ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 4/07 ojú ìwé 1
  • “Sọ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Láìbẹ̀rù”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Sọ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Láìbẹ̀rù”
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Jésù Máa Fìgboyà Wàásù
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2009
  • Ẹ Máa Sọ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Nìṣó Láìṣojo
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Polongo Ìhìn Rere Láìṣojo
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1996
  • Ǹjẹ́ O Ń Wàásù Láìṣojo?
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
km 4/07 ojú ìwé 1

“Sọ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Láìbẹ̀rù”

1 Bí wọ́n bá fún ẹ láǹfààní nílé ẹ̀kọ́ tàbí níbi iṣẹ́ pé kó o sọ̀rọ̀ nípa ohun tó o gbà gbọ́, ṣé o máa ń lọ́ tìkọ̀ nígbà míì? Ṣó máa ń ṣòro fún ẹ láti wàásù láìjẹ́ bí àṣà fáwọn mọ̀lẹ́bí tàbí àwọn aládùúgbò rẹ tàbí fáwọn tó ò tiẹ̀ mọ̀ rí? Kí ló lè ran gbogbo wa lọ́wọ́ láti máa lo àwọn àǹfààní tá a bá ní láti “sọ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run láìbẹ̀rù” nígbàkigbà tí àyè ẹ̀ bá yọ?—Fílí. 1:14.

2 Má Ṣe Lọ́ Tìkọ̀: Bí wọ́n bá fẹ̀sùn èké kan ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ tàbí mọ̀lẹ́bí rẹ kan, ṣé wàá lọ́ra láti lọ gbà á sílẹ̀? Láti ọgọ́rọ̀ọ̀rún ọdún wá ni wọ́n ti purọ́ tó burú jáì mọ́ Jèhófà, ẹni tó jẹ́ Ọ̀rẹ́ wa tímọ́tímọ́. A sì ní àǹfààní tá a fi lè sọ ohun tá a mọ̀ nípa Ọlọ́run wa gíga! (Aís. 43:10-12) Bí ìfẹ́ Jèhófà bá jinlẹ̀ lọ́kàn wa, a ò ní jẹ́ káwọn tó ń wò wá kó wa láyà jẹ tàbí kí wọ́n mú wa dẹni tó ń bẹ̀rù àtisọ̀rọ̀, dípò ìyẹn, ńṣe ló máa mú ká lè sọ ohun tá a gbà gbọ́, a ò sì ní máa lọ́ tìkọ̀ láti fi ìgboyà wàásù òtítọ́.—Ìṣe 4:26, 29, 31.

3 Rántí pé ìhìn rere la fẹ́ wàásù. Ayọ̀ tí kò lópin ló sì máa jẹ́ tàwọn tó bá tẹ́tí sí i. Ó máa rọrùn fún wa láti máa wàásù láìṣojo bá a bá ń ronú nípa bí iṣẹ́ ìwàásù ṣe ṣe pàtàkì tó dípò ká máa ronú nípa irú ẹni tá a jẹ́ tàbí nípa ohun táwọn alátakò ń rò tàbí sọ nípa wa.

4 Àpẹẹrẹ Àwọn Ẹlòmíì: Àpẹẹrẹ àwọn olùṣòtítọ́ míì tí wọ́n sọ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run láìbẹ̀rù lè fún wa lágbára láti ṣe bíi tiwọn. Bí àpẹẹrẹ, Énọ́kù fìgboyà wàásù pé ìdájọ́ Jèhófà ń bọ̀ wá sórí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀. (Júdà 14, 15) Nóà fi ìṣòtítọ́ wàásù fáwọn èèyàn tí wọn ò fẹ́ gbọ́rọ̀ rẹ̀. (Mát. 24:37-39) Àwọn Kristẹni ọ̀rúndún kìíní, tí wọn ‘ò mọ̀wé tí wọ́n sì jẹ́ gbáàtúù’ ń bá a nìṣó láti máa wàásù lójú àtakò tó gbóná janjan. (Ìṣe 4:13, 18-20) Lóòrèkóòrè làwọn ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ àti Jí! máa ń gbé ìtàn ìgbésí ayé àwọn Kristẹni òde òní tí wọ́n ti fi hàn pé àwọn ní ìgbàgbọ́ nínú Jèhófà jáde nípa bí ìbẹ̀rù èèyàn kì í ṣeé pa wọ́n lẹ́nu mọ́, èyí tó mú kí wọ́n dẹni tó ń fìtara wàásù.

5 Ẹ̀rù ò ní máa bà wá bá a bá ń ronú lórí báwọn olùṣòtítọ́ ìránṣẹ́ Jèhófà ayé ìgbà yẹn ṣe gbé ìgbé ayé wọn láìfi onírúurú ipò tó le koko tí wọ́n bá pàdé pè. (1 Ọba 19:2, 3; Máàkù 14:66-71) Wọ́n “máyàle nípasẹ̀ Ọlọ́run wa,” wọ́n sì sọ̀rọ̀ láìbẹ̀rù. Àwa náà lè ṣe bẹ́ẹ̀!—1 Tẹs. 2:2.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́