ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w10 7/1 ojú ìwé 30-31
  • Bí O Ṣe Lè Rí Àwọn Ọ̀rẹ́ Tó Jẹ́ Adúróṣinṣin

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Bí O Ṣe Lè Rí Àwọn Ọ̀rẹ́ Tó Jẹ́ Adúróṣinṣin
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Bí Sódómù àti Gòmórà Ṣe Pa Run
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Jésù Fi Iṣẹ́ Ìyanu Mú Àwọn Aláìsàn Lára Dá
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Wọ́n Fi Ẹ̀sùn Èké Kàn Án!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
  • Òye Jésù Ṣe Àwọn Tó Gbọ́rọ̀ Rẹ̀ Ní Kàyéfì
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
w10 7/1 ojú ìwé 30-31

Abala Àwọn Ọ̀dọ́

Bí O Ṣe Lè Rí Àwọn Ọ̀rẹ́ Tó Jẹ́ Adúróṣinṣin

Ohun tó o máa ṣe: Ibi tí kò sí ariwo ni kó o ti ṣe ìdánrawò yìí. Bó o bá ṣe ń ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó wà nísàlẹ̀ yìí, máa fojú inú wò ó bíi pé o wà níbi tọ́rọ̀ náà ti ń ṣẹlẹ̀, jẹ́ kó dà bíi pé ò ń gbọ́ bí àwọn èèyàn náà ṣe ń sọ̀rọ̀. Ronú nípa bí ohun tó ò ń kà yẹn ṣe máa rí lára àwọn èèyàn wọ̀nyẹn. Kó o sì máa fojú inú wò ó bí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lọ́wọ́lọ́wọ́.

Àwọn tá a sọ̀rọ̀ nípa wọn: Jónátánì, Dáfídì àti Sọ́ọ̀lù

Àkópọ̀: Lẹ́yìn tí Dáfídì pa Gòláyátì, Jónátánì di ọ̀rẹ́ kòríkòsùn Dáfídì.

1 KA ÌTÀN NÁÀ DÁADÁA.—KA 1 SÁMÚẸ́LÌ 17:57–18:11; 19:1; 20:1-17, 41, 42.

Ṣàpèjúwe bí o ṣe rò pé Sọ́ọ̀lù ṣe rí. (Ojútùú: Ka 1 Sámúẹ́lì 10:20-23.)

․․․․․

Ó ṣeé ṣe kí Dáfídì ṣì wà lọ́dọ̀ọ́ nígbà tó bá Jónátánì pàdé. Báwo lo ṣe rò pé ó rí nígbà yẹn? (Ojútùú: Ka 1 Sámúẹ́lì 16:12, 13.)

․․․․․

Kí lo kíyè sí nínú ohùn Dáfídì àti Jónátánì nígbà tí wọ́n fẹ́ fi ara wọn sílẹ̀ ní ìparí 1 Sámúẹ́lì orí 20?

․․․․․

2 ṢÈWÁDÌÍ KÓ O SÌ RONÚ JINLẸ̀.

Àkọsílẹ̀ náà sọ pé, “ọkàn Jónátánì pàápàá wá fà mọ́ ọkàn Dáfídì,” tàbí gẹ́gẹ́ bí Bíbélì Contemporary English Version ṣe sọ ọ́, ó ní, “Dáfídì àti Jónátánì di ọ̀rẹ́ kòríkòsùn.” (1 Sámúẹ́lì 18:1) Àwọn ànímọ́ wo ni Dáfídì ní tó ti lè fa Jónátánì mọ́ra? (Ojútùú: Ka 1 Sámúẹ́lì 17:45, 46.)

․․․․․

Jónátánì fi nǹkan bí ọgbọ̀n ọdún ju Dáfídì lọ. Kí lo rò pé ó mú kí wọ́n di “ọ̀rẹ́ kòríkòsùn,” láìka ìyàtọ̀ tó wà láàárín ọjọ́ orí wọn sí?

․․․․․

Irú ìwà wo ni àwọn ọ̀rẹ́ tòótọ́ máa ń hù, gẹ́gẹ́ bí a ti rí i nínú ìtàn alárinrin yìí? (Ojútùú: Ka Òwe 17:17; 18:24.)

․․․․․

Kí nìdí tí ìdúróṣinṣin tí Jónátánì ní sí Dáfídì fi ju èyí tó ní sí bàbá òun fúnra rẹ̀ lọ?

․․․․․

3 MÁA FOHUN TÓ O KỌ́ ṢÈWÀ HÙ. ṢÀKỌSÍLẸ̀ Ẹ̀KỌ́ TÓ O KỌ́ NÍPA . . .

Jíjẹ́ ọ̀rẹ́.

․․․․․

Ìdúróṣinṣin.

․․․․․

Bíbá ẹni tó dàgbà juni lọ ṣọ̀rẹ́.

․․․․․

Kí lo lè ṣe tó o fi lè ní àwọn ọ̀rẹ́ tó dára jù lọ?

․․․․․

4 KÍ LÓ WÚ Ẹ LÓRÍ JÙ LỌ NÍNÚ ÌTÀN YÌÍ, KÍ SÌ NÌDÍ?

․․․․․

KẸ́KỌ̀Ọ́ SÍ I NÍPA BÍBÉLÌ, LÓRÍ ÌKÀNNÌ WA www.watchtower.org ÀTI www.jw.org

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́