ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Fífún Jèhófà Ní Ohun Tó Dára Jù Lọ
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2004 | April
    • Fífún Jèhófà Ní Ohun Tó Dára Jù Lọ

      1 Nínú Òfin tí Jèhófà fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ó sọ fún wọn pé àwọn ẹran tí wọ́n bá fẹ́ fi rúbọ sí òun gbọ́dọ̀ jẹ́ èyí tí “ara rẹ̀ dá ṣáṣá.” Jèhófà kò ní tẹ́wọ́ gba ẹran èyíkéyìí tó bá ní àbùkù lára. (Léf. 22:18-20; Mál. 1:6-9) Síwájú sí i, nígbà tí wọ́n bá rúbọ, Jèhófà ló ni gbogbo ọ̀rá, èyí tó jẹ́ apá tó dára jù lọ lára ẹran náà. (Léf. 3:14-16) Níwọ̀n bí Jèhófà ti jẹ́ Baba àti Atóbilọ́lá Ọ̀gá fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ó tọ́ kí wọ́n fún un ní ohun tó dára jù lọ.

      2 Bíi ti ayé ọjọ́un, Ọlọ́run ń kíyè sí irú ẹbọ tí à ń rú sí i lónìí. Ó yẹ kí iṣẹ́ ìsìn wa fi hàn pé a ní ọ̀wọ̀ jíjinlẹ̀ fún Jèhófà. Ká sòótọ́, ipò wa yàtọ̀ lẹ́nì kọ̀ọ̀kan. Síbẹ̀, ó yẹ ká ṣàyẹ̀wò ara wa fínnífínní láti rí i dájú pé ohun tó dára jù lọ là ń fún un.—Éfé. 5:10.

      3 Iṣẹ́ Ìsìn Àtọkànwá: Bá a bá fẹ́ fi iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa bọlá fún Jèhófà, kí ọ̀rọ̀ wa sì wọ àwọn tá à ń wàásù fún lọ́kàn, ó gbọ́dọ̀ máa wá látinú ọkàn wa. Ó yẹ kí ọ̀rọ̀ tí à ń sọ nípa Ọlọ́run àtàwọn ohun ribiribi tó fẹ́ láti ṣe máa wá látinú ọkàn tó kún fún ìmọrírì. (Sm. 145:7) Èyí fi hàn pé ó ṣe pàtàkì pé kí ẹnì kọ̀ọ̀kan wa máa ka Bíbélì ká sì máa kẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ déédéé.—Òwe 15:28.

      4 Síwájú sí i, ọ̀nà kan tá a lè gbà fún Jèhófà ní ohun tó dára jù lọ ni pé ká nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn bí Jèhófà ṣe nífẹ̀ẹ́ wọn. (Éfé. 5:1, 2) Ìfẹ́ tá a ní fún àwọn èèyàn yóò sún wa láti gbìyànjú láti lọ sọ ọ̀rọ̀ òtítọ́ tó ń fúnni níyè fún gbogbo àwọn tá a bá lè rí. (Máàkù 6:34) Ó ń sún wa láti fi ìfẹ́ àtọkànwá hàn sí àwọn tá à ń bá sọ̀rọ̀. Ó ń jẹ́ ká máa ronú nípa wọn lẹ́yìn ìbẹ̀wò àkọ́kọ́, ó sì ń sún wa láti tún padà lọ sọ́dọ̀ wọn. Ìfẹ́ yìí tún ń mú ká ṣe gbogbo ohun tá a bá lè ṣe láti ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n lè tẹ̀ síwájú nípa tẹ̀mí.—Ìṣe 20:24; 26:28, 29.

      5 “Ẹbọ Ìyìn”: Ọ̀nà mìíràn tá a lè gbà fún Jèhófà ní ohun tó dára jù lọ ni pé ká jẹ́ aláápọn nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa. Bá a bá ṣètò àwọn ìgbòkègbodò wa dáadáa tá a sì pọkàn pọ̀ sórí iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa, ìsapá wa á lè méso jáde níwọ̀nba àkókò tó kù fún ayé yìí. (1 Tím. 4:10) Bá a bá múra sílẹ̀ dáadáa, a ó lè fi ìdánilójú sọ̀rọ̀, a ó sì lè sọ ọ́ lọ́nà tó máa yéni yékéyéké, èyí sì lè mú kí àwọn èèyàn túbọ̀ tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ wa. (Òwe 16:21) Bí a ṣe ń sọ ìhìn rere fún àwọn èèyàn, ó tọ́ bí a bá pe àwọn ọ̀rọ̀ tó ń ti ọkàn wa wá ní “ẹbọ ìyìn.”—Héb. 13:15.

  • Ẹ̀yin Ọ̀dọ́—Ẹ Máa Ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run!
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2004 | April
    • Ẹ̀yin Ọ̀dọ́—Ẹ Máa Ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run!

