-
Ṣíṣèdájọ́ Aṣẹ́wó Burúkú NáàÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
1. Kí ni ọ̀kan nínú àwọn áńgẹ́lì méje náà ṣí payá fún Jòhánù?
GBOGBO ìbínú òdodo Jèhófà tó wà nínú àwokòtò méjèèje la gbọ́dọ̀ dà jáde pátápátá! Nígbà tí áńgẹ́lì kẹfà da ohun tó wà nínú àwokòtò rẹ̀ jáde sí ibi tí Bábílónì ìgbàanì wà, ó jẹ́ àpẹẹrẹ bí ìyọnu ṣe máa bá Bábílónì Ńlá, bí àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó máa yọrí sí ogun Amágẹ́dọ́nì ṣe ń yára kánkán ṣẹlẹ̀. (Ìṣípayá 16:1, 12, 16) Nísinsìnyí, ó dà bíi pé, áńgẹ́lì yìí kan náà ló ń ṣí ìdí tí Jèhófà fi ń mú àwọn ìdájọ́ òdodo rẹ̀ ṣẹ àti bó ṣe ń mú un ṣẹ payá. Kàyéfì ṣe Jòhánù torí ohun tó gbọ́ tó sì rí lẹ́yìn ìyẹn, ó ní: “Ọ̀kan lára àwọn áńgẹ́lì méje tí wọ́n ní àwokòtò méje lọ́wọ́ sì wá, ó sì bá mi sọ̀rọ̀, pé: ‘Wá, èmi yóò fi ìdájọ́ lórí aṣẹ́wó ńlá tí ó jókòó lórí omi púpọ̀ hàn ọ́, ẹni tí àwọn ọba ilẹ̀ ayé bá ṣe àgbèrè, nígbà tí ó jẹ́ pé àwọn tí ń gbé ilẹ̀ ayé ni a ti mú kí wọ́n mu wáìnì àgbèrè rẹ̀ ní àmupara.’”—Ìṣípayá 17:1, 2.
2. Ẹ̀rí wo ló wà pé “aṣẹ́wó ńlá náà” (a) kì í ṣe Róòmù ìgbàanì? (b) kì í ṣe iṣẹ́ ajé aládàá ńlá? (d) jẹ́ ètò ìsìn?
2 “Aṣẹ́wó ńlá náà”! Kí nìdí tí orúkọ náà fi burú tó bẹ́ẹ̀? Ta ni obìnrin náà? Àwọn kan sọ pé Róòmù ìgbàanì ni aṣẹ́wó ìṣàpẹẹrẹ yìí. Ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè olóṣèlú ni Róòmù. Aṣẹ́wó yìí ń bá àwọn ọba ilẹ̀ ayé ṣàgbèrè, ó sì hàn gbangba pé àwọn ọba Róòmù wà nínú èyí. Yàtọ̀ síyẹn, lẹ́yìn ìparun rẹ̀, “àwọn ọba ilẹ̀ ayé” ni Ìwé Mímọ́ sọ pé wọ́n ṣọ̀fọ̀ lórí ikú rẹ̀. Nítorí náà, obìnrin náà kò lè jẹ́ ètò ìṣèlú. (Ìṣípayá 18:9, 10) Ní àfikún, níwọ̀n bí àwọn oníṣòwò ayé ti ń ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, obìnrin náà kò lè ṣàpẹẹrẹ iṣẹ́ ajé aládàá ńlá. (Ìṣípayá 18:15, 16) Àmọ́ Bíbélì sọ pé ‘àwọn ìṣe ìbẹ́mìílò rẹ̀ ti ṣi gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè lọ́nà.’ (Ìṣípayá 18:23) Èyí jẹ́ kó ṣe kedere pé aṣẹ́wó ńlá náà ní láti jẹ́ ètò ìsìn tó kárí ayé.
3. (a) Kí nìdí tó fi jẹ́ pé ohun tí aṣẹ́wó ńlá náà dúró fún gbọ́dọ̀ ju ìjọ Kátólíìkì tàbí gbogbo àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì lọ? (b) Àwọn ẹ̀kọ́ Bábílónì wo là ń rí nínú ọ̀pọ̀ jù lọ àwọn ìsìn Ìlà Oòrùn àtàwọn ẹ̀ya ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì? (d) Kí ni kádínà ìjọ Kátólíìkì náà John Henry Newman sọ nípa ìpilẹ̀ṣẹ̀ ọ̀pọ̀ ẹ̀kọ́, ayẹyẹ, àtàwọn àṣà ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì? (Wo àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé.)
