ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ọjọ́ Jèhófà Ti Sún Mọ́lé
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2005 | May
    • Ọjọ́ Jèhófà Ti Sún Mọ́lé

      1 Lójú méjèèjì làwa Kristẹni ń retí pé kí ọjọ́ Jèhófà dé, ìyẹn àkókò tó máa pa ètò nǹkan ìsinsìnyí run tó sì máa fi ayé tuntun òdodo rọ́pò rẹ̀. (2 Pét. 3:12, 13) Níwọ̀n bá ò ti mọ ọjọ́ tó máa jẹ́ gan-an, a ní láti máa bá a nìṣó ní ṣíṣọ́nà ká sì ran àwọn ẹlòmíràn lọ́wọ́ láti máa ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú. (Ìsík. 33:7-9; Mát. 24:42-44) Bá a bá ń ṣàṣàrò lórí Ọ̀rọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ Ọlọ́run, ó máa mú kó túbọ̀ dá wa lójú pé “ọjọ́ ńlá Jèhófà [ti] sún mọ́lé.”—Sef. 1:14.

      2 Bí Àwọn Agbára Ayé Ṣe Ń Rọ́pò Ara Wọn: Bó ṣe wà lákọọ́lẹ̀ nínú Ìṣípayá 17:9-11, àpọ́sítélì Jòhánù dárúkọ “ọba méje” tó ń ṣojú fún agbára ayé méje. Jòhánù tún tọ́ka sí “ọba kẹjọ,” èyí tí Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè ń ṣojú fún. Ṣé ká tún máa retí agbára ayé mìíràn ni? Rárá o, ohun tí àsọtẹ́lẹ̀ yẹn sọ ni pé ṣe ni ọba kẹjọ “kọjá lọ sínú ìparun,” lẹ́yìn rẹ̀, kò sọ̀rọ̀ nípa ọba èyíkéyìí mọ́ tó jẹ lórí ilẹ̀ ayé. Ǹjẹ́ àsọtẹ́lẹ̀ yìí ò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti rí i pé ọjọ́ ti lọ jìnnà?

      3 Dáníẹ́lì 2:31-45, ràn wá lọ́wọ́ láti lóye dídé ọjọ́ Jèhófà. Nínú àsọtẹ́lẹ̀ yẹn, ṣe ni ère gàgàrà tí Nebukadinésárì rí nínú àlá rẹ̀ ṣàpẹẹrẹ bí àwọn agbára ayé yóò ṣe máa rọ́pò ara wọn. Gbogbo àwọn agbára ayé yìí ló ti yọjú tán. Èwo lára àwọn agbára ayé ló ń ṣàkóso lónìí? Àkókò tí ẹsẹ̀ ère náà dúró fún là ń gbé yìí. Àsọtẹ́lẹ̀ náà sọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ tẹ̀lé e kedere. Ìjọba èèyàn máa pa run títí láé láti lè ṣí ọ̀nà sílẹ̀ fún ìjọba kan “èyí tí a kì yóò run láé.” Ṣé o ti wá rí i bí èyí ṣe fi hàn pé ọjọ́ Jèhófà ti sún mọ́lé?

      4 Ẹ̀rí Síwájú Sí I: À ń fojú ara wa rí àwọn ẹ̀rí síwájú sí i pé ọjọ́ Jèhófà ti sún mọ́lé. À ń rí bí ọ̀rọ̀ tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ tẹ́lẹ̀ nípa ìwà táwọn èèyàn á bẹ̀rẹ̀ sí hù “ní àwọn ọjọ́ ìkẹyìn” yìí ṣe ń nímùúṣẹ. (2 Tím. 3:1-5) Àti pé à ń lọ́wọ́ sí ìjẹ́rìí kárí ayé tó gbọ́dọ̀ di ṣíṣe kí òpin tó ó dé. (Mát. 24:14) Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí ọ̀nà tá à ń gba ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa máa fi hàn pé ó jẹ́ kánjúkánjú bí áńgẹ́lì yẹn ṣe polongo pé: “Ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run, kí ẹ sì fi ògo fún un, nítorí wákàtí ìdájọ́ láti ọwọ́ rẹ̀ ti dé.”—Ìṣí. 14:6, 7.

