-
“A Ti Fìmọ̀ Ṣọ̀kan”“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
9. Àwọn àǹfààní wo ló wà nínú àbá tí Jémíìsì mú wá?
9 Ṣé àbá tí Jémíìsì mú wá yìí dáa? Bẹ́ẹ̀ ni, torí ohun tó sọ yẹn làwọn àpọ́sítélì àtàwọn alàgbà tó kù wá ṣe. Àǹfààní wo nìyẹn mú wá? Lákọ̀ọ́kọ́ ná, àbá tí Jémíìsì mú wá yìí ò ní jẹ́ kí wọ́n “dààmú” àwọn Kèfèrí tó di Kristẹni tàbí ‘yọ wọ́n lẹ́nu’ pé wọ́n gbọ́dọ̀ máa pa Òfin Mósè mọ́. (Ìṣe 15:19; Bíbélì Ìròyìn Ayọ̀) Àǹfààní míì ni pé ìpinnu yìí ò ní jẹ́ kí wọ́n ṣe ohun tó máa kó bá ẹ̀rí ọkàn àwọn Júù tó jẹ́ Kristẹni. Ó ṣe tán, ọjọ́ pẹ́ táwọn Júù yẹn ti ń gbọ́ nípa “Mósè . . . torí wọ́n ń ka ìwé rẹ̀ sókè nínú àwọn sínágọ́gù ní gbogbo sábáàtì.”b (Ìṣe 15:21) Ohun tí Jémíìsì sọ yìí á tún jẹ́ káwọn Júù àtàwọn Kèfèrí tó di Kristẹni túbọ̀ sún mọ́ra wọn dáadáa. Èyí tó ṣe pàtàkì jù ni pé, ó máa múnú Jèhófà Ọlọ́run dùn, torí ìpinnu tí wọ́n ṣe yẹn máa bá ìfẹ́ rẹ̀ mu. Ẹ ò rí i pé ìpinnu yìí máa wúlò gan-an láti yanjú ìṣòro tó fẹ́ ba àlàáfíà àti ìṣọ̀kan ìjọ Ọlọ́run jẹ́! Àpẹẹrẹ tó dáa lèyí sì jẹ́ fáwa Kristẹni lónìí!
-
-
“A Ti Fìmọ̀ Ṣọ̀kan”“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
b Ó bọ́gbọ́n mu bí Jémíìsì ṣe fa ọ̀rọ̀ yọ látinú àwọn ìwé tí Mósè kọ. Ara àwọn ìwé náà ni Òfin Mósè àtàwọn àkọsílẹ̀ tó jẹ́ ká mọ ohun tó jẹ́ ìfẹ́ Ọlọ́run fáwa èèyàn kí Òfin Mósè tó dé. Bí àpẹẹrẹ, a lè rí àlàyé tó ṣe kedere nípa ojú tí Ọlọ́run fi ń wo ẹ̀jẹ̀, àgbèrè àti panṣágà nínú ìwé Jẹ́nẹ́sísì. (Jẹ́n. 9:3, 4; 20:2-9; 35:2, 4) Lọ́nà yìí, Jèhófà jẹ́ ká mọ àwọn ìlànà tó yẹ kí gbogbo èèyàn máa tẹ̀ lé, bóyá wọ́n jẹ́ Júù tàbí Kèfèrí.
-