọ́n á ṣe lọ́dọ̀ aṣojú ìjọba yìí ju ìgbéyàwó ti ìbílẹ̀ lọ. Òfin ò sọ pé káwọn tó fẹ́ di tọkọtaya ṣe ìgbéyàwó méjèèjì yìí pa pọ̀ torí pé méjèèjì ló bófin mu. Ohun tí ìpínrọ̀ 9 àti 10 sọ nípa gbígbọ́ àsọyé ìgbéyàwó àti kíka ẹ̀jẹ́ la máa tẹ̀ lé nínú irú ìgbéyàwó yìí náà. Kókó ibẹ̀ ni pé kí tọkọtaya rí i pé ìgbéyàwó tó ní ọlá lójú Ọlọ́run àti èèyàn làwọn ṣe.—Lúùkù 20:25; 1 Pétérù 2:13, 14.
Ẹ Jẹ́ Kí Ọlá Wà Nínú Ìgbéyàwó Yín
15, 16. Báwo la ṣe lè jẹ́ kí ọlá wà nínú ìgbéyàwó?
15 Nígbà tí ìṣòro wà láàárín ọba ilẹ̀ Páṣíà kan àti ìyàwó rẹ̀, ọ̀kan lára àwọn bọ́bajíròrò tó ń jẹ́ Mẹ́múkánì dámọ̀ràn ohun kan tó lè ṣe tọkọtaya láǹfààní, ìyẹn ni pé ‘kí gbogbo àwọn aya máa fi ọlá fún ọkọ wọn.’ (Ẹ́sítérì 1:20) Nínú ìgbéyàwó àwọn Kristẹni, kò yẹ kó jẹ́ pé ọba tó jẹ́ ẹ̀dá èèyàn ló máa ṣẹ̀ṣẹ̀ pàṣẹ pé kí wọ́n tẹ̀ lé ìmọ̀ràn yẹn. Ńṣe ló yẹ káwọn aya máa bọlá fáwọn ọkọ wọn. Lọ́nà kan náà, ó yẹ káwọn ọkọ tí wọ́n jẹ́ Kristẹni máa fi ọlá fáwọn aya wọn, kí wọ́n sì máa yìn wọ́n. (Òwe 31:11, 30; 1 Pétérù 3:7) Kì í ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún lẹ́yìn téèyàn ti ṣègbéyàwó ló yẹ kó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa fi ọlá hàn nínú ìgbéyàwó rẹ̀. Àtìbẹ̀rẹ̀ ló ti yẹ kó máa fi í hàn, àní látọjọ́ ìgbéyàwó.
16 Ọkọ àti ìyàwó nìkan kọ́ ló yẹ kó fi ọlá hàn lọ́jọ́ ìgbéyàwó wọn. Bí alàgbà bá máa sọ àsọyé ìgbéyàwó, ó ní láti rí i pé àsọyé yìí ní ọlá pẹ̀lú. Tọkọtaya náà ló máa darí ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí. Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé àsọyé náà wà lára ohun tó máa fi bọlá fún wọn, kò yẹ kí alásọyé náà sọ ọ́ di ọ̀rọ̀ àwàdà tàbí kó máa pa ìtàn àlọ́ lásán. Kò yẹ kó sọ àwọn ohun tó jẹ́ ọ̀rọ̀ àṣírí nípa tọkọtaya náà, èyí tó lè kó ìtìjú bá àwọn àtàwọn olùgbọ́. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ló yẹ kó fi ọ̀yàyà sọ̀rọ̀, kó sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà gbéni ró. Kó tún rí i pé Ọlọ́run tó dá ètò ìgbéyàwó sílẹ̀ àti ìmọ̀ràn rẹ̀ tó ta yọ gbogbo ìmọ̀ràn ẹ̀dá ni òun gbé lárugẹ nínú ọ̀rọ̀ náà. Kò sí àní-àní pé àsọyé ìgbéyàwó tó buyì kúnni tí alàgbà náà bá sọ yóò wà lára ohun tó máa jẹ́ kí ìgbéyàwó náà bọlá fún Jèhófà Ọlọ́run.
17. Kí nìdí tí ohun tí òfin béèrè fi jẹ́ ara ètò ìgbéyàwó àwọn Kristẹni?
17 Wàá kíyè sí i pé nínú àpilẹ̀kọ yìí, a sọ̀rọ̀ púpọ̀ gan-an nípa onírúurú ohun tí òfin béèrè téèyàn bá fẹ́ ṣègbéyàwó. Àwọn kan lára ohun tá a sọ yìí lè má bá ohun tí wọ́n ń ṣe lágbègbè rẹ mu. Síbẹ̀, ó yẹ kí gbogbo wa máa rántí pé ó ṣe pàtàkì pé kí ètò ìgbéyàwó táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń ṣe fi hàn pé à ń tẹ̀ lé òfin Késárì, ìyẹn òfin ìjọba ibi tá à ń gbé. (Lúùkù 20:25) Pọ́ọ̀lù rọ̀ wá pé: “Ẹ fi ẹ̀tọ́ gbogbo ènìyàn fún wọn, ẹni tí ó béèrè fún owó orí, ẹ fún un ní owó orí; ẹni tí ó béèrè fún owó òde, ẹ fún un ní owó òde; . . . ẹni tí ó béèrè fún ọlá, ẹ fún un ní irúfẹ́ ọlá bẹ́ẹ̀.” (Róòmù 13:7) Bẹ́ẹ̀ ni o, ó dára kó jẹ́ pé látọjọ́ ìgbéyàwó ni Kristẹni yóò ti máa fi ọlá fún ètò tí Ọlọ́run ti ṣe fún àkókò tá a wà yìí.
18. Kí lohun táwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó lè ṣe tó bá wù wọ́n tá a máa gbé yẹ̀ wò, ibo la sì ti lè rí àlàyé nípa rẹ̀?
18 Lẹ́yìn tí ọ̀pọ̀ Kristẹni bá ti ṣe ìgbéyàwó, àsè ìgbéyàwó tàbí àpèjẹ ló sábà máa ń tẹ̀ lé e. Má gbàgbé pé Jésù lọ sí ọ̀kan lára irú àwọn àsè bẹ́ẹ̀. Bí tọkọtaya kan bá wá ṣètò irú àpèjẹ bẹ́ẹ̀, báwo ni ìmọ̀ràn Bíbélì ṣe lè ràn wọ́n lọ́wọ́ láti rí i pé ìyẹn náà yóò bọlá fún Ọlọ́run, kò sì ní kó ẹ̀gàn bá àwọn tó ṣẹ̀ṣẹ̀ ṣègbéyàwó náà àti ìjọ Kristẹni? Kókó yẹn gan-an ni àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé èyí yóò jíròrò.e
-
-
Jẹ́ Kí Ọ̀nà Tí o Gbà Ń gbé Ìgbésí Ayé Rẹ Fi Hàn Pé o Ní Ìgbàgbọ́Ilé Ìṣọ́—2006 | October 15
-
-
Jẹ́ Kí Ọ̀nà Tí o Gbà Ń gbé Ìgbésí Ayé Rẹ Fi Hàn Pé o Ní Ìgbàgbọ́
“Ìgbàgbọ́, bí kò bá ní àwọn iṣẹ́, jẹ́ òkú nínú ara rẹ̀.”—JÁKỌ́BÙ 2:17.
1. Kí nìdí táwọn Kristẹni ọ̀rúndún kìíní fi fi iṣẹ́ ti ìgbàgbọ́ wọn lẹ́yìn?
Ó FẸ́RẸ̀Ẹ́ jẹ́ pé gbogbo àwọn Kristẹni ọ̀rúndún kìíní ni wọ́n gbé ìgbésí ayé wọn lọ́nà tó fi hàn pé wọ́n ní ìgbàgbọ́. Ọmọ ẹ̀yìn náà Jákọ́bù rọ gbogbo àwọn Kristẹni pé: “Ẹ di olùṣe ọ̀rọ̀ náà, kì í sì í ṣe olùgbọ́ nìkan.” Ó fi kún un pé: “Gẹ́gẹ́ bí ara láìsí ẹ̀mí ti jẹ́ òkú, bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ni ìgbàgbọ́ láìsí àwọn iṣẹ́ jẹ́ òkú.” (Jákọ́bù 1:22; 2:26) Ní nǹkan bí ọdún márùndínlógójì lẹ́yìn tí Jákọ́bù sọ ọ̀rọ̀ yìí nínú lẹ́tà tó kọ, ọ̀pọ̀ àwọn Kristẹni ṣì ń ṣe àwọn iṣẹ́ rere tó fi hàn pé wọ́n ní ìgbàgbọ́. Àmọ́ o, àwọn kan ò ṣe bẹ́ẹ̀ ní tiwọn. Jésù yin ìjọ tó wà ní Símínà, ṣùgbọ́n ó sọ fún ọ̀pọ̀ lára àwọn tó wà nínú ìjọ tó wà ní Sádísì pé: “Mo mọ àwọn iṣẹ́ rẹ, pé ìwọ ní orúkọ pé o wà láàyè, ṣùgbọ́n o ti kú.”—Ìṣípayá 2:8-11; 3:1.
