-
Ṣé Ò Ń Jẹ́ Kí “Ọgbọ́n Tó Wá Láti Òkè” Darí Rẹ?Sún Mọ́ Jèhófà
-
-
11 Kí ló yẹ kó o ṣe tó o bá rí i pé o ti ṣe ohun tó dun arákùnrin tàbí arábìnrin kan? Jésù sọ pé: “Tí o bá ń mú ẹ̀bùn rẹ bọ̀ níbi pẹpẹ, tí o sì rántí níbẹ̀ pé arákùnrin rẹ ní ohun kan lòdì sí ọ, fi ẹ̀bùn rẹ sílẹ̀ níbẹ̀ níwájú pẹpẹ, kí o sì lọ. Kọ́kọ́ wá àlàáfíà pẹ̀lú arákùnrin rẹ, lẹ́yìn náà, kí o pa dà wá fi ẹ̀bùn rẹ rúbọ.” (Mátíù 5:23, 24) Ìyẹn fi hàn pé ńṣe ló yẹ kó o lọ bá arákùnrin rẹ, kẹ́ e lè jọ sọ̀rọ̀. Àmọ́ kí ló yẹ kó o fi sọ́kàn? Ó yẹ kó o fi sọ́kàn pé ńṣe lo fẹ́ “wá àlàáfíà” pẹ̀lú ẹ̀.b Kíyẹn lè ṣeé ṣe, ó yẹ kó o gbà pẹ̀lú ẹ̀ pé ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn dùn ún lóòótọ́. Tó o bá fi sọ́kàn pé ṣe lo fẹ́ kí àlàáfíà jọba, tí ìwà àti ìṣe rẹ sì fi hàn bẹ́ẹ̀, ó ṣeé ṣe kẹ́ ẹ yanjú ọ̀rọ̀ náà, kẹ́ ẹ bẹ ara yín, kẹ́ ẹ sì dárí ji ara yín. Tó o bá ṣe gbogbo ohun tó o lè ṣe láti wá àlàáfíà, ńṣe lò ń fi hàn pé ọgbọ́n Ọlọ́run ń darí rẹ.
-
-
Ṣé Ò Ń Jẹ́ Kí “Ọgbọ́n Tó Wá Láti Òkè” Darí Rẹ?Sún Mọ́ Jèhófà
-
-
b Ọ̀rọ̀ Gíríìkì tá a tú sí “wá àlàáfíà” túmọ̀ sí “kí àwọn tó ń bára wọn ṣọ̀tá pa dà di ọ̀rẹ́.” Torí náà, ohun tí ẹni tó ń wá àlàáfíà fẹ́ ṣe ni pé kó gbìyànjú láti ran ẹni tó ṣẹ̀ lọ́wọ́, tó bá ṣeé ṣe, kí ẹni náà lè mú gbogbo ohun tó ń bí i nínú kúrò lọ́kàn.—Róòmù 12:18.
-