ORIN 64
À Ń Fayọ̀ Ṣe Iṣẹ́ Ìkórè Náà
Bíi Ti Orí Ìwé
1. Àǹfààní àláìlẹ́gbẹ́ ló jẹ́
Pé ìgbà ‘kórè la wà yìí.
Iṣẹ́ bẹ̀rẹ̀, ká bọ́ sí pápá,
Ká sì sa gbogbo ipá wa.
Torí pé Kristi wà pẹ̀lú wa,
Tó ń darí iṣẹ́ tá à ń ṣe yìí,
Èyí ń fún wa láyọ̀ lójoojúmọ́,
Ọlá ńlá ló sì jẹ́ fún wa.
2. Torí pé a nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run
Àtàwọn aládùúgbò wa,
Ó ń mú ká tẹra mọ́ ìwàásù,
Torí òpin ti sún mọ́lé.
À ń láyọ̀ bí a ṣe ńṣiṣẹ́ yìí;
Jèhófà ló ń fún wa láyọ̀.
A ó fìgbàgbọ́ fara dà á dé òpin,
A ó sì máa fayọ̀ bá a ṣiṣẹ́.
(Tún wo Mát. 24:13; 1 Kọ́r. 3:9; 2 Tím. 4:2.)