2. Àwọn ìbéèrè wo ló yẹ káwa Kristẹni bi ara wa nípa ìgbàgbọ́ wa?
2 Ìdí rèé tí Jésù fi rọ àwọn ará Sádísì pé kí wọ́n máa ṣe ohun tí yóò fi ẹ̀rí hàn pé wọ́n ṣì ní ìfẹ́ tí wọ́n ní fún òtítọ́ níbẹ̀rẹ̀, kí wọ́n sì jẹ́ kí níní àjọṣe tó dára pẹ̀lú Ọlọ́run jẹ wọ́n lógún. Ọ̀rọ̀ ìṣírí Jésù yìí kan àwọn tó máa kà á lẹ́yìn ìgbà yẹn. (Ìṣípayá 3:2, 3) Ẹnì kọ̀ọ̀kan wa lè bi ara rẹ̀ pé: ‘Báwo làwọn iṣẹ́ tèmi ṣe rí? Ǹjẹ́ mò ń sa gbogbo ipá mi láti jẹ́ kó hàn nínú gbogbo ohun tí mò ń ṣe pé mo ní ìgbàgbọ́, àní nínú àwọn ohun tí kò fi bẹ́ẹ̀ jẹ mọ́ iṣẹ́ ìwàásù tàbí ìpàdé ìjọ pàápàá?’ (Lúùkù 16:10) Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan là ń ṣe nígbèésí ayé tó lè fi hàn pé a ní ìgbàgbọ́. Àmọ́, ẹ jẹ́ ká sọ̀rọ̀ lórí ẹyọ kan ṣoṣo, ìyẹn ni àwọn àpèjẹ wa, títí kan èyí tó máa ń wáyé lẹ́yìn ìgbéyàwó àwọn Kristẹni.
Àwọn Àpèjẹ Kékeré
3. Kí ni Bíbélì sọ nípa àpèjẹ?
3 Inú ọ̀pọ̀ lára wa máa ń dùn tí wọ́n bá pè wá síbi táwọn Kristẹni aláyọ̀ kóra jọ sí. Jèhófà jẹ́ “Ọlọ́run aláyọ̀” tó fẹ́ káwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ láyọ̀. (1 Tímótì 1:11) Ó fi ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ darí Sólómọ́nì láti kọ ọ̀rọ̀ kan tó jẹ́ òótọ́ pọ́ńbélé sínú Bíbélì. Ọ̀rọ̀ náà ni pé: “Èmi alára sì gbóríyìn fún ayọ̀ yíyọ̀, nítorí pé aráyé kò ní nǹkan kan tí ó sàn lábẹ́ oòrùn ju pé kí wọ́n máa jẹ, kí wọ́n sì máa mu, kí wọ́n sì máa yọ̀, kí ó sì máa bá wọn rìn nínú iṣẹ́ àṣekára wọn ní àwọn ọjọ́ ìgbésí ayé wọn.” (Oníwàásù 3:1, 4, 13; 8:15) Èèyàn lè yọ irú ayọ̀ bẹ́ẹ̀ nígbà tóun àtàwọn tí wọ́n wà nínú ìdílé rẹ̀ bá ń jẹun pọ̀ tàbí tó bá wà níbi àpèjẹ kéékèèké mìíràn táwọn olùjọsìn tòótọ́ ṣètò.—Jóòbù 1:4, 5, 18; Lúùkù 10:38-42; 14:12-14.
4. Kí ló yẹ kí ẹni tó bá pe àpèjẹ fi sọ́kàn?
4 Bó bá jẹ́ pé ìwọ lo fẹ́ pe irú àpèjẹ bẹ́ẹ̀, o ní láti gbé gbogbo ètò tó o ṣe yẹ̀ wò dáadáa, kódà bó bá jẹ́ pé ìwọ̀nba àwọn Ẹlẹ́rìí díẹ̀ lo fẹ́ pè kẹ́ ẹ lè jọ jẹun kẹ́ ẹ sì jọ fọ̀rọ̀ jomi toro ọ̀rọ̀. (Róòmù 12:13) Rí i pé ‘ohun gbogbo ṣẹlẹ̀ lọ́nà tí ó bójú mu,’ kó o sì tún rí i pé “ọgbọ́n tí ó wá láti òkè” lẹ fi ń ṣe gbogbo ohun tó wáyé níbẹ̀. (1 Kọ́ríńtì 14:40; Jákọ́bù 3:17) Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ̀wé pé: “Yálà ẹ ń jẹ tàbí ẹ ń mu tàbí ẹ ń ṣe ohunkóhun mìíràn, ẹ máa ṣe ohun gbogbo fún ògo Ọlọ́run. Ẹ máa fà sẹ́yìn kúrò nínú dídi okùnfà ìkọ̀sẹ̀.” (1 Kọ́ríńtì 10:31, 32) Kí ni díẹ̀ lára àwọn nǹkan tó yẹ ká gbé yẹ̀ wò? Bó o bá gbé irú nǹkan bẹ́ẹ̀ yẹ̀ wò ṣáájú, wàá mọ ohun tó o lè ṣe láti rí i dájú pé ohun tí ìwọ àtàwọn àlejò rẹ bá ṣe yóò fi hàn pé ẹ̀ ń fi ohun tí Bíbélì kọ́ yín sílò.—Róòmù 12:2.
Báwo Ni Nǹkan Ṣe Máa Lọ Sí Níbi Àpèjẹ Náà?
5. Kí nìdí tí ẹni tó pe àpèjẹ fi ní láti ronú jinlẹ̀ nípa pípèsè ọtí àti orin?
5 Ọ̀pọ̀ àwọn tó pe àpèjẹ máa ń ronú nípa bóyá káwọn fún àwọn àlejò wọn ní ọtí tàbí káwọn má ṣe bẹ́ẹ̀. Kò dìgbà tí ọtí bá wà níbi àpèjẹ kí irú àpèjẹ bẹ́ẹ̀ tó dùn. Wàá rántí pé Jésù pèsè oúnjẹ fún ogunlọ́gọ̀ èèyàn tó wá bá a, ó fún wọn ní búrẹ́dì àti ẹja. Ìtàn yẹn ò sọ pé ó pèsè wáìnì lọ́nà ìyanu, bó tilẹ̀ jẹ́ pé a mọ̀ pé ó lè ṣe é. (Mátíù 14:14-21) Bó o bá fẹ́ pèsè ọtí níbi àpèjẹ, jẹ́ kó wà ní ìwọ̀ntúnwọ̀nsì, kó o sì rí i pé àwọn ohun mímu míì wà yàtọ̀ sí ọtí fáwọn tó bá nífẹ̀ẹ́ sí irú rẹ̀. (1 Tímótì 3:2, 3, 8; 5:23; 1 Pétérù 4:3) O ò gbọ́dọ̀ ṣe ohunkóhun tó máa jẹ́ kí ẹnikẹ́ni rò pé òun ní láti mu ọtí tó jẹ́ ohun tó lè “buni ṣán gẹ́gẹ́ bí ejò.” (Òwe 23:29-32) Bí orin bá máa wà níbẹ̀ ńkọ́? Bí orin bá máa wà níbẹ̀, rí i pé o fara balẹ̀ ṣe àṣàyàn àwọn orin tó o máa lò, kó o sì wo ìlù tí wọ́n lù nínú rẹ̀ àti ọ̀rọ̀ inú orin náà. (Kólósè 3:8; Jákọ́bù 1:21) Ọ̀pọ̀ àwọn Kristẹni ti rí i pé gbígbọ́ àwọn orin atunilára tí ètò Ọlọ́run ṣe, ìyẹn Kingdom Melodies, tàbí kíkọ irú orin bẹ́ẹ̀ pa pọ̀ máa ń jẹ́ kí àpèjẹ dùn. (Éfésù 5:19, 20) Bákan náà, o tún ní láti rí i pé ò ń kíyè sí bí orin náà ṣe lọ sókè sí látìgbàdégbà kí orin náà má bàa ṣèdíwọ́ fáwọn àlejò rẹ tó ń fọ̀rọ̀ wérọ̀ àtàwọn ará àdúgbò.—Mátíù 7:12.