3 Ìsìn wo ni obìnrin yìí dúró fún? Ṣé ìjọ Kátólíìkì ni, bí àwọn kan ṣe sọ? Àbí gbogbo àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ló dúró fún? Rárá o. Ó gbọ́dọ̀ tóbi ju àwọn wọ̀nyí lọ bó bá máa lágbára láti ṣi gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè lọ́nà. Ní tòótọ́, ó jẹ́ ilẹ̀ ọba ìsìn èké àgbáyé, ìyẹn gbogbo ìsìn èké lápapọ̀. Ohun tó fi hàn pé inú àwọn ohun ìjìnlẹ̀ Bábílónì ló ti pilẹ̀ ni pé ọ̀pọ̀ ẹ̀kọ́ àtàwọn àṣà Bábílónì wọ́pọ̀ láàárín àwọn ìsìn jákèjádò ayé. Bí àpẹẹrẹ, ọ̀pọ̀ jù lọ àwọn ìsìn Ìlà Oòrùn àtàwọn ẹ̀ya ìsìn Ṣọ́ọ̀ṣì ló gbà gbọ́ pé ẹ̀dá èèyàn ti jogún ọkàn tí kì í kú, pé iná ọ̀run àpáàdì wà àti pé ọlọ́run mẹ́talọ́kan wà. Ìsìn èké, tó ti wà láti ohun tó lé ní ẹgbàajì [4,000] ọdún sẹ́yìn ní ìlú Bábílónì ìgbàanì, ti di ohun àràmàǹdà òde òní tá a mọ̀ sí Bábílónì Ńlá.a Àmọ́, kí nìdí tó fi jẹ́ pé orúkọ tó ń kóni nírìíra náà, “aṣẹ́wó ńlá” ni Ìwé Mímọ́ fi ṣàpèjúwe rẹ̀?
4. (a) Báwo ni Ísírẹ́lì ìgbàanì ṣe ṣe àgbèrè? (b) Ọ̀nà títayọ wo ni Bábílónì Ńlá gbà ṣe àgbèrè?
4 Àkókò Nebukadinésárì ni ògo Bábílónì (tàbí Bábélì, tó túmọ̀ sí “Ìdàrúdàpọ̀”) dé òtéńté rẹ̀. Ó jẹ́ ilẹ̀ tí ọ̀rọ̀ ìsìn àti ìṣèlú ti wọnú ara wọn gan-an, níbi tí àwọn tẹ́ńpìlì àtàwọn ilé ìsìn kéékèèké tó lé ní ẹgbẹ̀rún wà. Àwọn ẹgbẹ́ àlùfáà rẹ̀ lágbára gan-an. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọjọ́ pẹ́ tí Bábílónì ti dẹ́kun jíjẹ́ agbára ayé, Bábílónì Ńlá tó jẹ́ ètò ìsìn ṣì wà, àti pé bíi ti Bábílónì ìgbàanì, ó ṣì ń wá ọ̀nà láti darí bí nǹkan ṣe ń lọ nínú ètò ìṣèlú. Ṣùgbọ́n ṣé Ọlọ́run fọwọ́ sí dída ọ̀rọ̀ ìsìn mọ́ ìṣèlú? Nínú Ìwé Mímọ́ Lédè Hébérù, Bíbélì sọ pé Ísírẹ́lì sọ ara rẹ̀ di kárùwà nígbà tó lọ́wọ́ nínú ìjọsìn èké, tó sì lọ bá àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn ní àjọṣepọ̀, dípò kó ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Jèhófà. (Jeremáyà 3:6, 8, 9; Ìsíkíẹ́lì 16:28-30) Bábílónì Ńlá pẹ̀lú ń ṣe àgbèrè. Àní ọ̀ràn tiẹ̀ ta yọ ní ti pé ó ti ṣe ohunkóhun yòówù tó bá rí i pé ó pọn dandan kó bàa lè máa darí àwọn ọba tó ń ṣàkóso lórí ilẹ̀ ayé, kó sì máa lo agbára rẹ̀ lórí wọn.—1 Tímótì 4:1.
