KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | O LÈ SÚN MỌ́ ỌLỌ́RUN
Ǹjẹ́ O Máa Ń Bá Ọlọ́run Sọ̀rọ̀?
Ọ̀rẹ́ àtọ̀rẹ́ máa ń bá ara wọn sọ̀rọ̀ déédéé, ì báà jẹ́ lórí Íńtánẹ́ẹ̀tì, lórí fóònú tàbí kí wọ́n kọ lẹ́tà síra wọn. Bí àwa náà bá fẹ́ sún mọ́ Ọlọ́run, a gbọ́dọ̀ máa bá a sọ̀rọ̀ déédéé. Àmọ́, báwo la ṣe lè bá Ọlọ́run sọ̀rọ̀?
A lè bá Jèhófà sọ̀rọ̀ nínú àdúrà, ṣùgbọ́n a ò kàn lè máa sọ̀rọ̀ bí ìgbà tá à ń bá ọ̀rẹ́ wa tàkúrọ̀sọ. A gbọ́dọ̀ máa rántí pé òun ni Ẹlẹ́dàá ohun gbogbo, òun sì ni Ọ̀gá Ògo láyé àtọ̀run. Torí náà, tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ló yẹ ká máa bá a sọ̀rọ̀ tá a bá ń gbàdúrà. Àmọ́ bá a bá fẹ́ kí Ọlọ́run gbọ́ àdúrà wa kó sì dáhùn rẹ̀, ó ní àwọn nǹkan tá a gbọ́dọ̀ ṣe. Ẹ jẹ́ ká gbé mẹ́ta yẹ̀ wọ̀.
Àkọ́kọ́ ni pé Ọlọ́run ló yẹ ká darí àdúrà wa sí kì í ṣe Jésù tàbí ère tàbí àwọn kan tí wọ́n ń pè ní “ẹni mímọ́.” (Ẹ́kísódù 20:4, 5) Ìmọ̀ràn Bíbélì ni pé: “Nínú ohun gbogbo nípasẹ̀ àdúrà àti ìrawọ́ ẹ̀bẹ̀ pa pọ̀ pẹ̀lú ìdúpẹ́ kí ẹ máa sọ àwọn ohun tí ẹ̀ ń tọrọ di mímọ̀ fún Ọlọ́run.” (Fílípì 4:6) Èkejì ni pé ó yẹ ká máa gbàdúrà sí Ọlọ́run lórúkọ Jésù Kristi. Ìdí nìyẹn tí Jésù fúnra rẹ̀ fi sọ pé: “Kò sí ẹni tí ń wá sọ́dọ̀ Baba bí kò ṣe nípasẹ̀ mi.” (Jòhánù 14:6) Ìkẹta ni pé àdúrà wa gbọ́dọ̀ bá ìfẹ́ Ọlọ́run mu. Torí Bíbélì sọ pé: “Ohun yòówù tí ì báà jẹ́ tí a bá béèrè ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ̀, ó ń gbọ́ tiwa.”a—1 Jòhánù 5:14.
Ọ̀rẹ́ àtọ̀rẹ́ máa ń bá ara wọn sọ̀rọ̀ déédéé
Síbẹ̀, máa rántí pé bí ẹni méjì bá ń ṣọ̀rẹ́, wọ́n gbọ́dọ̀ jọ máa sọ̀rọ̀, ẹnì kìíní sí ẹnì kejì, kì ọ̀rẹ́ wọn lè kalẹ́. Bí àwa náà bá fẹ́ bá Ọlọ́run ṣọ̀rẹ́ kalẹ́, kì í ṣe ohun tá a fẹ́ bá Ọlọ́run sọ nínú àdúrà nìkan ló yẹ kó jẹ wá lógún, a gbọ́dọ̀ jẹ́ kí Ọlọ́run máa bá wa sọ̀rọ̀ ká sì fetí sí ohun tí ó bá sọ. Ǹjẹ́ o mọ bí Ọlọ́run ṣe ń bá wa sọ̀rọ̀?
Lónìí, Bíbélì ni Jèhófà fi ń bá wa “sọ̀rọ̀.” (2 Tímótì 3:16, 17) Báwo la ṣe mọ̀ bẹ́ẹ̀? Ó dáa, ká ní ọ̀rẹ́ rẹ tímọ́tímọ́ kọ lẹ́tà sí ẹ, ó dájú pé inú rẹ á dùn gan-an, kódà lẹ́yìn tó o bá kà á tán, o lè bẹ̀rẹ̀ sí í fi lẹ́tà náà han àwọn èèyàn pé “ẹ wá gbọ́ ohun tí ọ̀rẹ́ mi sọ fún mi!” Bẹ́ẹ̀ sì rèé, ó kọ ọ̀rọ̀ náà sínú ìwé ni kò bá ẹ sọ̀rọ̀ ní tààràtà. Bákan náà, bó o bá ń ka Bíbélì, ńṣe lò ń gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Jèhófà ń sọ fún ẹ. Ìdí nìyẹn tí Gina tá a sọ̀rọ̀ rẹ̀ nínú àkòrí tó bẹ̀rẹ̀ ìwé yìí fi sọ pé: “Bí mo bá fẹ́ kí Ọlọ́run kà mí sí ọ̀rẹ́ rẹ̀, àfi kí n máa ka Bíbélì torí òun ni ‘lẹ́tà’ tí Ọlọ́run kọ sí wa. Bí mo ṣe ń ka Bíbélì déédéé ti jẹ́ kí n sún mọ́ Ọlọ́run gan-an.” Ṣé ìwọ náà máa ń jẹ́ kí Jèhófà bá ẹ sọ̀rọ̀ nípa kíka Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀ déédéé? Bó o bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, wàá túbọ̀ sún mọ́ Ọlọ́run.
a Tó o bá fẹ́ mọ̀ sí i nípa bí o ṣe lè sún mọ́ Ọlọ́run nínú àdúrà, ka orí 17 nínú ìwé Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an? Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe é.