ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jèhófà Dáhùn Àdúrà Àtọkànwá Tí Ìránṣẹ́ Rẹ̀ Kan Gbà
    Ilé Ìṣọ́—2008 | October 15
    • 17. Àǹfààní wo ni kò ní pẹ́ dópin, àdúrà wo la sì máa rántí láìpẹ́?

      17 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àtakò táwọn ọ̀tá ń ṣe sí wa kò tíì parí, síbẹ̀ náà, à ń bá a nìṣó láti máa wàásù, àní fáwọn ọ̀tá pàápàá. (Mát. 24:14, 21) Àmọ́ ṣá o, àǹfààní táwọn ọ̀tá náà ní láti ronú pìwà dà kí wọ́n lè rí ìgbàlà, kò ní pẹ́ dópin, nítorí pé sísọ orúkọ Jèhófà di mímọ́ ṣe pàtàkì gan-an ju ìgbàlà àwọn èèyàn. (Ka Ìsíkíẹ́lì 38:23.) Nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé bá kóra wọn jọ láti pa àwọn èèyàn Ọlọ́run rẹ́, gẹ́gẹ́ bí Bíbélì ti sọ, a óò rántí àdúrà tí Ásáfù gbà pé: “Kí ojú tì wọ́n, kí a sì yọ wọ́n lẹ́nu ní ìgbà gbogbo, kí wọ́n sì tẹ́, kí wọ́n sì ṣègbé.”—Sm. 83:17.

      18, 19. (a) Kí ló máa gbẹ̀yìn àwọn olóríkunkun tó ń ta ko Jèhófà, ọba aláṣẹ ayé àtọ̀run? (b) Níwọ̀n bí a ó ti dá Jèhófà láre gẹ́gẹ́ bí Ọba Aláṣẹ ayé àtọ̀run láìpẹ́, kí ló yẹ kí o máa ṣe?

      18 Ẹ̀tẹ́ ló máa gbẹ̀yìn àwọn olóríkunkun tó ń ta ko Jèhófà, Ọba Aláṣẹ ayé àtọ̀run. Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ ká mọ̀ pé “ìparun àìnípẹ̀kun” ló máa jẹ́ ti àwọn tí “kò ṣègbọràn sí ìhìn rere,” tí wọ́n sì wá tipa bẹ́ẹ̀ pa rún ní ogun Amágẹ́dọ́nì. (2 Tẹs. 1:7-9) Bó ṣe jẹ́ pé Jèhófà máa pa àwọn wọ̀nyí run, tó sì máa gba àwọn tó ń fòtítọ́ sìn ín là, jẹ́ ẹ̀rí tó lágbára pé Jèhófà ni Ọlọrun tòótọ́ kan ṣoṣo náà. Nínú ayé tuntun, títí láé la ó máa rántí ìṣẹ́gun ńlá yẹn! Àwọn tó bá pa dà wá sí ìyè nígbà “àjíǹde àwọn olódodo àti àwọn aláìṣòdodo” yóò gbọ́ nípa iṣẹ́ àrà Jèhófà. (Ìṣe 24:15) Nínú ayé tuntun, wọn yóò rí ẹ̀rí tó lágbára pé ìwà ọgbọ́n ló jẹ́ láti wà lábẹ́ Jèhófà, Ọba Aláṣẹ ayé àtọ̀run. Àwọn tó sì jẹ́ ọlọ́kàn tútù nínú wọn yóò tètè gbà pé Jèhófà ni Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo náà.