5. (a) Kí làwọn àlùfáà ìsìn máa ń fẹ́ káwọn èèyàn rí wọn pé àwọn ń ṣe? (b) Kí nìdí tí ìfẹ́ fún jíjẹ́ gbajúmọ̀ nínú ayé fi ta ko àwọn ọ̀rọ̀ Jésù Kristi ní tààràtà?
5 Lónìí, ńṣe làwọn olórí ìsìn máa ń forí ṣe fọrùn ṣe kí wọ́n lè di ipò gíga mú nínú ìjọba, láwọn ilẹ̀ kan sì rèé, àwọn àtàwọn olóṣèlú ni wọ́n jọ ń ṣèjọba, àní wọ́n tiẹ̀ tún ń ní ipò nínú ìgbìmọ̀ alábẹ-ṣékélé ìjọba. Lọ́dún 1988, àwọn àlùfáà ṣọ́ọ̀ṣì Pùròtẹ́sítáǹtì méjì táwọn èèyàn mọ̀ dáadáa ló díje fún ipò ààrẹ orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà. Àwọn aṣáájú nínú Bábílónì Ńlá fẹ́ràn káwọn èèyàn máa rí wọn ṣáá; ọ̀pọ̀ ìgbà ni fọ́tò bí wọ́n ṣe ń ṣe wọlé-wọ̀de pẹ̀lú àwọn gbajúmọ̀ olóṣèlú máa ń wà nínú àwọn ìwé ìròyìn. Àmọ́ ti Jésù ò rí bẹ́ẹ̀ rárá o, ńṣe ló kẹ̀yìn sí ọ̀rọ̀ ìṣèlú pátápátá, ó sì sọ nípa àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé: “Wọn kì í ṣe apá kan ayé, gan-an gẹ́gẹ́ bí èmi kì í ti í ṣe apá kan ayé.”—Jòhánù 6:15; 17:16; Mátíù 4:8-10; tún wo Jákọ́bù 4:4 pẹ̀lú.
‘Iṣẹ́ Aṣẹ́wó’ Òde Òní
6, 7. (a) Báwo ni Ẹgbẹ́ Násì ti Hitler ṣe dé orí àlééfà ní Jámánì? (b) Báwo ni àdéhùn ìmùlẹ̀ tí Póòpù ṣe pẹ̀lú ilẹ̀ Jámánì tí ìjọba Násì ń ṣàkóso ṣe ran Hitler lọ́wọ́ nínú gbogbo akitiyan rẹ̀ láti ṣàkóso lórí ayé?
6 Nípasẹ̀ àtojúbọ̀ rẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ ìṣèlú, aṣẹ́wó ńlá náà ti kó aráyé sínú ìbànújẹ́ tí kò ṣeé fẹnu sọ. Bí àpẹẹrẹ, ronú nípa àwọn ohun tó ṣẹlẹ̀ kó tó di pé Hitler gorí àlééfà ní Jámánì. Àwọn ohun wọ̀nyẹn burú débi pé ì bá wu àwọn kan pé kí wọ́n pa á rẹ́ pátápátá kúrò nínú àwọn ìwé ìtàn. Ní May 1924, aṣojú méjìlélọ́gbọ̀n ni Ẹgbẹ́ Násì ní nínú Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin ilẹ̀ Jámánì. Nígbà tó fi máa di May 1928, ìwọ̀nyí ti dín kù sí méjìlá. Àmọ́, ọrọ̀ ajé dẹnu kọlẹ̀ lágbàáyé lọ́dún 1930; ẹgbẹ́ Násì sì lo àǹfààní yìí láti yára kọ́fẹ padà, tó fi di pé ẹgbẹ́ náà ní igba ó lé ọgbọ̀n [230] aṣojú lára ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ [608] aṣojú nígbà táwọn èèyàn Jámánì dìbò ní July 1932. Láìpẹ́ lẹ́yìn náà, olórí ìjọba tẹ́lẹ̀ rí Franz von Papen, ẹni tí póòpù ti fi oyè Ajagungboyè dá lọ́lá, dìde fún ìrànlọ́wọ́ Ẹgbẹ́ Násì. Gẹ́gẹ́ bí àwọn òpìtàn ti wí, von Papen ní àfojúsùn pé Ilẹ̀ Ọba Róòmù Mímọ́ á di àkọ̀tun. Òtúbáńtẹ́ ni gbogbo ohun tó ṣe níwọ̀nba àkókò kúkúrú tó fi jẹ́ olórí ìjọba já sí, nítorí náà nísinsìnyí ó ń wá bí agbára tún ṣe máa tẹ̀ ẹ́ lọ́wọ́ nípasẹ̀ àwọn Násì. Nígbà tó fi máa di January 1933, ó ti sún ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀gá láwọn ilé iṣẹ́ ńláńlá láti gbárùkù ti Hitler. Ó sì tún lo ọgbọ́n àrékérekè láti rí i dájú pé Hitler di olórí ìjọba ní January 30, 1933. Wọ́n fi òun fúnra rẹ̀ ṣe igbá kejì olórí ìjọba, Hitler sì lò ó láti wá ìtìlẹyìn àwọn ẹlẹ́sìn Kátólíìkì nílẹ̀ Jámánì. Láàárín oṣù méjì tí Hitler gba agbára, Hitler tú ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ká, ó fi ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn aṣáájú ẹgbẹ́ alátakò ránṣẹ́ sí àwọn ibùdó ìṣẹ́niníṣẹ̀ẹ́ láìjáfara, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í tẹ àwọn Júù lórí ba ní gbangba gbàǹgbà.
