ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • be ẹ̀kọ́ 18 ojú ìwé 143-ojú ìwé 144 ìpínrọ̀ 4
  • Lílo Bíbélì Láti Fi Dáhùn Ìbéèrè

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Lílo Bíbélì Láti Fi Dáhùn Ìbéèrè
  • Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Lílo Ìwé Mímọ́ Bí Ó Ti Yẹ
    Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
  • Fi Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Ran Ara Rẹ Àti Àwọn Míì Lọ́wọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • “Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run . . . Ń Sa Agbára”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2017
  • Ẹ̀rí tó Yè Kooro
    Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
Àwọn Míì
Jàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
be ẹ̀kọ́ 18 ojú ìwé 143-ojú ìwé 144 ìpínrọ̀ 4

Ẹ̀KỌ́ 18

Lílo Bíbélì Láti Fi Dáhùn Ìbéèrè

Kí ló yẹ kí o ṣe?

Ó yẹ kí o fi Bíbélì tìkára rẹ̀ dáhùn àwọn ìbéèrè, dípò gbígbé ìdáhùn ka ọgbọ́n orí.

Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì?

Iṣẹ́ tá a gbé lé wa lọ́wọ́ ni láti máa “wàásù ọ̀rọ̀ náà.” Jésù fi àpẹẹrẹ lélẹ̀ nígbà tó sọ pé: “Èmi kò [sọ̀rọ̀] láti inú àpilẹ̀ṣe ti ara mi.”—2 Tím. 4:2; Jòh. 14:10.

NÍGBÀ táwọn èèyàn bá bi wá nípa ohun tá a gbà gbọ́, nípa bá a ṣe ń gbé ìgbésí ayé wa, tàbí tí wọ́n ń béèrè èrò wa nípa àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ lọ́ọ́lọ́ọ́, tàbí nípa ìrètí wa fún ọjọ́ ọ̀la, a máa ń ṣakitiyan láti fi Bíbélì dá wọn lóhùn. Èé ṣe? Nítorí pé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni. Inú Bíbélì la ti mú àwọn ohun tá a gbà gbọ́ jáde wá. Bíbélì la gbé ìgbésí ayé wa kà. Ó ń là wá lóye nípa àwọn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ láyé. Àwọn ìlérí onímìísí tó wà nínú Bíbélì la gbé ìrètí wa fún ọjọ́ ọ̀la kà.—2 Tím. 3:16, 17.

A mọ̀ dájú pé ojúṣe wa ni láti máa ṣe ohun tó bá orúkọ wa mu. Ẹlẹ́rìí Jèhófà ni wá. (Aísá. 43:12) Ìyẹn ló fi jẹ́ pé a kì í lo ọgbọ́n orí ènìyàn nígbà tá a bá ń dáhùn ìbéèrè, bí kò ṣe ohun tí Jèhófà wí nínú Ọ̀rọ̀ rẹ̀ onímìísí. Òótọ́ ni pé kálukú wa ló ní ojú tá a fi ń wo àwọn ọ̀ràn, ṣùgbọ́n a máa ń jẹ́ kí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run darí èrò wa nítorí pé ó dá wa lójú hán-ún pé òun gan-an ló jẹ́ òtítọ́. Àmọ́ o, Bíbélì kì í ṣe òfin dandan gbọ̀n lórí ọ̀ràn èyí-ó-wù-mí-ò-wù-ọ́. Dípò ṣíṣe òfin má-ṣu-má-tọ̀ fáwọn ẹlòmíràn lórí àwọn ọ̀ràn èyí-ó-wù-mí-ò-wù-ọ́, ìfẹ́ wa ni láti kọ́ wọn ní àwọn ìlànà tí Ìwé Mímọ́ gbé kalẹ̀, kí àwọn tó ń gbọ́ wa lè ní òmìnira kan náà bíi tiwa, ìyẹn ni, láti yan èyí tó wù wọ́n. Gẹ́gẹ́ bí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù, ìfẹ́ wa ni “láti gbé ìgbọràn ga síwájú sí i nípasẹ̀ ìgbàgbọ́.”—Róòmù 16:26.

A pe Jésù Kristi ní “ẹlẹ́rìí aṣeégbíyèlé àti olóòótọ́” nínú ìwé Ìṣípayá 3:14. Báwo ló ṣe dáhùn àwọn ìbéèrè, tó sì yanjú àwọn ọ̀ràn tí wọ́n gbé kò ó lójú? Nígbà mìíràn, ó máa ń lo àwọn àpèjúwe tó máa ń mú káwọn èèyàn ronú jinlẹ̀. Ní àwọn ìgbà míì sì rèé, ó máa ń bi oníbèéèrè náà nípa bí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan ṣe yé onítọ̀hún sí. Àmọ́ lọ́pọ̀ ìgbà, ńṣe ló máa ń fa ọ̀rọ̀ Ìwé Mímọ́ yọ, tàbí kí ó tún wọn sọ lọ́rọ̀ mìíràn, tàbí kó sọ wọ́n mọ́ ọ̀rọ̀. (Mát. 4:3-10; 12:1-8; Lúùkù 10:25-28; 17:32) Ní ọ̀rúndún kìíní, wọ́n sábà máa ń kó àwọn àkájọ Ìwé Mímọ́ sínú sínágọ́gù. Kò sí ẹ̀rí tó fi hàn pé Jésù ní àwọn àkájọ Ìwé Mímọ́ tirẹ̀, ṣùgbọ́n ńṣe ni Ìwé Mímọ́ ń hó lágbárí rẹ̀, kò sì lè ṣe kí ó máà tọ́ka sí i nígbà tó bá ń kọ́ àwọn èèyàn. (Lúùkù 24:27, 44-47) Ìyẹn ló fi lè sọ tòótọ́tòótọ́ pé ohun tí òun fi ń kọ́ni kì í ṣe àpilẹ̀ṣe tara òun. Ohun tó gbọ́ látọ̀dọ̀ Baba rẹ̀ ló ń sọ.—Jòh. 8:26.

