-
Ọ̀rọ̀ Ìrètí fún Àwọn Ìgbèkùn Tí Ìrẹ̀wẹ̀sì Ọkàn BáÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
“Aláṣẹ fún Àwọn Àwùjọ Orílẹ̀-Èdè”
13. Báwo ni Jésù ṣe jẹ́ ‘ẹlẹ́rìí fún àwọn àwùjọ orílẹ̀-èdè’ nígbà iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ àti lẹ́yìn tó gòkè re ọ̀run pàápàá?
13 Kí ni ọba ọjọ́ iwájú yìí yóò ṣe? Jèhófà sọ pé: “Wò ó! Mo ti fi í fún àwọn àwùjọ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí, gẹ́gẹ́ bí aṣáájú àti aláṣẹ fún àwọn àwùjọ orílẹ̀-èdè.” (Aísáyà 55:4) Nígbà tí Jésù dàgbà tán, ó jẹ́ aṣojú Jèhófà lórí ilẹ̀ ayé, ẹlẹ́rìí Ọlọ́run fún àwọn orílẹ̀-èdè. Lásìkò tí Jésù fi wà ní ayé, “àwọn àgùntàn ilé Ísírẹ́lì tí wọ́n sọnù” ló dárí iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ sí. Àmọ́, kété ṣáájú kí Jésù tó gòkè re ọ̀run, ó sọ fún àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ pé: “Nítorí náà, ẹ lọ, kí ẹ sì máa sọ àwọn ènìyàn gbogbo orílẹ̀-èdè di ọmọ ẹ̀yìn . . . Wò ó! mo wà pẹ̀lú yín ní gbogbo àwọn ọjọ́ títí dé ìparí ètò àwọn nǹkan.” (Mátíù 10:5, 6; 15:24; 28:19, 20) Nípa báyìí, láìpẹ́, iṣẹ́ Ìjọba yìí di èyí tó dé ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe Júù, àwọn kan lára wọn sì kópa nínú ìmúṣẹ májẹ̀mú tí Ọlọ́run bá Dáfídì dá. (Ìṣe 13:46) Lọ́nà yìí, Jésù ń bá a lọ láti jẹ́ ‘ẹlẹ́rìí Jèhófà fún àwọn àwùjọ orílẹ̀-èdè’ kódà lẹ́yìn ikú, àjíǹde, àti ìgòkè re ọ̀run rẹ̀.
14, 15. (a) Báwo ni Jésù ṣe fi hàn pé òun jẹ́ “aṣáájú àti aláṣẹ”? (b) Kí ni àwọn ọmọlẹ́yìn Jésù ti ọ̀rúndún kìíní ń retí láti dà?
14 Jésù yóò sì tún jẹ́ “aṣáájú àti aláṣẹ.” Gẹ́gẹ́ bí àsọtẹ́lẹ̀ yìí ṣe wí lóòótọ́, nígbà tí Jésù fi wà lórí ilẹ̀ ayé, ó gbà láti ṣe ojúṣe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí délẹ̀délẹ̀, ó sì mú ipò iwájú ní gbogbo ọ̀nà, ó wá di ẹni tí àwùjọ ńlá ń wọ́ tọ̀, òun náà sì ń kọ́ wọn ní ọ̀rọ̀ òtítọ́, ó sì ń jẹ́ kí wọ́n rí àǹfààní tí àwọn tó bá tẹ̀ lé òun gẹ́gẹ́ bí aṣáájú wọn yóò rí gbà. (Mátíù 4:24; 7:28, 29; 11:5) Ó dá àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ lẹ́kọ̀ọ́ lọ́nà tó yé wọn, ó fi ìyẹn múra wọn sílẹ̀ fún iṣẹ́ ìwàásù káàkiri tí wọ́n máa tó dáwọ́ lé. (Lúùkù 10:1-12; Ìṣe 1:8; Kólósè 1:23) Láàárín ọdún mẹ́ta àti ààbọ̀ péré, Jésù ti fìdí ìjọ oníṣọ̀kan lọ́lẹ̀, ìjọ tí yóò kárí ayé, tí yóò sì ní ẹgbẹẹgbẹ̀rún ọmọ ìjọ látinú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀yà! Àfi “aṣáájú àti aláṣẹ” tòótọ́ nìkan ló lè gbé irú iṣẹ́ bàǹtàbanta yẹn ṣe.b