7 Ní July 20, 1933, ohun kan ṣẹlẹ̀ tó fi hàn pé Vatican, ìyẹn Ìjọba Póòpù, nífẹ̀ẹ́ sí agbára Ìjọba Násì tó ń pọ̀ sí i. Lọ́jọ́ náà, nílùú Róòmù, Kádínà Pacelli (ẹni tó wá di Póòpù Pius Kejìlá lẹ́yìn náà) fọwọ́ sí ìwé àdéhùn ìmùlẹ̀ kan láàárín Vatican àti ilẹ̀ Jámánì tí ìjọba Násì ń ṣàkóso. Von Papen fọwọ́ sí ìwé náà gẹ́gẹ́ bí aṣojú Hitler, ibẹ̀ ni Pacelli sì ti fi oyè pàtàkì kan tí póòpù fi ń dáni lọ́lá, ìyẹn òye Àgbélébùú Títóbilọ́lá ti Ẹgbẹ́ Piusb dá von Papen lọ́lá. Nínú ìwé tí Tibor Koeves kọ tó pè ní Satan in Top Hat, ó sọ̀rọ̀ nípa èyí, ó ní: “Àdéhùn Ìmùlẹ̀ náà jẹ́ ìjagunmólú fún Hitler. Àdéhùn yẹn ni ìtìlẹyìn tó kọ́kọ́ rí gbà láti ibòmíràn yàtọ̀ sí ilẹ̀ Jámánì, èyí sì wá láti orísun tó ga jù lọ láyé.” Ohun tí àdéhùn ìmùlẹ̀ náà béèrè fún ni pé kí Póòpù yọwọ́ ìtìlẹyìn rẹ̀ kúrò nínú ẹgbẹ́ Catholic Center Party ti Jámánì, kó sì tipa bẹ́ẹ̀ fohùn sí “ìjọba apàṣẹwàá”c Hitler tó jẹ́ ẹgbẹ́ kan ṣoṣo. Síwájú sí i, ìpínrọ̀ kẹrìnlá nínú àdéhùn náà sọ pé: “Ó dìgbà tí gómìnà tí Ìjọba Násì fi jẹ bá ti rí i dájú ṣáká pé kò sí iyèméjì kankan nípa bóyá kò ní sí wàhálà ìṣèlú kí wọ́n tó lè yan àwọn olórí bíṣọ́ọ̀bù, àwọn bíṣọ́ọ̀bù, àtàwọn bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ sípò.” Ní òpin ọdún 1933 (tí Póòpù Pius Kọkànlá pè ní “Ọdún Mímọ́”), ìtìlẹyìn Ìjọba Póòpù ti di ọ̀kan pàtàkì lára ohun tó mú kí gbogbo akitiyan Hitler láti ṣàkóso lórí ayé ṣeé ṣe.
8, 9. (a) Kí ni Ìjọba Póòpù àti Ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì àti àwọn àlùfáà rẹ̀ ṣe sí ìwà ìkà Násì? (b) Kí làwọn bíṣọ́ọ̀bù Kátólíìkì ní Jámánì sọ ní ìbẹ̀rẹ̀ Ogun Àgbáyé Kejì? (d) Kí làjọṣe tó wà láàárín ìsìn àti ìṣèlú ti yọrí sí?