6. Báwo lẹni tó pe àpèjẹ ṣe lè jẹ́ kó hàn pé ìgbàgbọ́ òun kì í ṣe òkú nígbà táwọn èèyàn bá ń fọ̀rọ̀ wérọ̀ tàbí táwọn nǹkan mìíràn bá ń ṣẹlẹ̀ níbẹ̀?
6 Nígbà táwọn Kristẹni bá kóra jọ fún àpèjẹ, wọ́n lè sọ̀rọ̀ nípa onírúurú nǹkan, kí wọ́n ka àwọn ohun kan jáde látinú ìwé tàbí kí wọ́n sọ àwọn ìrírí tí ń gbéni ró. Bó bá di pé àwọn tó wà níbẹ̀ fẹ́ máa sọ ohun tí kò bójú mu, ẹni tó pe àpèjẹ náà lè rọra fi ọgbọ́n darí ìfọ̀rọ̀wérọ̀ náà sí ohun tó bá ìlànà Bíbélì mu. Ó tún yẹ kó rí i dájú pé ẹnì kan ṣoṣo kọ́ ló ń dá gbogbo ọ̀rọ̀ sọ. Bó bá kíyè sí i pé ẹnì kan fẹ́ máa sọ̀rọ̀ ṣáá, ó lè rọra fi ọgbọ́n sọ ohun tó máa jẹ́ káwọn mìíràn lè dá sí ọ̀rọ̀ náà, bóyá kó sọ pé káwọn ọmọdé sọ èrò wọn lórí àwọn nǹkan kan tàbí kó ju ọ̀rọ̀ kan sílẹ̀ táwọn èèyàn máa dá sí. Àtọmọdé àtàgbà ni inú wọn máa dùn bí àpèjẹ bá rí báyìí. Bí ìwọ tó o pe àpèjẹ bá fi ọgbọ́n àti òye ṣe ètò náà, ‘ìfòyebánilò rẹ á di mímọ̀’ fún àwọn tó wà níbẹ̀. (Fílípì 4:5) Wọ́n á rí i pé ìgbàgbọ́ rẹ kì í ṣe òkú, pé ó ń nípa lórí gbogbo ohun tó ò ń ṣe.
Ìgbéyàwó àti Àpèjẹ Ìgbéyàwó
7. Kí nìdí tí ètò ìgbéyàwó àtàwọn ayẹyẹ míì tó máa wáyé lákòókò náà fi gba àròjinlẹ̀?
7 Ìgbéyàwó àwa Kristẹni jẹ́ ohun pàtàkì kan tó ń fún wa láyọ̀. Àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run láyé àtijọ́ fi tayọ̀tayọ̀ kópa nínú irú ayẹyẹ alárinrin bẹ́ẹ̀ àti àsè tó ń bá a rìn. Kódà, Jésù àtàwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pàápàá lọ síbi ayẹyẹ bẹ́ẹ̀. (Jẹ́nẹ́sísì 29:21, 22; Jòhánù 2:1, 2) Àmọ́ o, láwọn ọdún àìpẹ́ yìí, àwọn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ níbi ìgbéyàwó ti jẹ́ ká rí i kedere pé a ní láti gbé gbogbo ètò tá à ń ṣe yẹ̀ wò dáadáa tá a bá fẹ́ kí ohun tó máa wáyé níbi ayẹyẹ ìgbéyàwó wa fi hàn pé Kristẹni tó lóye ni wá àti pé à ń ṣe nǹkan ní ìwọ̀ntúnwọ̀nsì. Ó ṣe tán, ayẹyẹ ìgbéyàwó jẹ́ ara irú àwọn ohun tí Kristẹni kan lè lọ́wọ́ sí, tó sì lè lo àǹfààní èyí láti fi hàn pé ìgbàgbọ́ òun kì í ṣe òkú.
8, 9. Báwo lohun tó ń ṣẹlẹ̀ níbi ọ̀pọ̀ ìgbéyàwó ṣe fi hàn kedere pé òótọ́ lohun tó wà nínú 1 Jòhánù 2:16, 17?
8 Ọ̀pọ̀ àwọn tí kò mọ àwọn ìlànà Bíbélì tàbí tí wọn kò kà á sí máa ń wo ìgbà ìgbéyàwó gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí wọ́n lè ṣe bó ṣe wù wọ́n, láìsí pé ẹnikẹ́ni ń ká wọn lọ́wọ́ kò. Nínú ìwé ìròyìn kan tí wọ́n ṣe nílẹ̀ Yúróòpù, obìnrin kan tó ṣẹ̀ṣẹ̀ ṣègbéyàwó sọ pé wọ́n ṣe ayẹyẹ ìgbéyàwó òun ayé gbọ́ ọ̀run mọ̀, ó ní: ‘Inú kẹ̀kẹ́ ẹṣin tí ẹṣin mẹ́rin ń fà la wà lọ́jọ́ náà. Kẹ̀kẹ́ ẹṣin méjìlá ló tẹ̀ lé wa, bẹ́ẹ̀ làwọn olórin náà wà nínú kẹ̀kẹ́ ẹṣin tiwọn. Lẹ́yìn èyí la wá lọ jẹ oúnjẹ àjẹpọ́nnulá, tá a sì gbádùn orin aládùn. Ayẹyẹ yẹn ti lọ wà jù. Bí mo ṣe fẹ́ gan-an ló rí, ńṣe ni mo dà bí ayaba lọ́jọ́ náà.’
9 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àṣà ibì kọ̀ọ̀kan máa ń yàtọ̀, ohun tó sọ yẹn fi hàn kedere pé òótọ́ lohun tí àpọ́sítélì Jòhánù kọ sílẹ̀, ó ní: “Ohun gbogbo tí ń bẹ nínú ayé—ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ojú àti fífi àlùmọ́ọ́nì ìgbésí ayé ẹni hàn sóde lọ́nà ṣekárími—kò pilẹ̀ṣẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Baba, ṣùgbọ́n ó pilẹ̀ṣẹ̀ láti ọ̀dọ̀ ayé.” Ǹjẹ́ o rò pé àwọn Kristẹni méjì tí wọ́n dàgbà dénú á fẹ́ ṣe ìgbéyàwó tó jẹ́ pé ayé á gbọ́ ọ̀run á mọ̀? Rárá o. Kàkà bẹ́ẹ̀, gbogbo ètò tí wọ́n bá ṣe ní láti fi hàn pé wọ́n ti ronú jinlẹ̀ lórí ìmọ̀ràn Bíbélì tó sọ pé “ẹni tí ó bá ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run ni yóò dúró títí láé.”—1 Jòhánù 2:16, 17.
10. (a) Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì pé kéèyàn ronú dáadáa tó bá fẹ́ ṣe ìgbéyàwó tó mọ́gbọ́n dání? (b) Báwo ló ṣe yẹ kí wọ́n ṣèpinnu nípa àwọn tí wọ́n máa pè?
10 Kò yẹ káwọn Kristẹni tó fẹ́ ṣègbéyàwó ṣe ju ara wọn lọ, wọ́n sì ní láti ṣe ohun tó bọ́gbọ́n mu. Bíbélì lè ràn wọ́n lọ́wọ́ láti ṣe èyí. Ọjọ́ ìgbéyàwó ṣe pàtàkì lóòótọ́, àmọ́ wọ́n mọ̀ pé ńṣe ló wulẹ̀ jẹ́ ìbẹ̀rẹ̀ ìgbésí ayé àwọn Kristẹni méjì tí wọ́n ní ìrètí pé àwọn yóò jọ wà láàyè títí láé. Kò pọn dandan kí wọ́n filé pọntí fọ̀nà rokà nígbà ìgbéyàwó wọn. Bí wọ́n bá fẹ́ pe àpèjẹ, wọ́n ní láti ronú nípa iye tó máa ná wọn àti bí ètò náà a ṣe lọ sí. (Lúùkù 14:28) Nígbà táwọn Kristẹni méjèèjì bá bẹ̀rẹ̀ sí í gbé pa pọ̀ gẹ́gẹ́ bí tọkọtaya, ọkọ ni yóò jẹ́ orí gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ ṣe sọ. (1 Kọ́ríńtì 11:3; Éfésù 5:22, 23) Nítorí náà, ọkọ ìyàwó gan-an ló máa pinnu ohun tó máa wáyé níbi àpèjẹ ìgbéyàwó náà. Á dára kó gba èrò ìyàwó rẹ̀ nípa ètò àpèjẹ náà yẹ̀ wò ṣá o, kí wọ́n jọ sọ̀rọ̀ nípa àwọn tí wọ́n fẹ́ kó wá tàbí iye àwọn tí agbára wọn gbé láti pè. Ó lè má ṣeé ṣe láti pe gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ wọn àti mọ̀lẹ́bí wọn, ó tiẹ̀ lè máà mọ́gbọ́n dání láti ṣe bẹ́ẹ̀; nítorí náà, wọ́n ní láti mọ̀wọ̀n ara wọn kí wọ́n sì ṣe àwọn ìpinnu tó bọ́gbọ́n mu. Ó yẹ kí ọkàn àwọn tó fẹ́ di tọkọtaya náà balẹ̀ pé bí àwọn kò bá pe àwọn kan lára àwọn Ẹlẹ́rìí bíi tiwọn, wọ́n á gba tàwọn rò wọn ò sì ní fi ṣe ìbínú.—Oníwàásù 7:9.
