ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w14 12/1 ojú ìwé 6
  • Ǹjẹ́ O Máa Ń Ṣe Ohun Tí Ọlọ́run Fẹ́?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ O Máa Ń Ṣe Ohun Tí Ọlọ́run Fẹ́?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Bó O Ṣe Lè Di Ọ̀rẹ́ Jèhófà
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
  • “Olùsẹ̀san fún Àwọn Tí Ń Fi Taratara Wá A”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • “Ẹ Sún Mọ́ Ọlọ́run”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
  • Máa Lo Ìgbàgbọ́ Nínú Àwọn Ìlérí Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
w14 12/1 ojú ìwé 6
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 6]

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | O LÈ SÚN MỌ́ ỌLỌ́RUN

Ǹjẹ́ O Máa Ń Ṣe Ohun Tí Ọlọ́run Fẹ́?

Ká sọ pé o rí àjèjì kan, ǹjẹ́ o lè sọ fún un pé: “Ohunkóhun tó o bá fẹ́, ìwọ ṣáà ti sọ fún mi, inú mi á dùn láti ṣe é fún ẹ láìjáfara”? Kò dájú pé wàá sọ bẹ́ẹ̀, àmọ́ á rọrùn fún ẹ láti sọ irú ọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀ fún ọ̀rẹ́ rẹ tímọ́tímọ́, torí pé ọ̀rẹ́ àtọ̀rẹ́ máa ń ran ara wọn lọ́wọ́, ẹnì kìíní sì máa ń ṣe ohun tó máa múnú ẹnì kejì dùn.

Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé ìgbà gbogbo ni Jèhófà máa ń ṣe ohun tó máa múnú àwọn tó ń jọ́sìn rẹ̀ dùn. Bí àpẹẹrẹ, Dáfídì Ọba tí òun náà jẹ́ ọ̀rẹ́ Ọlọ́run sọ pé: “Ọ̀pọ̀ nǹkan ni ìwọ fúnra rẹ ti ṣe, Ìwọ Jèhófà Ọlọ́run mi, àní àwọn iṣẹ́ àgbàyanu rẹ àti ìrònú rẹ sí wa. . . . Wọ́n pọ̀ níye ju èyí tí mo lè máa ròyìn lẹ́sẹẹsẹ!” (Sáàmù 40:5) Pabanbarì rẹ̀ ni pé oore Ọlọ́run kò yọ ẹnikẹ́ni sílẹ̀, títí kan àwọn tí kò mọ̀ ọ́n pàápàá, gbogbo wọn pátá ló ń fi ‘oúnjẹ àti ìmóríyágágá kún ọkàn-àyà wọn dé ẹ̀kúnrẹ́rẹ́.’​—Ìṣe 14:17.

Ó máa ń rọ̀ wá lọ́rùn láti ṣoore fún àwọn tá a fẹ́ràn tá a sì kà sí

Jèhófà ń ṣe ipa tiẹ̀ láti ṣe ohun tó máa múnú gbogbo ẹ̀dá dùn, torí náà gbogbo ẹní tó bá fẹ́ jẹ́ ọ̀rẹ́ Ọlọ́run gbọ́dọ̀ máa ṣe ohun tó máa “mú ọkàn-àyà” rẹ̀ yọ̀. (Òwe 27:11) Àwọn nǹkan wo la lè ṣe tó máa múnú Ọlọ́run dùn? Bíbélì sọ fún wa, ó ní: “Ẹ má gbàgbé rere ṣíṣe àti ṣíṣe àjọpín àwọn nǹkan pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn, irú àwọn nǹkan bẹ́ẹ̀ ni inú Ọlọ́run dùn sí jọjọ.” (Hébérù 13:16) Ṣé ohun tá a wa ń sọ ni pé béèyàn bá ṣáà ti ń ṣoore, tó sì lawọ́, ó parí náà nìyẹn?

Bíbélì sọ pé: “Láìsí ìgbàgbọ́ kò ṣeé ṣe láti wu [Ọlọ́run] dáadáa.” (Hébérù 11:6) Bí àpẹẹrẹ, ìgbà tí “Ábúráhámù ní ìgbàgbọ́ nínú Jèhófà,” ló tó di “Ọ̀rẹ́ Jèhófà.” (Jákọ́bù 2:23) Jésù pàápàá jẹ́rìí sí i pé a gbọ́dọ̀ “lo ìgbàgbọ́ nínú Ọlọ́run” bá a bá fẹ́ kí Ọlọ́run bù kún wa. (Jòhánù 14:1) Báwo wá la ṣe lè ní irú ìgbàgbọ́ tó máa jẹ́ kí Ọlọ́run fà wá mọ́ra bí ọ̀rẹ́ rẹ̀? A gbọ́dọ̀ máa kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run déédéé. Èyí ló máa jẹ́ ká ní “ìmọ̀ pípéye nípa ìfẹ́ rẹ̀,” àá sì mọ bí a ṣe lè “wù ú dáadáa.” Bí ìmọ̀ wa nípa Jèhófà ṣe túbọ̀ ń pọ̀ sí i, tá a sì ń fi àwọn ìlànà rẹ̀ sílò láyé wa, ìgbàgbọ́ wa máa lágbára sí i, Jèhófà náà á sì túbọ̀ sún mọ́ wa.​—Kólósè 1:​9, 10.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́