8 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ̀nba kéréje lára àwọn àlùfáà àtàwọn obìnrin ajẹ́jẹ̀ẹ́ ìnìkàngbé fi ẹ̀hónú wọn hàn sí ìwà ìkà Hitler tí ìyà sì jẹ wọ́n nítorí ẹ̀, ibùjókòó Ìjọba Póòpù àti Ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlùfáà wọn ṣètìlẹyìn fún ìwà ìkà ìjọba Násì, èyí tí wọ́n kà sóhun tí ò ní jẹ́ kí ìjọba Kọ́múníìsì ayé rọ́wọ́ mú kárí ayé. Wọ́n ń ṣètìlẹyìn fún ìjọba Násì, bóyá ní tààràtà tàbí lábẹ́lẹ̀. Ńṣe ni Póòpù Pius Kejìlá jókòó gbẹdẹmukẹ ní ibùjókòó rẹ̀, tó ń wo bí wọ́n ṣe ń fẹ́ pa àwọn Júù run àti bí wọ́n ṣe ń ṣe inúnibíni oníwà ìkà sáwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà àtàwọn mìíràn, kò sì sọ pé ohun tí ìjọba ń ṣe ò dáa. Bẹ́ẹ̀ sì rèé, ó yani lẹ́nu pé nígbà tí Póòpù John Paul Kejì ń ṣèbẹ̀wò sí Jámánì ní May 1987, ó gbóṣùbà fún àlùfáà olóòótọ́ inú kan torí bí kò ṣe gbè sẹ́yìn ìjọba Násì. Kí ni ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn àlùfáà Jámánì yòókù ń ṣe lákòókò ìjọba Hitler tó ń kó ìpayà bá àwọn èèyàn? Lẹ́tà kan táwọn bíṣọ́ọ̀bù Kátólíìkì ilẹ̀ Jámánì kọ sáwọn olùre ṣọ́ọ̀ṣì ní September 1939, nígbà tí Ogun Àgbáyé Kejì bẹ́ sílẹ̀ ṣàlàyé lórí kókó yìí. Ó kà lápá kan pé: “Ní wákàtí tọ́rọ̀ ti dojú ọ̀gbagadè yìí, a gba àwọn ọmọ ogun wa ní Kátólíìkì níyànjú pé kí wọ́n ṣe iṣẹ́ wọn bí iṣẹ́ nípa gbígbọ́ràn sí Hitler Abàṣẹwàá lẹ́nu kí wọ́n sì múra tán láti fi gbogbo ara wọn fún ogun yìí. A rọ àwọn ọmọ ìjọ láti dara pọ̀ nínú àdúrà gbígbóná janjan pé kí Ọlọ́run bá wa lọ́wọ́ sí ogun yìí kó lè yọrí sí rere kó sì bù kún un.”
9 Irú ọgbọ́n mẹ̀bẹ́mẹ̀yẹ̀ tí Ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì ń lò nínú àjọṣe rẹ̀ pẹ̀lú ètò ìṣèlú jẹ́ ká rí bí ìsìn ti ṣe ń ṣe aṣẹ́wó láti ẹgbàajì [4,000] ọdún sẹ́yìn, tí wọ́n ń fa ojú Ìjọba elétò òṣèlú mọ́ra kí wọ́n lè ní agbára, kí wọ́n sì rí àǹfààní jẹ. Irú àwọn àjọṣe tó wà láàárín ìsìn àti ìṣèlú bẹ́ẹ̀ ti ṣokùnfà ogun àti inúnibíni, ó sì ti kó ìnira tó bùáyà bá ẹ̀dá èèyàn. Ẹ wo bí aráyé á ti láyọ̀ tó, pé ìdájọ́ Jèhófà lórí aṣẹ́wó ńlá náà kù sí dẹ̀dẹ̀. Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run mú ìdájọ́ náà wá láìpẹ́!