“Olùdarí Àsè”
11. Ipa wo ni ẹni tó bá ṣe “olùdarí àsè” ń kó níbi ìgbéyàwó?
11 Bí àwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó bá fẹ́ kó àwọn èèyàn lẹ́nu jọ nígbà ìgbéyàwó wọn, báwo ni wọ́n ṣe lè rí i dájú pé àwọn ohun tó bójú mu ló máa wáyé níbi ayẹyẹ náà? Láti ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn làwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ti mọ̀ pé ó bọ́gbọ́n mu pé kéèyàn ṣe irú ètò kan tí Bíbélì sọ pé wọ́n ṣe níbi àsè ìgbéyàwó tí Jésù lọ ní Kánà. Ètò tí wọ́n ṣe níbẹ̀ ni pé wọ́n yan “olùdarí àsè,” ó sì dájú pé olùjọsìn Ọlọ́run kan tó dàgbà dénú ni wọ́n fi ṣe olùdarí yìí. (Jòhánù 2:9, 10) Bákan náà, arákùnrin kan tó dàgbà dénú nípa tẹ̀mí ni ọkọ ìyàwó tó bá gbọ́n yóò yàn láti kó ipa pàtàkì yìí. Tí olùdarí àsè náà bá ti mọ àwọn ohun tí ọkọ ìyàwó fẹ́, yóò tẹ̀ lé àwọn ohun náà ṣáájú kí ayẹyẹ náà tó bẹ̀rẹ̀ àti nígbà tó bá ń lọ lọ́wọ́.
12. Kí ni ọkọ ìyàwó ní láti fi sọ́kàn nípa ọ̀rọ̀ ọtí?
12 Gẹ́gẹ́ bá a ṣe jíròrò ní ìpínrọ̀ 5, àwọn kan tó fẹ́ ṣègbéyàwó kì í pèsè ọtí níbi àsè ìgbéyàwó wọn kó má bàa di pé ọtí àmupara ba ayọ̀ ayẹyẹ náà jẹ́. (Róòmù 13:13; 1 Kọ́ríńtì 5:11) Àmọ́, bí wọ́n bá máa pèsè ọtí, ọkọ ìyàwó ní láti rí i dájú pé ìwọ̀ntúnwọ̀nsì ni wọ́n fún àwọn èèyàn. Wáìnì wà níbi ìgbéyàwó tí Jésù lọ ní Kánà, wáìnì tó dára gan-an sì ni. Àní, olùdarí àsè náà sọ pé: “Olúkúlùkù ènìyàn mìíràn a kọ́kọ́ gbé wáìnì àtàtà jáde, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì ti mutíyó tán, yóò sì kan gbàrọgùdù. Ìwọ ti fi wáìnì àtàtà pa mọ́ títí di ìsinsìnyí.” (Jòhánù 2:10) Ó dájú pé Jésù ò ṣe ohun tó máa mú káwọn èèyàn mu ọtí àmupara, torí ó mọ̀ pé ọtí àmupara kò dára. (Lúùkù 12:45, 46) Ìyàlẹ́nu gbáà ló jẹ́ fún olùdarí àsè náà láti rí bí wáìnì náà ṣe dára tó, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì fi hàn pé ó ti rí ibi táwọn kan ti mutí àmupara níbi ìgbéyàwó. (Ìṣe 2:15; 1 Tẹsalóníkà 5:7) Nítorí náà, ọkọ ìyàwó àti Kristẹni tó ṣeé gbára lé tó fi ṣe olùdarí àsè ní láti rí i dájú pé gbogbo àwọn tó pésẹ̀ ló tẹ̀ lé ìtọ́ni tó ṣe kedere yìí pé: “Ẹ má ṣe máa mu wáìnì ní àmupara, nínú èyí tí ìwà wọ̀bìà wà.”—Éfésù 5:18; Òwe 20:1; Hóséà 4:11.
13. Kí ló yẹ kí àwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó fi sọ́kàn tí wọ́n bá fẹ́ kí orin wà níbi àpèjẹ ìgbéyàwó wọn, kí sì nìdí?
13 Gẹ́gẹ́ bó ṣe yẹ kó rí láwọn ibi táwọn Kristẹni bá kóra jọ sí, bí orin bá máa wà, wọ́n ní láti rí i pé kò lọ sókè jù débi pé àwọn èèyàn ò ní lè gbọ́ ọ̀rọ̀ tí wọ́n ń bára wọn sọ. Alàgbà kan sọ pé: “Bí ilẹ̀ bá ti ń ṣú lọ, tó di pé ọ̀rọ̀ táwọn èèyàn ń sọ ti wọ̀ wọ́n lára tàbí tí ijó ti bẹ̀rẹ̀, wọ́n máa ń yí ohùn orin sókè nígbà míì. Orin tó rọra ń dún tẹ́lẹ̀ lè wá lọ sókè gan-an débi pé àwọn èèyàn ò ní lè gbọ́ ọ̀rọ̀ tí wọ́n ń bára wọn sọ. Èèyàn máa ń láǹfààní láti bá àwọn ẹlòmíràn fọ̀rọ̀ jomi toro ọ̀rọ̀ níbi àpèjẹ ìgbéyàwó. Á mà burú o tó bá di pé ariwo orin ò jẹ́ kí ìyẹn lè ṣeé ṣe!” Lórí kókó yìí náà, ó yẹ kí ọkọ ìyàwó àti olùdarí àsè ṣe ojúṣe wọn. Kò yẹ kí wọ́n jẹ́ kí àwọn olórin tàbí àwọn tí wọ́n bá fi sídìí orin pinnu irú orin tí wọ́n máa lò àti bí orin náà yóò ṣe lọ sókè tó, ì báà jẹ́ pé wọ́n máa sanwó fún wọn àbí wọn ò gbowó. Pọ́ọ̀lù kọ̀wé pé: “Ohun yòówù tí ẹ bá sì ń ṣe ní ọ̀rọ̀ tàbí ní iṣẹ́, ẹ máa ṣe ohun gbogbo ní orúkọ Jésù Olúwa.” (Kólósè 3:17) Nígbà táwọn tí wọ́n pè síbi àpèjẹ ìgbéyàwó bá padà sílé wọn, ǹjẹ́ kò yẹ kí wọ́n máa rántí pé orin tó wà níbẹ̀ fi hàn pé tọkọtaya náà ṣe ohun gbogbo lórúkọ Jésù? Bó ṣe yẹ kí ọ̀rọ̀ rí nìyẹn o.
14. Kí ló yẹ kó máa múnú àwọn Kristẹni dùn tí wọ́n bá ń rántí ibi ìgbéyàwó tí wọ́n lọ?
14 Ká má purọ́, bí nǹkan bá lọ létòlétò níbi ayẹyẹ ìgbéyàwó kan, tìdùnnú-tìdùnnú làwọn èèyàn á fi máa rántí rẹ̀. Ọgbọ̀n ọdún sẹ́yìn ni Adam àti Edyta ṣègbéyàwó. Nígbà tí wọ́n ń sọ̀rọ̀ nípa ìgbéyàwó kan tí wọ́n lọ, wọ́n ní: “Kò sí béèyàn ò ṣe ní rí i pé àwọn Kristẹni ló ń ṣe nǹkan. Wọ́n kọ orin ìyìn sí Jèhófà, síbẹ̀ wọ́n tún fi àwọn nǹkan míì dá àwọn èèyàn lára yá. Kì í ṣe orin àti ijó ló kó ipa pàtàkì níbẹ̀. Ayẹyẹ ọ̀hún dùn ó sì gbéni ró, gbogbo ohun tó wáyé níbẹ̀ ló bá ìlànà Bíbélì mu.” Ó ṣe kedere pé, ọ̀pọ̀ nǹkan ni ìyàwó àti ọkọ lè ṣe láti jẹ́ káwọn èèyàn rí i pé àwọn ń fi iṣẹ́ ti ìgbàgbọ́ wọn lẹ́yìn.
