ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Apá Keje: Bí A Ṣe Lè Darí Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Tí Yóò Máa Tẹ̀ Síwájú
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2005 | March
    • Apá Keje: Bí A Ṣe Lè Darí Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Tí Yóò Máa Tẹ̀ Síwájú

      Ta Ló Yẹ Kó Gbàdúrà Níbi Ìkẹ́kọ̀ọ́?

      1. (a) Kí nìdí tó fi dára kéèyàn fàdúrà bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ kó sì tún fàdúrà parí ẹ̀? (b) Ìgbà wo ló yẹ ká bẹ̀rẹ̀ sí gbàdúrà níbi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?

      1 Kí àwọn tá à ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì bàa lè máa tẹ̀ síwájú nípa tẹ̀mí, ó ṣe pàtàkì ká máa tọrọ ìbùkún Jèhófà sórí ìkẹ́kọ̀ọ́ náà. (1 Kọ́r. 3:6) Nítorí náà, ó bójú mu bá a bá ti ń darí ìkẹ́kọ̀ọ́ kan ká máa fàdúrà bẹ̀rẹ̀ rẹ̀ ká sì tún máa fàdúrà parí rẹ̀. Láwọn ìgbà míì, a lè máa gbàdúrà nígbà àkọ́kọ́ ta á bá bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ àwọn èèyàn tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. Àmọ́, àwọn ìkẹ́kọ̀ọ́ míì wà tó jẹ́ pé àwa gan-an la ó fi òye gbé e ká tó lè mọ ìgbà tá á dáa ká bẹ̀rẹ̀ sí gbàdúrà níbẹ̀. Kó o bàa lè ran akẹ́kọ̀ọ́ náà lọ́wọ́ láti lòye ìdí tí gbígbàdúrà fi ṣe pàtàkì, o lè bá a jíròrò Sáàmù 25:4, 5 àti 1 Jòhánù 5:14. O sì tún lè lo Jòhánù 15:16 láti ṣàlàyé fún un bó ti ṣe pàtàkì tó pé kéèyàn máa gbàdúrà sí Jèhófà nípasẹ̀ Jésù Kristi.

      2. Bí ọkùnrin tó jẹ́ akéde tó ti ṣèrìbọmi tàbí akéde tí kò tíì ṣèrìbọmi bá bá arábìnrin kan lọ síbi ìkẹ́kọ̀ọ́, ta ló yẹ kó gbàdúrà?

      2 Ta ló yẹ kó máa gbàdúrà níbi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì? Bí arákùnrin tó ti ṣèrìbọmi bá bá arábìnrin kan lọ síbi ìkẹ́kọ̀ọ́, arákùnrin náà ló máa gbàdúrà. Lẹ́yìn ìyẹn, arábìnrin náà lè darí ìkẹ́kọ̀ọ́, ṣùgbọ́n ó gbọ́dọ̀ fi nǹkan borí. (1 Kọ́r. 11:5, 10) Ẹ̀wẹ̀, bí ọkùnrin tó jẹ́ akéde tí kò tíì ṣèrìbọmi àti arábìnrin kan bá jọ lọ síbi ìkẹ́kọ̀ọ́, arábìnrin yẹn ló máa gbàdúrà. Bí ọ̀ràn bá sì rí bẹ́ẹ̀, ó gbọ́dọ̀ fi nǹkan borí nígbà tó bá ń gbàdúrà àti nígbà tó bá ń darí ìkẹ́kọ̀ọ́.

      3. Kí làwọn nǹkan tó yẹ kí àdúrà wa dá lé lórí níbi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?

      3 Àwọn Nǹkan Tẹ́ Ẹ Lè Gbàdúrà Lé Lórí: Kò yẹ kí àdúrà téèyàn bá gbà níbi ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì gùn jàn-ànràn jan-anran, àmọ́ ó dára kí irú àdúrà bẹ́ẹ̀ dá lórí ohun tó ṣe pàtó. Èèyàn lè tọrọ ìbùkún Ọlọ́run sórí ìkẹ́kọ̀ọ́ náà, kéèyàn sì dúpẹ́ fún òtítọ́ tá a rí kọ́. Á tún dára kéèyàn yin Jèhófà nítorí pé ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìtọ́ni ti ń wá. (Aís. 54:13) A sì tún lè sọ àwọn ọ̀rọ̀ tá á fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ akẹ́kọ̀ọ́ náà tọkàntọkàn, àtèyí tó fi hàn pé a mọrírì ètò tí Jèhófà ń lò. (1 Tẹs. 1:2, 3; 2:7, 8) Bá a bá ń gbàdúrà pé kí Jèhófà bù kún ìsapá akẹ́kọ̀ọ́ náà kó bàa lè fi ohun tó ń kọ́ sílò, ìyẹn á ràn án lọ́wọ́ láti rí bó ti ṣe pàtàkì tó pé kéèyàn jẹ́ “olùṣe ọ̀rọ̀ náà.”—Ják. 1:22.