      1 Onírúurú ìṣòro ló ń yọjú nígbà ọ̀dọ́, ó sì tún jẹ́ ìgbà tí ẹ ní láti ṣe àwọn ìpinnu pàtàkì. Ọ̀pọ̀ lára ẹ̀yin ọ̀dọ́ Kristẹni ló jẹ́ pé ojoojúmọ́ lẹ̀ ń dojú kọ àwọn nǹkan tó lè mú yín tàpá sáwọn ìlànà Ọlọ́run nípa ìwà rere. Kó tó di pé ẹ ṣe ìpinnu nípa ẹ̀kọ́ ìwé, iṣẹ́ oúnjẹ òòjọ́ àti ìgbéyàwó, ó yẹ kẹ́ ẹ ti kọ́kọ́ ní àwọn góńgó tẹ̀mí tí ẹ óò máa lépa. Ọ̀nà yẹn nìkan lẹ fi lè ṣe àwọn ìpinnu mìíràn tó máa ṣe yín láǹfààní jálẹ̀ ìgbésí ayé yín. Àwọn góńgó tẹ̀mí tó ṣe pàtó á ràn yín lọ́wọ́ láti máa fi ọgbọ́n hùwà, èyí á sì mú kí nǹkan máa lọ déédéé fún yín. Bí ẹ bá ń ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí ẹ sì ń ṣàṣàrò lórí rẹ̀ déédéé, ẹ óò lè máa fi ìmọ̀ràn rẹ̀ tí Ọlọ́run mí sí sílò, àwọn ìsapá dáradára tẹ́ ẹ̀ ń ṣe yóò sì kẹ́sẹ járí.—Jóṣ. 1:8; Sm. 1:2, 3.

      2 Báwo Ló Ṣe Máa Ṣe Yín Láǹfààní? Àwọn nǹkan tó lè súnni hùwà àìtọ́ pọ̀ rẹpẹtẹ nínú ayé Sátánì yìí. (1 Jòh. 2:15, 16) O lè mọ àwọn ọmọ kíláàsì rẹ kan tàbí àwọn ojúgbà rẹ mìíràn tó ti jẹ̀ka àbámọ̀ nítorí pé wọ́n jẹ́ kí ẹ̀mí ṣohun-tẹ́gbẹ́-ń-ṣe nípa lórí wọn. Bó o bá ń tẹ̀ lé ìmọ̀ràn Bíbélì, wàá lè máa hùwà tó dára, wàá sì ní okun tẹ̀mí láti sá fún ẹ̀ṣẹ̀. Síwájú sí i, ìmọ̀ràn Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lè ràn ọ́ lọ́wọ́ láti yàgò fún àwọn ìdẹkùn Sátánì tó fara sin. (2 Kọ́r. 2:11; Héb. 5:14) Rírìn ní ọ̀nà Ọlọ́run yóò jẹ́ kó o ní ojúlówó ayọ̀, ìfọ̀kànbalẹ̀ nìyẹn yóò sì jẹ́ fún ọ ní ìgbésí ayé.—Sm. 119:1, 9, 11.

      3 Àwọn ìlànà inú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí kò lè kùnà láé ju ọgbọ́n ẹ̀dá èèyàn lọ fíìfíì. (Sm. 119:98-100) Bó o bá mọ àwọn ìlànà Bíbélì, tó ò ń ṣàṣàrò lórí àwọn ohun tí Jèhófà ti ṣí payá nínú Ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé òun yóò ṣe, tó o sì ń gba àdúrà àtọkànwá, wàá ní àjọṣe tó dán mọ́rán pẹ̀lú Jèhófà Ọlọ́run, ọlọ́gbọ́n gíga jù lọ tó ni Bíbélì. Ó ṣèlérí pé: “Èmi yóò mú kí o ní ìjìnlẹ̀ òye, èmi yóò sì fún ọ ní ìtọ́ni nípa ọ̀nà tí ìwọ yóò máa tọ̀. Dájúdájú, èmi yóò fún ọ ní ìmọ̀ràn pẹ̀lú ojú mi lára rẹ.”—Sm. 32:8.

      4 Ṣètò Àkókò Láti Máa Kà Á: Ọ̀dọ́bìnrin Kristẹni kan pinnu pé òun á ka Bíbélì látìbẹ̀rẹ̀ dópin, ó sì kà á tán láàárín ọdún kan. Báwo ló ṣe ṣe é láǹfààní? Ó sọ pé: “Mo kọ́ ọ̀pọ̀ nǹkan nípa Jèhófà—àwọn nǹkan tó mú kí n túbọ̀ sún mọ́ ọn, tó sì mú kí n fẹ́ láti bẹ̀rù rẹ̀ jálẹ̀ gbogbo ìgbésí ayé mi.” (Ják. 4:8) Ǹjẹ́ o ti ka Bíbélì látòkèdélẹ̀? Bí o kò bá tíì ṣe bẹ́ẹ̀, o ò ṣe fi ṣe góńgó rẹ pé wàá kà á tán? Kò sí àní-àní pé Jèhófà yóò bù kún àwọn ìsapá rẹ, wàá sì jàǹfààní lọ́pọ̀lọpọ̀.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́