-
Àwọn Kristian Obìnrin yẹ fún Ọlá àti Ọ̀wọ̀Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | July 15
-
-
10 Nípa ìkọ̀sílẹ̀, a bi Jesu ní ìbéèrè yìí pé: “Ó ha bófinmu fún ọkùnrin lati kọ aya rẹ̀ sílẹ̀ lórí onírúurú ìdí gbogbo?” Ní ìbámu pẹ̀lú àkọsílẹ̀ Marku, Jesu sọ pé: “Ẹni yòówù tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀ [bíkòṣe lórí ìpìlẹ̀ àgbèrè] tí ó sì gbé òmíràn níyàwó ṣe panṣágà lòdì sí i, bí obìnrin kan, lẹ́yìn kíkọ ọkọ rẹ̀ sílẹ̀, bá sì ṣe ìgbéyàwó pẹlu òmíràn pẹ́nrẹ́n, ó ṣe panṣágà.” (Marku 10:10-12; Matteu 19:3, 9) Àwọn ọ̀rọ̀ tí a sọ wẹ́rẹ́ wọ̀nyẹn fi ọ̀wọ̀ hàn fún iyì àwọn obìnrin. Báwo ni ó ṣe jẹ́ bẹ́ẹ̀?
-
-
Àwọn Kristian Obìnrin yẹ fún Ọlá àti Ọ̀wọ̀Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | July 15
-
-
13. Nípa ìkọ̀sílẹ̀, báwo ni Jesu ṣe fi hàn pé lábẹ́ ètò-ìgbékalẹ̀ Kristian, ọ̀pá-ìdiwọ̀n kan ni yóò wà fún àtọkùnrin àtobìnrin?
13 Ẹ̀kẹta ni pé, nípa àpólà-ọ̀rọ̀ náà “lẹ́yìn kíkọ ọkọ rẹ̀ sílẹ̀,” Jesu mọ ẹ̀tọ́ obìnrin láti kọ ọkọ aláìṣòótọ́ sílẹ̀—àṣà tí a mọ̀ dájúdájú ṣùgbọ́n tí kò wọ́pọ̀ lábẹ́ òfin Júù ní àkókò náà.c Wọ́n sọ pé “obìnrin kan ni a lè kọ̀ sílẹ̀ bóyá ó tẹ́ ẹ lọ́rùn tàbí bẹ́ẹ̀kọ́, ṣùgbọ́n níti ọkùnrin kìkì bí ó bá tẹ́ ẹ lọ́rùn.” Bí ó ti wù kí ó rí, bí Jesu ti sọ, lábẹ́ ètò-ìgbékalẹ̀ Kristian, ọ̀pá-ìdiwọ̀n kan náà ni a óò lò fún àtọkùnrin àtobìnrin.
-