Ó Jókòó Lórí Omi Púpọ̀
10. Kí ni “omi púpọ̀” tí Bábílónì Ńlá fi ṣe ààbò, kí ló sì ń ṣẹlẹ̀ sí wọn?
10 Bábílónì ìgbàanì jókòó lórí omi púpọ̀, ìyẹn ni Odò Yúfírétì àti ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ ipa odò. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ ààbò fún un, wọ́n sì tún jẹ́ ibi tí owó ń bá wọlé fún un tó fi jẹ́ pé ọlọ́rọ̀ ni, kó tó di pé wọ́n gbẹ táútáú lóru ọjọ́ kan. (Jeremáyà 50:38; 51:9, 12, 13) Bábílónì Ńlá pẹ̀lú ń wojú “omi púpọ̀” láti dáàbò bò ó kó sì sọ ọ́ di ọlọ́rọ̀. Omi ìṣàpẹẹrẹ yìí ni “àwọn ènìyàn àti ogunlọ́gọ̀ àti orílẹ̀-èdè àti ahọ́n,” ìyẹn gbogbo ẹgbẹẹgbẹ̀rún mílíọ̀nù èèyàn tó ń jọba lé lórí tó sì ti gba àwọn ohun ìní tara lọ́wọ́ wọn. Ṣùgbọ́n àwọn omi wọ̀nyí náà ti ń gbẹ lọ, tó túmọ̀ sí pé wọ́n ti ń fawọ́ ìtìlẹyìn wọn sẹ́yìn.— Ìṣípayá 17:15; fi wé Sáàmù 18:4; Aísáyà 8:7.
11. (a) Báwo ni Bábílónì ìgbàanì ṣe ‘mú kí gbogbo ilẹ̀ ayé mu àmupara’? (b) Báwo ni Bábílónì Ńlá ṣe ‘mú kí gbogbo ilẹ̀ ayé mu àmupara’?
11 Síwájú sí i, Bíbélì tún ṣàpèjúwe Bábílónì ìgbàanì gẹ́gẹ́ bí “ife wúrà ní ọwọ́ Jèhófà, ó ń mú kí gbogbo ilẹ̀ ayé mu àmupara.” (Jeremáyà 51:7) Bábílónì ìgbàanì mú àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n wà nítòsí rẹ̀ tipátipá láti gbé àwọn ohun tó ń fi ìbínú Jèhófà hàn mì nípa ṣíṣẹ́gun wọn lójú ogun, tó sọ wọ́n di aláìlera bí ọ̀mùtípara. Lọ́nà yẹn, ó jẹ́ ohun èlò Jèhófà. Bábílónì Ńlá náà ti ja àjàṣẹ́gun débi pé ó ti di ilẹ̀ ọba tó kárí ayé. Ṣùgbọ́n, ó dájú pé òun kì í ṣe ohun èlò Ọlọ́run. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó ti sin “àwọn ọba ilẹ̀ ayé” tó ń bá ṣe àgbèrè ìsìn. Ó ti ṣe ohun táwọn ọba wọ̀nyí fẹ́ nípa lílo àwọn ẹ̀kọ́ èké rẹ̀ àtàwọn àṣà tó ń sọ àwọn èèyàn dẹrú láti fi sọ ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ “àwọn tí ń gbé ilẹ̀ ayé” di aláìlera gẹ́gẹ́ bí ọ̀mùtípara, àwọn tó jẹ́ pé ńṣe ni wọ́n kàn ń ṣe ohunkóhun táwọn alákòóso wọn bá sọ fún wọn láìjanpata rárá.
12. (a) Báwo ni ẹ̀ka Bábílónì Ńlá kan ní Japan ṣe fa ìtàjẹ̀sílẹ̀ púpọ̀ nígbà Ogun Àgbáyé Kejì? (b) Báwo la ṣe fa “àwọn omi” tó ń ṣètìlẹyìn fún Bábílónì Ńlá gbẹ ní Japan, kí sì ni èyí yọrí sí?