Fífúnni Lẹ́bùn Níbi Ìgbéyàwó
15. Ìmọ̀ràn Bíbélì wo la lè tẹ̀ lé tó bá di ọ̀rọ̀ fífúnni lẹ́bùn níbi ìgbéyàwó?
15 Ní ọ̀pọ̀ ilẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ àti mọ̀lẹ́bí sábà máa ń fún àwọn tó ń ṣègbéyàwó lẹ́bùn. Bó o bá fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀, kí ló yẹ kó o fi sọ́kàn? Má ṣe gbàgbé ohun tí àpọ́sítélì Jòhánù sọ nípa “fífi àlùmọ́ọ́nì ìgbésí ayé ẹni hàn sóde lọ́nà ṣekárími.” Ó jẹ́ ká mọ̀ pé, àwọn Kristẹni tí wọ́n ń fi iṣẹ́ ti ìgbàgbọ́ wọn lẹ́yìn kọ́ ló ń ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀, ‘ayé tí ń kọjá lọ’ ló ń ṣe é. (1 Jòhánù 2:16, 17) Pẹ̀lú ohun tí ẹ̀mí mímọ́ darí Jòhánù láti sọ yìí, ǹjẹ́ ó yẹ káwọn tọkọtaya náà dárúkọ àwọn tó fún wọn lẹ́bùn fún gbogbo èèyàn? Àwọn Kristẹni tó wà ní Makedóníà àti Ákáyà fi nǹkan ránṣẹ́ sáwọn ará wọn ní Jerúsálẹ́mù, ṣùgbọ́n kò sóhun tó fi hàn pé wọ́n dárúkọ wọn fún gbogbo èèyàn. (Róòmù 15:26) Ọ̀pọ̀ àwọn Kristẹni tí wọ́n ń fúnni lẹ́bùn ìgbéyàwó kò ní fẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé àwọn làwọn mú ẹ̀bùn wá torí pé wọn ò ní fẹ́ ṣe àṣehàn. Níbi tí ọ̀rọ̀ dé yìí, wo ìmọ̀ràn Jésù tó wà nínú Mátíù 6:1-4.
16. Báwo làwọn tó ń ṣègbéyàwó ṣe lè yẹra fún kíkó ìtìjú bá àwọn ẹlòmíràn tí wọ́n bá ń gba ẹ̀bùn ìgbéyàwó?
16 Tí wọ́n bá ń dárúkọ àwọn tó fúnni lẹ́bùn, èyí lè mú káwọn èèyàn máa ‘ru ìdíje sókè pẹ̀lú ara wọn lẹ́nì kìíní-kejì,’ kí wọ́n máa wo ẹni tí ẹ̀bùn tiẹ̀ dára jù tàbí tówó ẹ̀ pọ̀ jù. Nípa báyìí, àwọn Kristẹni ọlọ́gbọ́n tó ń ṣègbéyàwó ò ní dárúkọ àwọn tó fún wọn lẹ́bùn fún gbogbo èèyàn. Kíkéde orúkọ àwọn tó mú ẹ̀bùn wá lè kó ìtìjú bá àwọn tí kò bá lè mú ẹ̀bùn wá. (Gálátíà 5:26; 6:10) Kò burú tí ọkọ àti ìyàwó bá mọ ẹni tó fún wọn lẹ́bùn kọ̀ọ̀kan o. Wọ́n lè fi ìwé tàbí káàdì tó wà lára ẹ̀bùn náà mọ ẹni tó fún wọn lẹ́bùn, ṣùgbọ́n wọn ò ní ka orúkọ wọn jáde fún gbogbo èèyàn. Yálà àwa la fẹ́ ra ẹ̀bùn tá a máa fún àwọn tó ń ṣègbéyàwó tàbí àwa la fẹ́ gbà á, gbogbo wa lè fi hàn pé ìgbàgbọ́ wa ń nípa lórí ohun tí à ń ṣe, títí kan ohun tó jẹ́ ọ̀rọ̀ ara ẹni yìí pàápàá.a
17. Kí ló yẹ káwọn Kristẹni máa ní lọ́kàn nípa ìgbàgbọ́ àti iṣẹ́ wọn?
17 Dájúdájú, kì í ṣe híhùwà ọmọlúwàbí, lílọ sí ìpàdé ìjọ àti ṣíṣe iṣẹ́ ìwàásù nìkan ló máa fi hàn pé à ń fi iṣẹ́ ti ìgbàgbọ́ wa lẹ́yìn. Ẹ jẹ́ kí gbogbo wa lẹ́nì kọ̀ọ̀kan rí i dájú pé ìgbàgbọ́ wa kì í ṣe òkú, ṣùgbọ́n pé ó ń nípa lórí gbogbo ohun tá a bá ń ṣe. Bẹ́ẹ̀ ni o, a lè fi ìgbàgbọ́ wa hàn nípa rírí i pé à ń ṣe àwọn iṣẹ́ wa “ní kíkún,” títí kan irú àwọn ohun tá a mẹ́nu kàn lókè yìí.—Ìṣípayá 3:2.
18. Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé ọ̀rọ̀ Jòhánù 13:17 níbi ìgbéyàwó àwọn Kristẹni tàbí níbi àpèjẹ?
18 Lẹ́yìn tí Jésù fi àpẹẹrẹ tó dára lélẹ̀ fáwọn àpọ́sítélì rẹ̀ olóòótọ́ nípa fífi ìrẹ̀lẹ̀ wẹ ẹsẹ̀ wọn, ó ní: “Bí ẹ bá mọ nǹkan wọ̀nyí, aláyọ̀ ni yín bí ẹ bá ń ṣe wọ́n.” (Jòhánù 13:4-17) Níbi tí à ń gbé lónìí, ó lè má pọn dandan fáwọn èèyàn láti máa wẹ ẹsẹ̀ ẹlòmíì, irú bí àlejò tó bá wá kí wọn nílé, ó sì lè máà jẹ́ àṣà wọn láti ṣe bẹ́ẹ̀. Àmọ́, gẹ́gẹ́ bá a ṣe gbé e yẹ̀ wò nínú àpilẹ̀kọ yìí, àwọn nǹkan míì wà tá a ti lè fi hàn pé a ní ìgbàgbọ́ nípa ṣíṣe àwọn ohun tó máa jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé a nífẹ̀ẹ́ wọn a sì gba tiwọn rò, títí kan irú àwọn ohun tó ń wáyé nígbà àpèjẹ àti nígbà ìgbéyàwó àwa Kristẹni. A lè ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀, yálà àwa là ń ṣègbéyàwó tàbí wọ́n pè wá síbi ìgbéyàwó tàbí síbi àpèjẹ tó máa ń wáyé lẹ́yìn ìgbéyàwó àwọn Kristẹni tí wọ́n fẹ́ kí ohun tí wọ́n ń ṣe fi hàn pé àwọn ń fi iṣẹ́ ti ìgbàgbọ́ wọn lẹ́yìn.
[Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]
a A sọ̀rọ̀ nípa àwọn ohun mìíràn tó ń ṣẹlẹ̀ níbi ìgbéyàwó àti níbi àpèjẹ tó máa ń wáyé lẹ́yìn ìgbéyàwó nínú àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé èyí, tó ní àkòrí náà, “Ṣe Ohun Tó Máa Jẹ́ Kí Ayọ̀ àti Iyì Ọjọ́ Ìgbéyàwó Rẹ Pọ̀ Sí I.”
Báwo Ni Wàá Ṣe Dáhùn?
Báwo lo ṣe lè fi hàn pé ò ń fi iṣẹ́ ti ìgbàgbọ́ rẹ lẹ́yìn
• tó o bá fẹ́ pe àpèjẹ?
• tó o bá fẹ́ ṣètò ìgbéyàwó tàbí àpèjẹ ìgbéyàwó?
• tó o bá fẹ́ fúnni lẹ́bùn tàbí tó o fẹ́ gbà á?