15 A fi ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run yan àwọn tí wọ́n kó jọ pọ̀ sínú ìjọ Kristẹni ní ọ̀rúndún kìíní, wọ́n sì dẹni tó ń retí láti di alájùmọ̀ṣàkóso pẹ̀lú Jésù ní Ìjọba ọ̀run. (Ìṣípayá 14:1) Ṣùgbọ́n ìgbà tí àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà ń wí ré kọjá ìgbà àwọn Kristẹni ti àkọ́kọ́bẹ̀rẹ̀. Ẹ̀rí fi hàn pé Jésù Kristi kò bẹ̀rẹ̀ sí ṣàkóso gẹ́gẹ́ bí Ọba Ìjọba Ọlọ́run títí di ọdún 1914. Láìpẹ́ sí ìgbà yẹn, àwọn nǹkan kan ṣẹlẹ̀ láàárín àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró tó wà lórí ilẹ̀ ayé, ìyẹn sì fi onírúurú ọ̀nà jọ irú ohun tó ṣẹlẹ̀ sí àwọn Júù tó wà nígbèkùn ní ọ̀rúndún kẹfà ṣááju Sànmánì Tiwa. Kódà, ohun tó ṣẹlẹ̀ sí àwọn Kristẹni wọ̀nyẹn tún jẹ́ ọ̀nà tí àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà gbà ṣẹ lọ́nà ńlá.
Ìgbèkùn àti Ìdáǹdè Òde Òní
16. Wàhálà wo ló wáyé bí Jésù ṣe gorí ìtẹ́ lọ́dún 1914?
16 Wàhálà kárí ayé, irú èyí tí kò ṣẹlẹ̀ rí, ló wáyé nígbà tí Jésù gorí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba lọ́dún 1914. Kí ló fà á? Ohun tó fà á ni pé, bí Jésù ṣe di Ọba, ńṣe ló lé Sátánì àti àwọn ẹ̀dá ẹ̀mí burúkú yòókù kúrò ní ọ̀run. Bó sì ṣe di pé Sátánì kò lè kúrò ní àyíká ayé yìí mọ́, ló bá dojú ogun kọ àwọn ẹni mímọ́ tí ó ṣẹ́ kù, ìyẹn àṣẹ́kù àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró. (Ìṣípayá 12:7-12, 17) Ọ̀ràn náà dé ògógóró rẹ̀ lọ́dún 1918, nígbà tó di pé iṣẹ́ ìwàásù láwùjọ fẹ́rẹ̀ẹ́ dáwọ́ dúró, tí wọ́n sì kó àwọn tó di ipò pàtàkì mú nínú àwọn òṣìṣẹ́ Watch Tower Society sẹ́wọ̀n lórí ẹ̀sùn èké pé wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ìjọba. Ìyẹn ni àwọn ìránṣẹ́ Jèhófà ti òde òní fi dèrò ìgbèkùn nípa tẹ̀mí, èyí tó dà bí irú ìgbèkùn nípa ti ara tí àwọn Júù ayé àtijọ́ lọ. Ló bá di pé ẹ̀gàn ńláǹlà fẹ́ bá wọn.
17. Ọ̀nà wo ni àyípadà gbà dé bá ipò àwọn ẹni àmì òróró lọ́dún 1919, báwo sì ni wọ́n ṣe dẹni táa fún lókun nígbà náà lọ́hùn-ún?