12 Àpẹẹrẹ kan tó hàn gbangba lórí ọ̀ràn yìí ni ilẹ̀ Japan tó jẹ́ ibi tí ìsìn Ṣintó ti ṣẹ̀ wá. Àwọn ọmọ ogun Japan tí wọ́n ti gbin èrò òdì sí lọ́kàn kà á sí ọlá gíga jù lọ láti fi ẹ̀mí wọn rúbọ fún olú ọba, ẹni tó jẹ́ ọlọ́run ìsìn Ṣintó tó ga jù lọ. Nígbà Ogun Àgbáyé Kejì, nǹkan bíi mílíọ̀nù kan ààbọ̀ [1,500,000] ọmọ ogun Japan ló kú lójú ogun; ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ pé gbogbo wọn lẹ́nì kọ̀ọ̀kan ni wọ́n ka títúúbá sí nǹkan àbùkù. Àmọ́ lẹ́yìn tí wọ́n ṣẹ́gun Japan, ó di dandan fún Olú Ọba Hirohito láti kó ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ pé òun jẹ́ ọlọ́run. Èyí yọrí sí fífa “àwọn omi” tí ń ṣètìlẹyìn fún ẹ̀ka Ṣintó nínú Bábílónì Ńlá gbẹ lọ́nà kíkàmàmà. Ó mà ṣe o, èyí jẹ́ lẹ́yìn tí ìsìn Ṣintó ti lóhùn sí ìtàjẹ̀sílẹ̀ tó pọ̀ rẹpẹtẹ lójú ogun ní Pàsífíìkì! Bí ìsìn Ṣintó ò ṣe lágbára mọ́ yìí ti mú kó ṣeé ṣe fún ohun tó ju ọ̀kẹ́ mẹ́wàá [200,000] àwọn ará Japan, tí ọ̀pọ̀ jù lọ wọn jẹ́ onísìn Ṣintó àti onísìn Búdà tẹ́lẹ̀ rí, láti ya ara wọn sí mímọ́, lẹ́yìn náà wọ́n ṣèrìbọmi, wọ́n sì di òjíṣẹ́ Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ.
-
-
Ṣíṣèdájọ́ Aṣẹ́wó Burúkú NáàÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
a Nínú ìwé Essay on the Development of Christian Doctrine, èyí tí kádínà Roman Kátólíìkì ti ọ̀rúndún kọkàndínlógún náà John Henry Newman kọ, ó fi hàn pé kì í ṣe inú ẹ̀sìn Kristẹni ni ọ̀pọ̀ ẹ̀kọ́ àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì apẹ̀yìndà, àwọn ayẹyẹ wọn àtàwọn àṣà tí wọ́n ń tẹ̀ lé ti wá. Ó wá ṣàlàyé pé: “Àtọ̀dọ̀ àwọn olórìṣà la ti kọ́ ìlò àwọn tẹ́ńpìlì tí a sì ya ìwọ̀nyí sí mímọ́ fún àwọn ẹni mímọ́ kan ní pàtó, tí a sì tún ń fi àwọn ẹ̀ka igi ṣe wọ́n lọ́ṣọ̀ọ́ nígbà míì; tùràrí, fìtílà, àti àbẹ́là; ẹ̀jẹ́ sísan lẹ́yìn téèyàn bá ti rí ìwòsàn gbà; omi mímọ́; ilé ààbò; àwọn ọjọ́ àti àsìkò mímọ́, ìlò kàlẹ́ńdà, ìtòlọ́wọ̀ọ̀wọ́rìn, àti ìsúre lórí pápá; aṣọ oyè àlùfáà, ìfárí oyè, òrùka ìgbéyàwó, yíyíjú sí Ìlà Oòrùn, ère táwọn Kristẹni wá ń lò lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn, bóyá sísun rárà àlùfáà, àti orin Kyrie Eleison [ìyẹn orin “Olúwa, Ṣàánú fún Wa”]. Gbogbo wọn pátá la kọ́ látọ̀dọ̀ àwọn olórìṣà, a sì sọ wọ́n di mímọ́ nípa lílò wọ́n nínú Ṣọ́ọ̀ṣì.”
“Jèhófà Olódùmarè” kò sọ irú ìbọ̀rìṣà bẹ́ẹ̀ di mímọ́, kàkà bẹ́ẹ̀ ńṣe ló sọ fún àwọn Kristẹni pé: “Ẹ jáde kúrò láàárín wọn, kí ẹ sì ya ara yín sọ́tọ̀, . . . kí ẹ sì jáwọ́ nínú fífọwọ́ kan ohun àìmọ́.”—2 Kọ́ríńtì 6:14-18.
-
-
Ṣíṣèdájọ́ Aṣẹ́wó Burúkú NáàÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
[Àpótí tó wà ní ojú ìwé 237]
Òǹkọ̀wé Churchill Tú Àṣírí ‘Ìwà Aṣẹ́wó’
Nínú ìwé rẹ̀ The Gathering Storm (1948), Winston Churchill sọ pé Hitler yan ọ̀gbẹ́ni Franz von Papen gẹ́gẹ́ bí aṣojú ilẹ̀ Jámánì ní ìlú Vienna “kó lè pa àwọn abẹnugan nínú òṣèlú ilẹ̀ Austria lẹ́nu mọ́ tàbí kó sọ wọ́n di alátìlẹyìn ilẹ̀ Jámánì.” Churchill tún fa ọ̀rọ̀ tí aṣojú ilẹ̀ Amẹ́ríkà tó wà ní Vienna sọ nípa von Papen yọ, pé: “Papen ò pẹ́ ọ̀rọ̀ sọ rárá bó ṣe ń pẹ̀gàn àwọn ará Austria . . . ó wá sọ fún mi pé . . . òun ní in lọ́kàn láti lo jíjẹ́ tí òun jẹ́ ọmọ ìjọ Kátólíìkì rere láti fi wá ìtìlẹ́yìn àwọn ará Austria, irú bíi Kádínà Innitzer.”
