ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • sjj orin 54
  • “Èyí Ni Ọ̀nà”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Èyí Ni Ọ̀nà”
  • “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Èyí Ni Ọ̀nà”
    Kọrin sí Jèhófà
  • Ẹ̀bùn Ni Àwọn Olùṣọ́ Àgùntàn
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Báwo Ló Ṣe Máa Ń Rí Lára Rẹ?
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Àwọn Olùṣọ́ Àgùntàn Jẹ́ Ẹ̀bùn
    Kọrin sí Jèhófà
Àwọn Míì
“Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
sjj orin 54

ORIN 54

“Èyí Ni Ọ̀nà”

Bíi Ti Orí Ìwé

(Àìsáyà 30:​20, 21)

  1. 1. Ọ̀nà kan wà tó ti

    Wà lọ́jọ́ tó ti pẹ́.

    Jésù sọ nípa rẹ̀

    Nígbà tó wá sáyé.

    Mo kẹ́kọ̀ọ́, mo sì ti

    Wá mọ ọ̀nà yìí gan-an.

    Ọ̀nà àlàáfíà yìí

    Wà nínú Bíbélì.

    (ÈGBÈ)

    Ọ̀nà ìyè àìnípẹ̀kun nìyí.

    Tẹsẹ̀ mọ́rìn, má ṣe wọ̀tún-wòsì!

    Jèhófà ń sọ pé: ‘Má yà kúrò;

    Má ṣe wẹ̀yìn, ojú ọ̀nà lo wà.’

  2. 2. Ọ̀nà ìfẹ́ lo wà,

    Má ṣe wọ̀tún-wòsì.

    Bíbélì fi hàn pé

    Jèhófà jẹ́ ìfẹ́.

    Ìfẹ́ tó dára, tó

    Jinlẹ̀ ló ní sí wa.

    Ọ̀nà tí à ń sọ yìí

    Kan ìgbé ayé wa.

    (Ègbè)

    Ọ̀nà ìyè àìnípẹ̀kun nìyí.

    Tẹsẹ̀ mọ́rìn, má ṣe wọ̀tún-wòsì!

    Jèhófà ń sọ pé: ‘Má yà kúrò;

    Má ṣe wẹ̀yìn, ojú ọ̀nà lo wà.’

  3. 3. Ọ̀nà ìyè la wà,

    Má ṣe bojú wẹ̀yìn.

    Kò sí ibòmíràn

    Tá a lè lọ, tá a lè rí

    Àlàáfíà àtìfẹ́

    Tí Jáà ṣèlérí rẹ̀.

    Ọ̀nà ìyè nìyí,

    Ọpẹ́ yẹ Jèhófà.

    (Ègbè)

    Ọ̀nà ìyè àìnípẹ̀kun nìyí.

    Tẹsẹ̀ mọ́rìn, má ṣe wọ̀tún-wòsì!

    Jèhófà ń sọ pé: ‘Má yà kúrò;

    Má ṣe wẹ̀yìn, ojú ọ̀nà lo wà.’

(Tún wo Sm. 32:8; 139:24; Òwe 6:23.)

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́