  • Apá Kẹsàn-án: Bí A Ṣe Lè Darí Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Tí Yóò Máa Tẹ̀ Síwájú
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2005 | May
    • Apá Kẹsàn-án: Bí A Ṣe Lè Darí Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Tí Yóò Máa Tẹ̀ Síwájú

      Bó O Ṣe Lè Kọ́ Àwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Láti Jẹ́rìí Láìjẹ́ bí Àṣà

      1 Nígbà tí Áńdérù àti Fílípì ti rí àrídájú pé Jésù ni Mèsáyà náà tó ń bọ̀, wọn ò lè bò ó mọ́ra ńṣe ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí sọ fáwọn ẹlòmíràn nípa ìròyìn ayọ̀ náà. (Jòh. 1:40-45) Bákan náà lónìí, bí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì bá ní ìgbàgbọ́ nínú ohun tí wọ́n ń kọ́, àwọn náà á máa fẹ́ láti sọ fáwọn ẹlòmíràn. (2 Kọ́r. 4:13) Báwo wá la ṣe lè fún wọn ní ìṣírí pé kí wọ́n máa wàásù láìjẹ́ bí àṣà, báwo la sì ṣe lè kọ́ wọn lọ́nà tí wọ́n á fi lè ṣe é dáadáa?

      2 O kàn lè bi akẹ́kọ̀ọ́ náà bóyá ó ti ń sọ nípa ẹ̀kọ́ tó ti kọ́ látinú Bíbélì fáwọn ẹlòmíràn. Ó ṣeé ṣe kó láwọn ọ̀rẹ́ tàbí àwọn míì nínú ìdílé rẹ̀ tó lè pè wá síbi ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀. Tún bi í bóyá ẹnì kan tó nífẹ̀ẹ́ sí ìhìn rere wà lára àwọn tí wọ́n jọ ń ṣíṣẹ níbi kan náà, lára àwọn tí wọ́n jọ wà nílé ìwé, tàbí lára àwọn ojúlùmọ̀ rẹ̀ mìíràn. Tó bá ń pe àwọn ẹlòmíràn síbi ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ tó sì ń sọ nípa ìhìn rere fáwọn tó nífẹ̀ẹ́ sí i, ó máa lè tipa bẹ́ẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí wàásù. Ràn án lọ́wọ́ láti lóye bó ṣe yẹ kó máa lo ìfòyemọ̀ kó sì máa fohùn pẹ̀lẹ́ bá àwọn ẹlòmíràn sọ̀rọ̀ tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ nípa Jèhófà Ọlọ́run àtàwọn ohun tó fẹ́ gbé ṣe.—Kól. 4:6; 2 Tím. 2:24, 25.

      3 Kí Wọ́n Máa Sọ̀rọ̀ Nípa Ìgbàgbọ́ Wọn: Ó ṣe pàtàkì pé ká kọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì wa bó ṣe yẹ kí wọ́n máa fi Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kọ́ àwọn ẹlòmíràn. Bẹ́ ẹ bá kẹ́kọ̀ọ́ dórí àwọn kókó kan, bi akẹ́kọ̀ọ́ náà pé: “Báwo lo ṣe máa fi Bíbélì ṣàlàyé òtítọ́ yìí fáwọn ará ilé rẹ?” tàbí “Ẹsẹ Bíbélì wo ló máa fi mú kí èyí dá àwọn ọ̀rẹ́ rẹ lójú?” Kíyè sí bó bá ṣe dáhùn, kó o sì wá fi hàn án bó ṣe lè máa fi Ìwé Mímọ́ ti ẹ̀kọ́ tó bá ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́yìn. (2 Tím. 2:15) Bó o ti ń ṣe èyí, ńṣe lò ń kọ́ akẹ́kọ̀ọ́ náà bí yóò ṣe máa wàásù láìjẹ́ bí àṣà, àti bí yóò ṣe máa bá ìjọ jáde nínú iṣẹ́ ìwàásù nígbà tó bá tóótun.

      4 Ohun tó bọ́gbọ́n mu ni pé ká kọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì wa bí wọ́n ṣe lè kojú inúnibíni. (Mát. 10:36; Lúùkù 8:13; 2 Tím. 3:12) Bí àwọn kan bá béèrè ìbéèrè tàbí tí wọ́n sọ nǹkan kan nípa àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà, ìyẹn lè ṣí ọ̀nà sílẹ̀ fáwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì láti wàásù. Ìwé pẹlẹbẹ náà Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà—Ta Ni Wọ́n? Kí Ni Wọ́n Gbà Gbọ́? lè mú kí wọ́n “wà ní ìmúratán . . . láti ṣe ìgbèjà.” (1 Pét. 3:15) Nínú ìwé yìí làwọn ẹni tuntun ti lè rí ìsọfúnni tó péye tí wọ́n lè fi ran àwọn ọ̀rẹ́ àtàwọn mọ̀lẹ́bí wọn lọ́wọ́ bí wọ́n bá fẹ́ mọ ìdí tá a fi gba àwọn ẹ̀kọ́ Bíbélì gbọ́ tí wọ́n sì fẹ́ mọ̀ nípa àwọn ìgbòkègbodò Kristẹni wa.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́