Àpẹẹrẹ Jésù la fẹ́ tẹ̀ lé. A ò tíì fetí ara wa gbóhùn Ọlọ́run rí gẹ́gẹ́ bí Jésù ti gbọ́ ọ. Ṣùgbọ́n Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni Bíbélì. Bó bá jẹ́ inú rẹ̀ làwọn ìdáhùn wa ti ń wá, kò ní sí pé à ń pe àfiyèsí sí ara wa. A ó fi hàn pé dípò sísọ èrò ẹ̀dá aláìpé, a pinnu látọkànwá láti jẹ́ kí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ sọ ohun tó jẹ́ òtítọ́.—Jòh. 7:18; Róòmù 3:4.

Àmọ́ ṣá o, lílo Bíbélì ní ìlò wọ̀ǹdùrùkù kọ́ ni ohun tí à ń lépa, bí kò ṣe lílò ó lọ́nà tí yóò ṣàǹfààní jù lọ fẹ́ni tó ń gbọ́ wa. A fẹ́ kó gbọ́ wa láìsí ẹ̀tanú. Bí ìṣesí onítọ̀hún bá ṣe rí ni yóò pinnu bóyá kó o bẹ̀rẹ̀ àlàyé ọ̀rọ̀ Bíbélì nípa sísọ pé: “Ǹjẹ́ o ò gbà pé ohun tó jà jù ni mímọ ohun tí Ọlọ́run wí?” Tàbí kẹ̀, o lè sọ pé: “Ǹjẹ́ o mọ̀ pé Bíbélì ṣàlàyé ìbéèrè yẹn?” Bó bá jẹ́ ẹni tí kò ka Bíbélì kún lò ń bá sọ̀rọ̀, ó lè di dandan láti bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ lọ́nà mìíràn. O lè sọ pé: “Jẹ́ kí n fi àsọtẹ́lẹ̀ ìgbà láéláé yìí hàn ọ́.” Tàbí kẹ̀, o lè sọ pé: “Ìwé tí a ti pín kiri jù lọ nínú ìtàn ẹ̀dá ènìyàn sọ pé . . . ”

Nínú àwọn ọ̀ràn kan, o kàn lè sọ ohun tó wà nínú ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan lọ́rọ̀ ara rẹ. Àmọ́, níbi tó bá ti ṣeé ṣe, ohun tó ti dára jù lọ ni kó o ṣí Bíbélì gan-an, kó o sì ka ohun tó wí. Fi ẹsẹ Ìwé Mímọ́ náà han onítọ̀hún nínú ẹ̀dà Bíbélì tirẹ̀, tí ìyẹn bá ṣeé ṣe. Bí àwọn èèyàn bá lo Bíbélì fúnra wọn lọ́nà yìí, ó sábà máa ń ní ipa lílágbára lórí wọn.—Héb. 4:12.

Ojúṣe àwọn Kristẹni alàgbà ni láti lo Bíbélì nígbà tí wọ́n bá ń dáhùn ìbéèrè. Ọ̀kan lára ohun tí à ń béèrè kí arákùnrin kan tó lè sìn gẹ́gẹ́ bí alàgbà ni pé ó ní láti jẹ́ ẹni “tí ń di ọ̀rọ̀ ṣíṣeégbíyèlé mú ṣinṣin ní ti ọnà ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀.” (Títù 1:9) Ẹnì kan nínú ìjọ lè lọ lo ìmọ̀ràn tí alàgbà kan fún un láti fi ṣe ìpinnu pàtàkì kan nínú ìgbésí ayé rẹ̀. Ẹ ò rí i pé ó ṣe pàtàkì gan-an pé kí ìmọ̀ràn ọ̀hún jẹ́ èyí tá a gbé karí Ìwé Mímọ́! Àpẹẹrẹ tí alàgbà bá fi lélẹ̀ nínú ṣíṣe èyí lè nípa lórí ọ̀nà tí ọ̀pọ̀ àwọn mìíràn gbà ń kọ́ni.

BÍ O ṢE LÈ TÚBỌ̀ JÁ FÁFÁ

  • Máa ka Bíbélì lójoojúmọ́. Ṣètò ìdákẹ́kọ̀ọ́ tó múná dóko.

  • Jẹ́ kó mọ́ ẹ lára láti máa lo ẹsẹ Ìwé Mímọ́ nígbà tó o bá ń dáhùn nínú ìpàdé ìjọ.

  • Nígbà táwọn ìbéèrè tàbí àwọn ipò kan bá yọjú, kó o tó fèsì tàbí kó o tó ṣe ìpinnu, rí i dájú pé o kọ́kọ́ bi ara rẹ pé, ‘Kí ni Bíbélì sọ?’

  • Tó ò bá mọ ohun tí Bíbélì sọ lórí ọ̀ràn kan, má ṣe méfò tàbí kí o sọ èrò ara rẹ. Gbà láti lọ ṣe ìwádìí.

ÌDÁNRANWÒ: Kọ ìbéèrè kan tàbí méjì tí wọ́n bi ọ́ rí (1) ní òde ẹ̀rí, (2) nípa ìṣẹ̀lẹ̀ lọ́ọ́lọ́ọ́ kan tó jáde nínú ìròyìn àti (3) nípa kíkópa nínú ìgbòkègbodò kan tó gbòde. Nínú ọ̀ràn kọ̀ọ̀kan, ó kéré tán yan ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan tó ṣeé fi fèsì.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́