  • “Orúkọ Ọlọ́run Tó Tóbi Tó sì Jẹ́ Mímọ́ Jù Lọ Rèé Lóòótọ́”
    Ilé Ìṣọ́—2008 | October 15
    • “Orúkọ Ọlọ́run Tó Tóbi Tó sì Jẹ́ Mímọ́ Jù Lọ Rèé Lóòótọ́”

      Ọ̀gbẹ́ni Nicholas ará Cusa tó jẹ́ ọmọ ilẹ̀ Jámánì ló sọ ọ̀rọ̀ tó wà lókè yìí nínú ìwàásù kan tó ṣe lọ́dún 1430.a Ọ̀gbẹ́ni yìí fẹ́ láti mọ̀ nípa oríṣiríṣi ẹ̀ka ẹ̀kọ́. Bí àpẹẹrẹ, ó kẹ́kọ̀ọ́ nípa èdè Gíríìkì àti Hébérù, ó tún kẹ́kọ̀ọ́ nípa ìmọ̀ ọgbọ́n orí, ẹ̀kọ́ ìsìn, ìṣirò àti ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa sánmà. Nígbà tó wà lọ́mọ ọdún méjìlélógún, ó di ọ̀mọ̀wé nínú òfin Kátólíìkì. Lọ́dún 1448 ó di kádínà ṣọ́ọ̀ṣì Kátólíìkì.

      Ní nǹkan bí àádọ́ta-dín-lẹ́gbẹ̀ta [550] ọdún sẹ́yìn, ọ̀gbẹ́ni Nicholas kọ́ ilé ìtọ́jú àwọn arúgbó kan sí abúlé Kues, tá a wá mọ̀ sí ìlú Bernkastel-Kues báyìí. Ìlú yìí wà ní nǹkan bí àádóje [130] kìlómítà lápá gúúsù ìlú Bonn, lórílẹ̀-èdè Jámánì. Ibi ìkówèésí kan tí wọ́n sọ ní orúkọ ọ̀gbẹ́ni Cusa ti wà nílé ìtọ́jú àwọn arúgbó yẹn báyìí. Àwọn ìwé àfọwọ́kọ tí wọ́n kó síbẹ̀ ju ọ̀ọ́dúnrún ó lé mẹ́wàá [310] lọ. Ọ̀kan lára àwọn ìwé náà ni ìwé àfọwọ́kọ alábala tí wọ́n ń pè ní Cusanus 220. Nínú ìwé yìí, èèyàn lè rí ìwàásù tí Nicholas ará Cusa ṣe lọ́dún 1430. Nínú ìwàásù yẹn tí àkọlé rẹ̀ sọ pé, In principio erat verbum (èyí tó túmọ̀ sí: Ní ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ni Ọ̀rọ̀ náà wà) Ọ̀gbẹ́ni Nicholas lo ẹyọ ọ̀rọ̀ náà, Iehoua látinú èdè Látìn fún orúkọ Jèhófà.b Lójú ìwé 56 nínú ìwé náà, ọ̀rọ̀ kan wà níbẹ̀ tó sọ nípa orúkọ Ọlọ́run, ó kà pé: “Ọlọ́run ló fún ara rẹ̀ ní orúkọ yìí. Òun ni lẹ́tà Hébérù mẹ́rin tó dúró fún orúkọ Ọlọ́run. . . . Orúkọ Ọlọ́run tó tóbi tó sì jẹ́ mímọ́ jù lọ rèé lóòótọ́.” Ọ̀rọ̀ Nicholas yìí tún fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé lóòótọ́ ni orúkọ Ọlọ́run wà nínú Ìwé Mímọ́ lédè Hébérù ti ìpilẹ̀ṣẹ̀.—Ẹ́kís. 6:3.

      Látìbẹ̀rẹ̀ ọ̀rúndún kẹẹ̀ẹ́dógún ni wọ́n ti kọ ìwé àfọwọ́kọ alábala yìí, ó sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìwé tí ọjọ́ rẹ̀ tíì pẹ́ jù lọ tí wọ́n ti túmọ̀ orúkọ Jèhófà látinú lẹ́tà Hébérù mẹ́rin náà sí “Iehoua.” Àkọsílẹ̀ yìí jẹ́ ẹ̀rí síwájú sí i pé kíkọ orúkọ Ọlọ́run lọ́nà tó fara jọ “Jèhófà” jẹ́ ọ̀nà tí wọ́n sábà máa ń gbà ṣe àdàkọ orúkọ Ọlọ́run láti ọ̀pọ̀ ọ̀rúndún wa.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́