-
Ìwé Kan Tí Ó Wúlò Fún Ìgbésí Ayé Òde ÒníÌwé kan tí ó Wà fún Gbogbo Ènìyàn
-
-
Ṣùgbọ́n ọlá àṣẹ òbí—“ọ̀pá ìbáwí”—ni wọn kò gbọ́dọ̀ ṣì ló láé.b (Òwe 22:15; 29:15) Bíbélì fún àwọn òbí ní ìkìlọ̀ pé: “Má ṣe tọ́ àwọn ọmọ rẹ sọ́nà lọ́nà àṣerégèé, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìwọ yóò sọ ọkàn wọn domi.” (Kólósè 3:21, Phillips) Ó tún gbà pé ìjẹniníyà ti ara ìyára kì í sábà jẹ́ ọ̀nà tí ó gbéṣẹ́ jù lọ láti gbà kọ́ni. Òwe 17:10 sọ pé: “Ìbáwí mímúná ń ṣiṣẹ́ jinlẹ̀ nínú ẹni tí ó ní òye ju lílu arìndìn ní ọgọ́rùn-ún ìgbà.” Àti pé, ohun tí Bíbélì dámọ̀ràn ni ìbáwí kí wọ́n má baà ṣe àṣìṣe. Nínú Diutarónómì 11:19, a rọ àwọn òbí pé kí wọ́n lo àǹfààní àwọn àyè kéékèèké tí ó bá yọ láti fi gbin ìwà rere sínú àwọn ọmọ wọn.—Tún wo Diutarónómì 6:6, 7.
-
-
Ìwé Kan Tí Ó Wúlò Fún Ìgbésí Ayé Òde ÒníÌwé kan tí ó Wà fún Gbogbo Ènìyàn
-
-
b Ní àwọn àkókò tí a kọ Bíbélì, ọ̀rọ̀ náà “ọ̀pá” (sheʹvet lédè Hébérù) túmọ̀ sí “igi” tàbí “ọ̀pá gbọọrọ,” irú èyí tí àwọn olùṣọ́ àgùntàn máa ń lò.10 Nínú àyíká ọ̀rọ̀ yí, ọ̀pá àṣẹ dámọ̀ràn ìtọ́sọ́nà onífẹ̀ẹ́, kì í ṣe ìwà òkú òǹrorò.—Fí wé Sáàmù 23:4.
-