-
Ìwé Kan Tí Ó Wúlò Fún Ìgbésí Ayé Òde ÒníÌwé kan tí ó Wà fún Gbogbo Ènìyàn
-
-
Ní ìyàtọ̀ sí èyí, Bíbélì fúnni ní ìmọ̀ràn tí ó ṣeé gbára lé, tí ó sì wà déédéé lórí ọ̀ràn ìgbéyàwó. Ó gbà pé àwọn ipò tí ó burú lé kenkà kan lè mú kí a yọ̀ǹda fún ìkọ̀sílẹ̀. (Mátíù 19:9) Lẹ́sẹ̀ kan náà, ó bu ẹnu àtẹ́ lu ìkọ̀sílẹ̀ tí kò lẹ́sẹ̀ńlẹ̀. (Málákì 2:14-16) Ó bu ẹnu àtẹ́ lu àìṣòótọ́ nínú ìgbéyàwó pẹ̀lú. (Hébérù 13:4) Ó sọ pé ẹ̀jẹ́ àdéhùn ni ìgbéyàwó jẹ́, pé: “Ìdí nìyẹn tí ọkùnrin yóò ṣe fi baba àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀ tí yóò sì fà mọ́ aya rẹ̀, wọn yóò sì di ara kan.”a—Jẹ́nẹ́sísì 2:24; Mátíù 19:5, 6.
-
-
Ìwé Kan Tí Ó Wúlò Fún Ìgbésí Ayé Òde ÒníÌwé kan tí ó Wà fún Gbogbo Ènìyàn
-
-
a Ọ̀rọ̀ Hébérù náà, da·vaqʹ, tí a túmọ̀ sí “fà mọ́” níhìn-ín, “ní òye ti dídìrọ̀mọ́ ẹnì kan láti inú ìfẹ́ni àti ìdúróṣinṣin.”4 Ní èdè Gírí ìkì, ọ̀rọ̀ tí a túmọ̀ sí “yóò fà mọ́” nínú Mátíù 19:5 ní ìbátan pẹ̀lú ọ̀rọ̀ tí ó túmọ̀ sí “láti lẹ̀ pọ̀” “láti rẹ́ pọ̀,” “láti so pọ̀ dan-indan-in.”5
-