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 24]
Àní bó tiẹ̀ jẹ́ pé ìwọ̀nba èèyàn díẹ̀ lo pè pàápàá, rí i pé ó fi “ọgbọ́n tí ó wá láti òkè” darí ètò náà
-
-
Ṣe Ohun Tó Máa Jẹ́ Kí Ayọ̀ àti Iyì Ọjọ́ Ìgbéyàwó Rẹ Pọ̀ Sí IIlé Ìṣọ́—2006 | October 15
-
-
Ṣe Ohun Tó Máa Jẹ́ Kí Ayọ̀ àti Iyì Ọjọ́ Ìgbéyàwó Rẹ Pọ̀ Sí I
ARÁKÙNRIN Gordon tó ṣègbéyàwó ní nǹkan bí ọgọ́ta ọdún sẹ́yìn sọ pé: “Ọjọ́ ìgbéyàwó mi jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọjọ́ tó ṣe pàtàkì fún mi tínú mi sì dùn jù lọ láyé mi.” Kí nìdí tí ọjọ́ ìgbéyàwó fi ṣe pàtàkì tó bẹ́ẹ̀ fáwọn Kristẹni tòótọ́? Ìdí ni pé ọjọ́ náà ni wọ́n jẹ́ ẹ̀jẹ́ mímọ́ pẹ̀lú àwọn tí wọ́n fẹ́ràn tọkàntọkàn, ìyẹn ọkọ tàbí aya wọn àti Jèhófà Ọlọ́run. (Mátíù 22:37; Éfésù 5:22-29) Kò sí àní-àní pé àwọn tó bá ń múra ìgbéyàwó yóò fẹ́ kí ọjọ́ náà dùn gan-an, àmọ́ ó yẹ kí wọ́n tún bọlá fún Ẹni tó dá ètò ìgbéyàwó sílẹ̀.—Jẹ́nẹ́sísì 2:18-24; Mátíù 19:5, 6.
Báwo ni ọkọ ìyàwó ṣe lè mú kí ayẹyẹ aláyọ̀ yìí túbọ̀ níyì sí i? Kí ni ìyàwó lè ṣe láti fi hàn pé òun bọlá fún ọkọ òun àti fún Jèhófà? Báwo làwọn tó wá síbi ìgbéyàwó náà ṣe lè mú kí ayọ̀ ọjọ́ náà pọ̀ sí i? Tá a bá gbé àwọn ìlànà Bíbélì kan yẹ̀ wò, a ó mọ ìdáhùn sáwọn ìbéèrè wọ̀nyí. Tá a bá sì tẹ̀ lé àwọn ìlànà náà, kò ní fi bẹ́ẹ̀ sáwọn ìṣòro tó ṣeé ṣe kó dín iyì ayẹyẹ pàtàkì náà kù.
Ta Ló Yẹ Kó Pinnu Ohun Tó Máa Wáyé Níbi Ìgbéyàwó?
Ní ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè, ìjọba yọ̀ǹda kí òjíṣẹ́ tó jẹ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà so ọkùnrin àti obìnrin pọ̀ gẹ́gẹ́ bí tọkọtaya. Àní láwọn orílẹ̀-èdè tó jẹ́ pé aṣojú ìjọba ló máa ń so àwọn méjì tó fẹ́ra wọn pọ̀ gẹ́gẹ́ bí tọkọtaya pàápàá, àwọn tó ṣègbéyàwó náà ṣì lè fẹ́ gbọ́ àsọyé tó dá lórí Bíbélì. Ẹni tó ń sọ àsọyé náà sábà máa ń sọ fún ọkọ ìyàwó náà pé kó ronú jinlẹ̀ lórí ojúṣe tí Ọlọ́run yàn fún un gẹ́gẹ́ bí olórí ìdílé. (1 Kọ́ríńtì 11:3) Nítorí náà, ọkọ ìyàwó ló yẹ kó pinnu ohun tó máa wáyé níbi ìgbéyàwó. Kò sí àní-àní pé àwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó ti máa ń múra sílẹ̀ fún ìgbéyàwó wọn tipẹ́tipẹ́ ṣáájú, títí kan àpèjẹ tó máa wáyé. Kí nìdí tí kì í fi í rọrùn fún ọkọ ìyàwó láti ṣe àwọn ètò yìí?
Ọ̀kan lára ìdí náà ni pé àwọn mọ̀lẹ́bí lọ́tùn-ún lósì tàbí ìyàwó gan-an lè fẹ́ gba gbogbo ètò ìgbéyàwó náà kanrí. Arákùnrin Rodolfo tó ti so ọ̀pọ̀ tọkọtaya pọ̀, sọ pé: “Nígbà míì, ńṣe làwọn ẹbí máa ń fẹ́ darí ọkọ ìyàwó, pàápàá tó bá jẹ́ pé àwọn ló máa gbé ẹrú ìnáwó àpèjẹ ìgbéyàwó. Wọ́n lè fẹ́ máa pàṣẹ ohun táwọn fẹ́ kó wáyé níbi ìgbéyàwó àti níbi àpèjẹ. Èyí lè máà jẹ́ kí ọkọ ìyàwó náà lè ṣe ojúṣe tí Ìwé Mímọ́ yàn fún un bó ṣe yẹ, ìyẹn ni pé kó pinnu ohun tó máa wáyé níbi ayẹyẹ náà.”
Arákùnrin Max tó ti ń so àwọn èèyàn pọ̀ gẹ́gẹ́ bí tọkọtaya láti ohun tó lé ní ọdún márùndínlógójì sẹ́yìn, sọ pé: “Mo ṣàkíyèsí pé ohun tó ń ṣẹlẹ̀ nísinsìnyí ni pé ìyàwó ló máa ń sábà sọ bí ayẹyẹ ìgbéyàwó àti àpèjẹ náà ṣe máa lọ, tí ọkọ ò sì ní fi bẹ́ẹ̀ lẹ́nu ọ̀rọ̀.” Arákùnrin David tóun náà ti so ọ̀pọ̀ ọkùnrin àti obìnrin pọ̀ gẹ́gẹ́ bíi tọkọtaya sọ pé: “Ó lè máa tíì mọ́ àwọn ọkọ ìyàwó lára láti máa ṣe kòkárí ètò, wọn kì í sì í sábà kópa nínú ètò ìmúrasílẹ̀ ìgbéyàwó tó bó ṣe yẹ.” Báwo ni ọkọ ìyàwó ṣe lè ṣe ojúṣe rẹ̀ bó ṣe tọ́ àti bó ṣe yẹ?
Bí Ìjùmọ̀sọ̀rọ̀ Bá Wà, Ayọ̀ Ayẹyẹ Náà Á Pọ̀ Sí I
Kí ọkọ tó lè ṣe ojúṣe rẹ̀ dáadáa bí wọ́n ṣe ń múra ìgbéyàwó náà, ó ní láti rí i pé òun bá àwọn tí ọ̀rọ̀ kàn jíròrò bí ètò náà yóò ṣe lọ sí. Bíbélì ti sọ̀rọ̀ síbi tọ́rọ̀ wà nígbà to sọ pé: “Àwọn ìwéwèé máa ń já sí pàbó níbi tí kò bá ti sí ọ̀rọ̀ ìfinúkonú.” (Òwe 15:22) Àmọ́, kò ní fi bẹ́ẹ̀ sí ìjákulẹ̀ bí ọkọ ìyàwó bá kọ́kọ́ bá ìyàwó rẹ̀, àwọn mọ̀lẹ́bí àtàwọn ẹlòmíràn tó lè fún wọn nímọ̀ràn tó yè kooro látinú Ìwé Mímọ́ sọ̀rọ̀ nípa ìmúrasílẹ̀ ìgbéyàwó náà.
Dájúdájú, ó ṣe pàtàkì kí àwọn àfẹ́sọ́nà náà kọ́kọ́ jọ jíròrò nípa bí ètò náà á ṣe lọ sí àtàwọn ohun tó ṣeé ṣe kó wáyé níbẹ̀. Kí nìdí? Ẹ jẹ́ ká gbé àpẹẹrẹ Ivan àti Delwyn yẹ̀ wò. Tọkọtaya yìí ti ń fi tayọ̀tayọ̀ gbé pọ̀ láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún sẹ́yìn bó tilẹ̀ jẹ́ pé àṣà ìbílẹ̀ wọn yàtọ̀ síra. Nígbà tí Ivan tó jẹ́ ọkọ ń sọ̀rọ̀ nípa ètò tí wọ́n ṣe ṣáájú ìgbéyàwó wọn, ó ní: “Mo ti fọkàn yàwòrán irú ayẹyẹ ìgbéyàwó tí mò ń fẹ́. Mo wò ó pé àá ṣe àpèjẹ fún gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ mi, àá ṣe kéèkì, ìyàwó mi á sì wọ aṣọ funfun. Àmọ́ ọ̀tọ̀ lohun tó wà lọ́kàn ìyàwó mi ní tiẹ̀. Kò fẹ́ ká pariwo rárá, bẹ́ẹ̀ ni kò fẹ́ ká ṣe kéèkì. Àní, ó tiẹ̀ ń rò ó pé bóyá lòun máa wọ aṣọ funfun pàápàá.”
