ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g20 No. 3 ojú ìwé 8-9
  • Máa Wo Ìwà Rere Táwọn Èèyàn Ní

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Wo Ìwà Rere Táwọn Èèyàn Ní
  • Jí!—2020
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tó Jẹ́ Ìṣòro
  • Ìlànà Bíbélì
  • Ohun Tó O Lè Ṣe
  • Ìgbà kan Ń Bọ̀ Tí Kò Ní Sí Ẹ̀tanú Mọ́
    Jí!—2004
  • Ṣé O Ní Ìkórìíra?
    Jí!—2020
  • Ìgbà Wo Ni Ayé Yìí Máa Bọ́ Lọ́wọ́ Ẹ̀tanú?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Ohun tó ń fa Ẹ̀tanú àti Àìbánilò-Lọ́gbọọgba
    Jí!—2009
Àwọn Míì
Jí!—2020
g20 No. 3 ojú ìwé 8-9
Collage: 1. Inú bí tọkọtaya kan torí pé obìnrin afọ́jú kan kó sí wọn lẹ́sẹ̀ bí wọ́n ṣe ń kánjú rìn lọ. 2. Nígbà tó yá, ẹnu ya tọkọtaya náà nígbà tí wọ́n rí afọ́jú yẹn tó ń ta gòjé láti dá àwọn èèyàn lára yá.

Máa Wo Ìwà Rere Táwọn Èèyàn Ní

Ohun Tó Jẹ́ Ìṣòro

Ìgbéraga lè mú kéèyàn kórìíra àwọn ẹlòmíì. Ẹni tó ń gbéra ga máa ń ro ara ẹ̀ ju bó ṣe yẹ lọ. Ó máa ń wo ara ẹ̀ pé òun dáa ju àwọn mìí lọ, ó sì gbà pé ẹni tó bá ti yàtọ̀ sóun ò já mọ́ nǹkan kan. Kò sẹ́ni tí kò lè ní ẹ̀mí ìgbéraga. Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ náà, Encyclopædia Britannica sọ pé: “Èyí tó pọ̀ jù nínú àwọn ẹ̀yà ló máa ń ronú pé ìgbé ayé wọn, oúnjẹ, aṣọ, ìwà àti ìṣe, ohun tí wọ́n gbà gbọ́, ohun tí wọ́n kà sí pàtàkì àtàwọn nǹkan míì tó jẹ́ tiwọn dáa ju ti àwọn ẹ̀yà yòókù lọ.” Báwo lá ṣe lè yẹra fún èrò tí kò dáa yìí?

Ìlànà Bíbélì

“Ẹ jẹ́ kí ìrẹ̀lẹ̀ máa mú kí ẹ gbà pé àwọn míì sàn jù yín lọ.”​—FÍLÍPÌ 2:3.

Kí la rí kọ́? Ká bàa lè yẹra fún ìgbéraga, ó pọn dandan ká kọ́ bá a ṣe lè ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀. Ìrẹ̀lẹ̀ máa ń jẹ́ ká mọ̀ pé àwọn ẹlòmíì sàn jù wá lọ láwọn ọ̀nà kan. Kò sí ẹ̀yà kan tó ní gbogbo ìwà tó dáa tán.

Wo àpẹẹrẹ ọkùnrin kan tó ń jẹ́ Stefan. Orílẹ̀-èdè kan tí wọ́n ti ń ṣe ìjọba orí-ò-jorí ló dàgbà sí, àmọ́ ó borí ẹ̀tanú tó ní sáwọn tó wá láti orílẹ̀-èdè ti kì í ṣe ti ìjọba orí-ò-jorí. Ó ní: “Téèyàn bá gbà pé àwọn míì sàn ju òun lọ, ìyẹn lohun pàtàkì táá jẹ́ kó borí ẹ̀tanú àti ìkórìíra. Gbogbo nǹkan kọ́ ni mo mọ̀. Mo lè rí nǹkan kọ́ lọ́dọ̀ gbogbo èèyàn.”

Ohun Tó O Lè Ṣe

Má ṣe ro ara ẹ ju bó ṣe yẹ lọ, kó o sì máa rántí pé ìwọ náà máa ń ṣàṣìṣe. Fi sọ́kàn pé àwọn ẹlòmíì lè ṣe àwọn nǹkan kan lọ́nà tó dáa ju tìẹ lọ. Má sì rò pé àbùkù kan náà ni gbogbo èèyàn tó wá láti ẹ̀yà kan ní.

Dípò kó o máa fojú burúkú wo ẹnì kan tó wá látinú ẹ̀yà kan, bi ara ẹ pé:

Fi sọ́kàn pé àwọn ẹlòmíì lè ṣe àwọn nǹkan kan lọ́nà tó dáa ju tìẹ lọ

  • ‘Ṣé ìwà ẹni náà burú lóòótọ́, àbí ọ̀nà tó ń gbà ṣe nǹkan ló kàn yàtọ̀?’

  • ‘Ṣé èmi náà ò ní àléébù tóun náà lè tọ́ka sí?’

  • ‘Àwọn ọ̀nà wo ni ẹni náà gbà sàn jù mí lọ?’

Tó o bá fi òótọ́ inú dáhùn àwọn ìbéèrè yẹn, wàá borí ìkórìíra tó o ní sí ẹni náà, wàá sì tún rí àwọn nǹkan míì tó máa wù ẹ́ nínú ìwà ẹni náà.

Ohun Tí Ẹnì Kan Sọ: Nelson (Amẹ́ríkà)

“Ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ pé gbogbo àwọn tó wà níbi tí mo dàgbà sí ló wá látinú ẹ̀yà kan náà. Àmọ́ nígbà tí mo di ọmọ ọdún mọ́kàndínlógún (19), mo kó lọ sí ìlú ńlá láti lọ ṣiṣẹ́ nílé iṣẹ́ kan, mo wá ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn tó wá láti oríṣiríṣi ẹ̀yà àti àṣà ìbílẹ̀, mo sì tún ń bá wọn gbé.

“Bí mo ṣe ń mọ àwọn tá a jọ ń ṣiṣẹ́ sí i, tí mo sì ń ní àwọn ọ̀rẹ́, mo wá rí i fúnra mi pé a ò lè fi àwọ̀, èdè àti ibi táwọn èèyàn ti wá mọ bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́ kára tó, bí wọ́n ṣe jólóòótọ́ sí àti bí nǹkan ṣe máa ń rí lára wọn.

“Nígbà tó yá, mo fẹ́ obìnrin kan láti orílẹ̀-èdè míì tí ẹ̀yà rẹ̀ yàtọ̀ tèmi. Inú mi dùn gan-an nígbà tí mo kọ́ oríṣiríṣi oúnjẹ àti orin tí mi ò mọ̀ tẹ́lẹ̀. Mo ti kẹ́kọ̀ọ́ pé gbogbo wa la níbi tá a dáa sí àti ibi tá a kù sí. Ká sòótọ́, ìwà mi ti wá dáa ju ti tẹ́lẹ̀ lọ, torí mo fẹ́ràn àwọn tí ẹ̀yà àti àṣà wọn yàtọ̀ sí tèmi gan-an, mo sì ti kọ́ ọ̀pọ̀ ìwà rere lára wọn.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́