-
‘Agbára Jèhófà Pọ̀’Sún Mọ́ Jèhófà
-
-
15. Ọ̀nà wo ni Jèhófà gbà ń lo agbára ẹ̀ nítorí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, báwo lohun tó ṣẹlẹ̀ sí Èlíjà sì ṣe jẹ́ ká mọ̀ bẹ́ẹ̀?
15 Jèhófà tún máa ń lo agbára rẹ̀ láti ràn wá lọ́wọ́ lẹ́nì kọ̀ọ̀kan. Kíyè sí ohun tí 2 Kíróníkà 16:9 sọ, ó ní: “Ojú Jèhófà ń lọ káàkiri gbogbo ayé láti fi agbára rẹ̀ hàn nítorí àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sìn ín.” Àpẹẹrẹ kan lohun tó ṣẹlẹ̀ sí Èlíjà, bá a ṣe rí i níbẹ̀rẹ̀ orí yìí. Kí nìdí tí Jèhófà fi jẹ́ kó rí agbára rẹ̀ lọ́nà tó ṣàrà ọ̀tọ̀ tóyẹn? Ìdí ni pé Jésíbẹ́lì Ayaba ti halẹ̀ mọ́ Èlíjà pé òun máa pa á. Ni Èlíjà bá fẹsẹ̀ fẹ́ ẹ kí wọ́n má bàa rí i pa. Ó gbà pé òun nìkan ṣoṣo ló ń sin Jèhófà, ẹ̀rù bà á, ayé sì sú u. Ńṣe ló dà bíi pé gbogbo iṣẹ́ àṣekára tó ṣe ti já sí asán. Jèhófà ṣe àwọn nǹkan kan kó lè rán Èlíjà létí pé alágbára lòun, ìyẹn sì tu Èlíjà nínú gan-an. Nígbà tí Èlíjà rí ẹ̀fúùfù, ìmìtìtì ilẹ̀ àti iná tó ń jó, ọkàn ẹ̀ balẹ̀ torí ó mọ̀ pé Olódùmarè tó lágbára jù lọ láyé àtọ̀run wà lẹ́yìn òun. Ó dájú pé kò sídìí kankan tó fi yẹ kí Èlíjà máa bẹ̀rù Jésíbẹ́lì, torí pé Ọlọ́run Olódùmarè wà lẹ́yìn rẹ̀.—1 Àwọn Ọba 19:1-12.b
-
-
‘Agbára Jèhófà Pọ̀’Sún Mọ́ Jèhófà
-
-
b Bíbélì sọ pé: “Jèhófà kò sí nínú ẹ̀fúùfù náà . . . , ìmìtìtì ilẹ̀ náà . . . , [àti] iná náà.” Àwọn ìránṣẹ́ Jèhófà yàtọ̀ sáwọn abọ̀rìṣà tí wọ́n máa ń jọ́sìn afẹ́fẹ́, iná tàbí òjò. Jèhófà lágbára gan-an, torí náà kò lè wà nínú àwọn nǹkan tóun fúnra ẹ̀ dá.—1 Àwọn Ọba 8:27.
-