Kí ni tọkọtaya yìí ṣe nípa èrò ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ tí wọ́n ní yìí? Ńṣe ni wọ́n jọ sọ ọ̀rọ̀ náà ní ìtùnbí-ìnùbí. (Òwe 12:18) Ivan sọ pé: “A gbé àwọn àpilẹ̀kọ tó sọ̀rọ̀ nípa ìgbéyàwó yẹ̀ wò, irú bí èyí tó wà nínú Ile-Iṣọ Naa ti October 15, 1984.a Ohun tá a kà níbẹ̀ jẹ́ ká mọ ojú tí Ọlọ́run fi wo ayẹyẹ yìí. Níwọ̀n bí àṣà ìbílẹ̀ wa ti yàtọ̀ síra, ńṣe làwa méjèèjì jọ fẹnu kò lórí èyí tá a máa ṣe nínú gbogbo ohun tó wu kálukú wa pé ká ṣe.”
Irú ohun tí Aret àti Penny náà ṣe nìyẹn. Nígbà tí Aret ń sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ ìgbéyàwó wọn, ó ní: “Èmi àti Penny ìyàwó mi jíròrò nípa bí kálukú ṣe fẹ́ kí ìgbéyàwó náà rí, a sì jọ fẹnu kò lórí èyí tá a máa ṣe. A gbàdúrà pé kí Jèhófà jẹ́ kí gbogbo ètò ọjọ́ náà yọrí sí rere. Mo tún fọ̀rọ̀ lọ àwọn òbí wa àtàwọn tọkọtaya míì tí wọ́n dàgbà dénú nínú ìjọ wa. Ìmọ̀ràn tí wọ́n fún wa wúlò gan-an ni. Gbogbo èyí jẹ́ kí ìgbéyàwó wa dùn, kó sì lárinrin.”
Ó Yẹ Kí Aṣọ àti Ìmúra Wa Buyì Kúnni
A mọ̀ pé àtọkọ àtìyàwó ló máa fẹ́ múra lọ́nà tó gbayì gan-an lọ́jọ́ nǹkan ẹ̀yẹ wọn. (Sáàmù 45:8-15) Wọ́n lè náwó nára, kí wọ́n sì ṣe wàhálà púpọ̀ láti wá irú aṣọ tó yẹ kí wọ́n lò lọ́jọ́ náà. Àwọn ìlànà Bíbélì wo ló lè jẹ́ kí wọ́n mọ irú aṣọ tó buyì kúnni tó sì fani mọ́ra?
Ẹ jẹ́ ká sọ̀rọ̀ lórí ohun tí ìyàwó máa wọ̀ lọ́jọ́ náà. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé èyí-wù-mí-ò-wù-ọ́ lọ̀rọ̀ aṣọ, ohun tí wọ́n ń ṣe lórílẹ̀-èdè kan sì yàtọ̀ sí ti orílẹ̀-èdè mìíràn, ibi gbogbo ni ìmọ̀ràn Bíbélì ti wúlò. Àwọn obìnrin ní láti “máa fi aṣọ tí ó wà létòletò ṣe ara wọn lọ́ṣọ̀ọ́, pẹ̀lú ìmẹ̀tọ́mọ̀wà àti ìyèkooro èrò inú.” Gbogbo ìgbà ló yẹ káwọn obìnrin tí wọ́n jẹ́ Kristẹni máa fi ìmọ̀ràn yìí sọ́kàn, àní títí kan ọjọ́ ìgbéyàwó wọn pàápàá. Kókó ibẹ̀ ni pé kò pọn dandan kéèyàn lo ‘aṣọ olówó ńlá’ kí ìgbéyàwó rẹ̀ tó lè dùn. (1 Tímótì 2:9; 1 Pétérù 3:3, 4) Á mà dára gan-an o bí ìyàwó bá lè fi ìmọ̀ràn yìí sọ́kàn!
Arákùnrin David tá a sọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sọ pé: “Èyí tó pọ̀ jù lára àwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó máa ń gbìyànjú láti tẹ̀ lé ìlànà Bíbélì, ó sì yẹ ká gbóríyìn fún wọn. Àmọ́ o, a ti rí ibi tí ìyàwó àti ọ̀rẹ́ ìyàwó ti wọṣọ tí kò bójú mu, irú bí aṣọ tí kò bo àyà dáadáa tàbí aṣọ tó ń fi ara hàn.” Nígbà tí alàgbà kan tó dàgbà dénú ń bá àwọn kan tó fẹ́ ṣègbéyàwó sọ̀rọ̀ ṣáájú ọjọ́ ìgbéyàwó wọn, ó sọ ohun tó máa jẹ́ kí wọ́n ronú nípa irú aṣọ tó yẹ kí Kristẹni wọ̀. Báwo ló ṣe ṣe é? Ńṣe ló béèrè lọ́wọ́ wọn bóyá aṣọ tí wọ́n fẹ́ wọ̀ lọ́jọ́ náà bójú mu tó èyí tí wọ́n lè wọ̀ lọ sípàdé ìjọ. Òótọ́ ni pé aṣọ téèyàn máa wọ̀ lọ́jọ́ náà lè yàtọ̀ sí irú èyí téèyàn máa ń wọ̀ lọ sí ìpàdé ìjọ, ó sì lè bá bí wọ́n ṣe ń wọṣọ ládùúgbò ẹni mu, síbẹ̀ ó yẹ kí aṣọ náà bójú mu, kó jẹ́ irú èyí tó yẹ Kristẹni. Bí àwọn èèyàn ayé kan bá tiẹ̀ ń sọ pé ìlànà Bíbélì nípa irú ìwà tó yẹ kéèyàn máa hù ti le jù, kò yẹ kí àwọn Kristẹni tòótọ́ jẹ́ kí ayé sọ wọ́n dà bó ṣe dà.—Róòmù 12:2; 1 Pétérù 4:4.
Arábìnrin Penny sọ pé: “Kì í ṣe aṣọ tá a máa wọ̀ àti àpèjẹ ìgbéyàwó wa ni èmi àti Aret ọkọ mi ká sí pàtàkì jù. Ṣùgbọ́n, bí ìgbéyàwó náà ṣe rí lójú Ọlọ́run ló jẹ wá lọ́kàn jù. Ìyẹn ló ṣe pàtàkì jù lọ́jọ́ náà. Kì í ṣe aṣọ tí mo wọ̀ tàbí oúnjẹ tí mo jẹ lohun pàtàkì tí mo rántí, bí kò ṣe ìfararora tí mo ní pẹ̀lú àwọn tó wá síbẹ̀ lọ́jọ́ náà àti ìdùnnú tí mo ní pé ẹni tí ọkàn mi yàn ni mo fẹ́.” Ó yẹ káwọn Kristẹni tó bá fẹ́ ṣègbéyàwó fi àwọn kókó pàtàkì wọ̀nyí sọ́kàn bí wọ́n ṣe ń múra ìgbéyàwó wọn.
Gbọ̀ngàn Ìjọba Jẹ́ Ibi Ọ̀wọ̀
Gbọ̀ngàn Ìjọba ni ọ̀pọ̀ àwọn Kristẹni ti máa ń fẹ́ ṣègbéyàwó wọn, bó bá ṣeé ṣe. Kí ló mú kó wù wọ́n? Àwọn kan sọ ohun tó mú kó wu àwọn láti lo Gbọ̀ngàn Ìjọba, wọ́n ní: “A mọ̀ pé ìgbéyàwó jẹ́ ètò pàtàkì tí Jèhófà dá sílẹ̀. Ṣíṣe ìgbéyàwó wa ní Gbọ̀ngàn Ìjọba tó jẹ́ ibi ìjọsìn Ọlọ́run jẹ́ ká túbọ̀ fi í sọ́kàn látìbẹ̀rẹ̀ pé Jèhófà ní láti wà nínú ìgbéyàwó wa. Àǹfààní mìíràn tó wà nínú ṣíṣègbéyàwó nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba dípò ibòmíràn ni pé, yóò jẹ́ káwọn mọ̀lẹ́bí tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí tí wọ́n wá síbi ìgbéyàwó náà mọ̀ pé a ò fọ̀rọ̀ ìjọsìn Ọlọ́run ṣeré.”