17 Ṣùgbọ́n ipò ìgbèkùn àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run kò wà fún ìgbà pípẹ́. Ní March 26, 1919, wọ́n tú àwọn òṣìṣẹ́ wọ̀nyẹn sílẹ̀, wọ́n sì wá fagi lé gbogbo ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn wọ́n. Ni Jèhófà wá tú ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ sórí àwọn èèyàn rẹ̀ tó dá nídè, ó tipa bẹ́ẹ̀ fún wọn lókun láti lè ṣe iṣẹ́ tí ń bẹ níwájú wọn. Àwọn náà sì fi ìdùnnú ṣe bí ìpè yìí ṣe wí, ìyẹn ni pé kí wọ́n wá “gba omi ìyè lọ́fẹ̀ẹ́.” (Ìṣípayá 22:17) Wọ́n ra “wáìnì àti wàrà, àní láìsí owó àti láìsí ìdíyelé,” wọ́n sì di ẹni tó lókun nípa tẹ̀mí láti lè mójú tó ìbísí ńláǹlà tó máa tó wáyé, ìbísí tí àwọn ẹni àmì òróró kò tilẹ̀ mọ̀ tẹ́lẹ̀.
Ogunlọ́gọ̀ Ńlá Sáré Tọ Ẹni Àmì Òróró Ọlọ́run Wá
18. Ẹgbẹ́ méjì wo ló wà nínú àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù Kristi, kí ni wọ́n sì pa pọ̀ jẹ́ lóde òní?
18 Àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù ń retí láti nípìn-ín nínú ọ̀kan nínú ìrètí méjì. Àkọ́kọ́, “agbo kékeré” tí iye wọ́n jẹ́ ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì ni a kó jọ pọ̀, ìyẹn àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró tó jẹ́ ẹ̀yà Júù àtàwọn tó jẹ́ Kèfèrí, tí wọ́n pa pọ̀ jẹ́ “Ísírẹ́lì Ọlọ́run,” tí wọ́n sì ń retí láti bá Jésù ṣàkóso nínú Ìjọba rẹ̀ ọ̀run. (Lúùkù 12:32; Gálátíà 6:16; Ìṣípayá 14:1) Ìkejì, ní àwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí, “ogunlọ́gọ̀ ńlá” ti “àwọn àgùntàn mìíràn” ti yọjú. Àwọn wọ̀nyí ń retí láti wà láàyè títí láé nínú Párádísè orí ilẹ̀ ayé. Kí ìpọ́njú ńlá tó bẹ́ sílẹ̀, ògìdìgbó yìí, tí wọn kò ní iye kan pàtó, ń bá agbo kékeré ṣiṣẹ́ pọ̀, tí agbo méjèèjì sí para pọ̀ di “agbo kan” lábẹ́ “olùṣọ́ àgùntàn kan.”—Ìṣípayá 7:9, 10; Jòhánù 10:16.
-
-
Ọ̀rọ̀ Ìrètí fún Àwọn Ìgbèkùn Tí Ìrẹ̀wẹ̀sì Ọkàn BáÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
b Jésù ṣì ń bá a lọ láti bójú tó iṣẹ́ sísọni di ọmọ ẹ̀yìn yìí. (Ìṣípayá 14:14-16) Lóde òní, Jésù ni àwọn Kristẹni lọ́kùnrin lóbìnrin kà sí Orí ìjọ. (1 Kọ́ríńtì 11:3) Bí ó bá sì tó àkókò lójú Ọlọ́run, Jésù yóò ṣe ojúṣe “aṣáájú àti aláṣẹ” ní ọ̀nà mìíràn, nígbà tó bá dojú ogun àjàṣẹ́gun kọ àwọn ọ̀tá Ọlọ́run nígbà ogun Amágẹ́dọ́nì.—Ìṣípayá 19:19-21.
-
-
Ọ̀rọ̀ Ìrètí fún Àwọn Ìgbèkùn Tí Ìrẹ̀wẹ̀sì Ọkàn BáÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 239]
Jésù fi hàn pé òun ni “aṣáájú àti aláṣẹ” fún àwọn àwùjọ orílẹ̀-èdè
-