      4. Àwọn àǹfààní wo ló wà nínú kéèyàn máa fi àdúrà bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ kó sì tún máa fi àdúrà parí rẹ̀?

      4 Àǹfààní tó wà nínú àdúrà pọ̀ gan-an ni. Ó máa ń jẹ́ kéèyàn rí ìbùkún Ọlọ́run gbà. (Lúùkù 11:13) Ó máa ń fi bí kíkẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ti ṣe pàtàkì tó hàn. Bí akẹ́kọ̀ọ́ ṣe ń fetí sí àdúrà wa, òun náà á máa kọ́ bóun ṣe lè máa gbàdúrà. (Lúùkù 6:40) Àti pé bó bá jẹ́ pé ìfẹ́ tá a ní sí Ọlọ́run àti ìmọrírì tá a ní fáwọn ànímọ́ rẹ̀ títayọ ló mú ká gbàdúrà sí i, ìyẹn lè ran akẹ́kọ̀ọ́ yẹn lọ́wọ́ láti sọ ara rẹ̀ di ọ̀rẹ́ Jèhófà.

  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2005 | March
    • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

      Ile Iṣọ Mar. 15

      “Ní orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé làwọn èèyàn ti mọyì ẹ̀kọ́ tí Jésù fi kọ́ni. [Ka ọ̀rọ̀ tó wà ní ojú ìwé 3, ìpínrọ̀ 1.] Ṣùgbọ́n kí lo ti rò ó sí, ṣé ẹ̀kọ́ tí Jésù fi kọ́ni, irú èyí tó wà nínú Ìwé Mímọ́ tá a fẹ́ kà yìí, wúlò fún wa lóde òní? [Ka Mátíù 5:21, 22a. Lẹ́yìn náà, jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé àwọn ẹ̀kọ́ Jésù àti àǹfààní tó wà nínú wọn.”

      Ile Iṣọ Apr. 1

      “Ǹjẹ́ o ti gbọ́ rí táwọn kan ń sọ pé ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì àti Bíbélì ta kora? [Jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé ohun tó fà á tí ọ̀rọ̀ ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì àti ìsìn fi máa ń fa awuyewuye. Ṣùgbọ́n ó tún fẹ̀rí hàn pé ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì tó jinlẹ̀ bá Bíbélì mu.” Fi ojú ìwé 6 àti 7 hàn án. Lẹ́yìn náà, ka Oníwàásù 1:7.

      Jí Apr. 8

      “Ọ̀pọ̀ èèyàn làwọn òkè máa ń wù nítorí bí wọ́n ṣe rẹwà, ṣùgbọ́n ǹjẹ́ o mọ̀ pé wọ́n jẹ́ ọ̀kan lára ohun tó so ẹ̀mí àwa èèyàn àti ẹranko ró? [Jẹ́ kó fèsì.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé ìdí táwọn òkè fi jẹ́ kòṣeémánìí àti ohun tó ń ṣẹlẹ̀ sí wọn lónìí. Ó tún mẹ́nu kan bí Ẹlẹ́dàá ò ṣe ní jẹ́ káwọn èèyàn bà á jẹ́.” Ka Sáàmù 95:4.

      “Báwo lo ṣe rò pé àwọn òbí lè ran àwọn ọmọ wọn lọ́wọ́ kí wọ́n má bàa kó sí ìṣòro ìgbà ọ̀dọ́ tó sábà, máa ń nira? [Jẹ́ kó fèsì. Lẹ́yìn náà ka Aísáyà 48:17, 18.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé bí fífi àwọn ìtọ́ni Bíbélì sílò ṣe lè ran àwọn òbí lọ́wọ́ láti máa bá àwọn ọmọ sọ̀rọ̀ tó jíire àti bí wọ́n ṣe lè máa tọ́ wọn sọ́nà kí wọ́n má bàa ṣe ohun tí kò tọ́.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́