Bí àwọn alàgbà ìjọ tó ń lo Gbọ̀ngàn Ìjọba náà bá fún àwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó láyè láti ṣe é níbẹ̀, àwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó ní láti sọ irú ìmúrasílẹ̀ tí wọ́n ń ṣe tó jẹ mọ ìlò gbọ̀ngàn náà fáwọn alàgbà náà ṣáájú. Ọ̀nà kan tí ọkọ àti ìyàwó lè gbà fi hàn pé àwọn ka àwọn tí wọ́n pè wá síbi ìgbéyàwó wọn kún ni pé kí wọ́n rí i dájú pé àwọn dé lákòókò. Ó sì yẹ kí wọ́n rí i dájú pé wọ́n ṣe gbogbo nǹkan lọ́nà tó buyì kúnni.b (1 Kọ́ríńtì 14:40) Nípa bẹ́ẹ̀, àwọn ohun tí kò bójú mu tí wọ́n máa ń ṣe níbi ìgbéyàwó àwọn èèyàn ayé kò ní wáyé níbi ìgbéyàwó wọn.—1 Jòhánù 2:15, 16.
Àwọn tó bá wá síbi ìgbéyàwó náà pẹ̀lú lè jẹ́ kó hàn pé ojú tí Jèhófà fi ń wo ìgbéyàwó làwọn náà fi ń wò ó. Bí àpẹẹrẹ, wọn ò ní máa retí pé kí ìgbéyàwó náà ta yọ àwọn ìgbéyàwó mìíràn táwọn Kristẹni kan ṣe, bí ẹni pé ńṣe làwọn tó ń ṣègbéyàwó ń bára wọn díje láti mọ ẹni tí ìgbéyàwó tiẹ̀ fakíki jù. Àwọn Kristẹni tí wọ́n dàgbà dénú tún mọ̀ pé kéèyàn lọ sí Gbọ̀ngàn Ìjọba láti lọ gbọ́ àsọyé ìgbéyàwó tó dá lórí Bíbélì ló ṣe pàtàkì jù, òun ló sì máa ṣeni láǹfààní ju lílọ síbi àpèjẹ ìgbéyàwó tàbí àpèjẹ míì tó bá wáyé lẹ́yìn ìyẹn. Bó bá jẹ́ pé ọ̀kan lèèyàn máa lè lọ nínú méjèèjì, kò sí àní-àní pé Gbọ̀ngàn Ìjọba ló máa dáa jù kéèyàn lọ. Alàgbà kan tó ń jẹ́ William sọ pé: “Bí àwọn tí wọ́n pè ò bá lọ sí Gbọ̀ngàn Ìjọba láìsí ìdí kan tó ṣe gúnmọ́, tí wọ́n wá lọ síbi àpèjẹ lẹ́yìn ìyẹn, èyí á fi hàn pé wọn ò mọyì jíjẹ́ tí ìgbéyàwó jẹ́ ohun mímọ́ nìyẹn. Àní bí wọn ò bá tiẹ̀ pè wá síbi àpèjẹ pàápàá,c tó bá jẹ́ pé Gbọ̀ngàn Ìjọba la lọ, yóò fi hàn pé a yẹ́ ọkọ àti ìyàwó sí, èyí á sì jẹ́ káwọn mọ̀lẹ́bí wa tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí rí i pé a ò fọ̀rọ̀ ìjọsìn wa ṣeré.”
Ayọ̀ Tí Kò Mọ sí Ọjọ́ Ìgbéyàwó
Àwọn oníṣòwò ti sọ ayẹyẹ ìgbéyàwó di ìjẹ, èyí tí wọ́n á fi máa pa òbítíbitì owó. Ìròyìn kan lẹ́nu àìpẹ́ yìí sọ pé, nílẹ̀ Amẹ́ríkà, “ẹgbẹ̀rún méjìlélógún dọ́là [nǹkan bíi mílíọ̀nù mẹ́ta náírà] tàbí ìdajì iye owó tó ń wọlé fún ìdílé kọ̀ọ̀kan [lọ́dọọdún] ní Amẹ́ríkà làwọn tó ń ṣègbéyàwó ń ná.” Ìpolówó ọjà táwọn tó fẹ́ ṣègbéyàwó tàbí àwọn mọ̀lẹ́bí wọn ń rí ló máa ń jẹ́ kí wọ́n tọrùn bọ gbèsè tí wọ́n á máa san fún ọ̀pọ̀ ọdún nítorí ayẹyẹ ọjọ́ kan ṣoṣo. Ǹjẹ́ ó mọ́gbọ́n dání kéèyàn fi gbèsè bẹ̀rẹ̀ ìgbéyàwó rẹ̀? Àwọn tí kò bá mọ ìlànà Bíbélì tàbí tí ìlànà náà kò bá jọ lójú lè fẹ́ ṣe irú ṣekárími bẹ́ẹ̀, àmọ́ ọ̀rọ̀ ò rí bẹ́ẹ̀ rárá o láàárín àwọn Kristẹni tòótọ́!
Ọ̀pọ̀ àwọn tọkọtaya tí wọ́n jẹ́ Kristẹni tí wọ́n ṣègbéyàwó wọn ní ìwọ̀ntúnwọ̀nsì, tí wọ́n ṣe ohun tí agbára wọn gbé, tí wọ́n sì tún rí i pé nǹkan tẹ̀mí ló jẹ wọ́n lógún nígbà ìgbéyàwó náà ti láǹfààní láti lo àkókò àti ohun ìní wọn ní ìbámu pẹ̀lú ẹ̀jẹ́ ìyàsímímọ́ wọn sí Ọlọ́run. (Mátíù 6:33) Wo àpẹẹrẹ Lloyd àti Alexandra tí wọ́n ti lo ọdún mẹ́tàdínlógún nínú iṣẹ́ ìsìn alákòókò-kíkún látìgbà tí wọ́n ti ṣègbéyàwó. Lloyd sọ pé: “Àwọn kan lè sọ pé ayẹyẹ ìgbéyàwó wa ti ṣe ráńpẹ́ jù, ṣùgbọ́n inú èmi àti Alexandra dùn gan-an. A wò ó pé kò yẹ ká jẹ́ kí ìnáwó ìgbéyàwó wa pa wá lára, kàkà bẹ́ẹ̀ ńṣe ló yẹ kí ìgbéyàwó wa jẹ́ ayẹyẹ ètò tí Jèhófà ṣe, èyí tó máa fún àwọn méjì tí wọ́n fẹ́ra wọn ní ayọ̀ ńlá.”
Alexandra fi kún un pé: “Mo ti ń ṣe aṣáájú ọ̀nà ká tó ṣègbéyàwó, mi ò fẹ́ tìtorí kí ìgbéyàwó lè fakíki pàdánù àǹfààní ńlá yìí. Ọjọ́ pàtàkì lọjọ́ ìgbéyàwó wa. Àmọ́, ìbẹ̀rẹ̀ ìgbésí ayé tí àwa méjèèjì yóò jọ máa gbé títí ayé ló wulẹ̀ jẹ́. A tẹ̀ lé ìmọ̀ràn pàtàkì tí ètò Ọlọ́run fún wa pé kò yẹ ká jẹ́ kí ohun tá a máa ṣe ní ọjọ́ ìgbéyàwó náà gbà wá lọ́kàn jù, a sì wá ìtọ́sọ́nà Jèhófà tó máa ṣe wá láǹfààní lẹ́yìn ọjọ́ ìgbéyàwó wa. Èyí ti mú kí Jèhófà bù kún wa.”d
Dájúdájú, ọjọ́ pàtàkì ni ọjọ́ ìgbéyàwó rẹ. Ìwà àti ìṣe rẹ lọ́jọ́ náà lè jẹ́ àpẹẹrẹ ohun tí yóò máa ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú tẹ́ ẹ bá ti di tọkọtaya. Nítorí náà, ẹ gbára lé Jèhófà kó lè tọ́ yín sọ́nà. (Òwe 3:5, 6) Ojú tí Jèhófà fi wo ìgbéyàwó náà ló yẹ kẹ́ ẹ fi sọ́kàn jù. Ẹ dúró ti ara yín kẹ́ ẹ lè ṣe ojúṣe tí Ọlọ́run yàn fún ẹnì kọ̀ọ̀kan yín. Nípa bẹ́ẹ̀, ẹ ó lè fi ìpìlẹ̀ tó lágbára lélẹ̀ fún ìgbéyàwó yín. Yàtọ̀ síyẹn, pẹ̀lú ìbùkún Jèhófà, ẹ ó lè ní ayọ̀ tí kò ní mọ sí ọjọ́ ìgbéyàwó yín nìkan.—Òwe 18:22.
-