Lẹ́yìn tí Austria ti túúbá, tí àwọn ọmọ ogun Hitler tí wọ́n jẹ́ òǹrorò sì ti yan wọ Vienna, kádínà Innitzer tó jẹ́ ọmọ Ìjọ Kátólíìkì pàṣẹ pé kí gbogbo àwọn ṣọ́ọ̀ṣì Austria ta àsíá ìjọba Násì, kí wọ́n lu aago wọn, kí wọ́n sì gbàdúrà fún Adolf Hitler láti ṣayẹyẹ ọjọ́ ìbí rẹ̀.
[Àpótí/Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 238]
‘ÀDÚRÀ OGUN’ FÚN ÌJỌBA NÁSÌ
Lábẹ́ àkòrí yìí, àpilẹ̀kọ tá a tú sísàlẹ̀ yìí fara hàn nínú ẹ̀dà ìwé ìròyìn The New York Times ti December 7, 1941 tí wọ́n kọ́kọ́ tẹ̀:
“Àwọn Bíṣọ́ọ̀bù Kátólíìkì Ìlú Fulda Gbàdúrà fún Ìbùkún àti Ìṣẹ́gun . . . Ẹgbẹ́ Àwọn Bíṣọ́ọ̀bù Kátólíìkì Ilẹ̀ Jámánì tí wọ́n pé jọ ní Fulda ti dámọ̀ràn pé kí àkànṣe ‘àdúrà ogun’ kan wà tí wọn yóò máa kà ní ìbẹ̀rẹ̀ àti ìparí gbogbo àwọn ìpàdé ìjọsìn. Àdúrà náà jẹ́ ìrawọ́ ẹ̀bẹ̀ sí Ọlọ́run pé kó jẹ́ káwọn ohun ìjà ogun Jámánì máa ṣẹ́gun nìṣó kó sì dáàbò bo ẹ̀mí àti ìlera gbogbo àwọn ọmọ ogun. Àwọn Bíṣọ́ọ̀bù náà tún sọ fún àwọn àlùfáà Kátólíìkì pé kí wọ́n máa rántí àwọn ọmọ ogun Jámánì tí wọ́n wà ‘lórí ilẹ̀, lórí omi àti lójú òfuurufú’ nínú àkànṣe ìwàásù tí wọ́n máa ń ṣe lọ́jọ́ Sunday, ó kéré tán lẹ́ẹ̀kan lóṣù, kí wọ́n sì máa ṣe èyí déédéé.”
Wọ́n yọ àpilẹ̀kọ yìí kúrò nínú àwọn ẹ̀dà ìwé ìròyìn yìí tí wọ́n tún tẹ̀ lẹ́yìn náà. December 7, 1941, ni ọjọ́ tí orílẹ̀-èdè Japan, tó ń bá ìjọba Násì ti Jámánì pawọ́ pọ̀ jagun, kọ lu àwọn ọkọ̀ ojú omi ilẹ̀ Amẹ́ríkà ní àgbègbè Pearl Harbor.
[Àpótí tó wà ní ojú ìwé 244]
“Àwọn Orúkọ Ọ̀rọ̀ Òdì”
Nígbà tí ẹranko ẹhànnà tó ní ìwo méjì náà rọ àwọn orílẹ̀-èdè láti dá Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè sílẹ̀ lẹ́yìn Ogun Àgbáyé Kìíní, ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ni ọ̀pọ̀ àwọn onísìn tí wọ́n jẹ́ àlè rẹ̀ gbìyànjú láti fọwọ́ sí àbá yìí. Nítorí èyí, àjọ tí wọ́n ló máa mú àlàáfíà wá náà di èyí tó “kún fún àwọn orúkọ ọ̀rọ̀ òdì.”
-